< 1 Mojžišova 4 >

1 Adam pak poznal Evu ženu svou, kterážto počavši, porodila Kaina a řekla: Obdržela jsem muže na Hospodinu.
Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
2 A opět porodila bratra jeho Abele. I byl Abel pastýř ovcí, a Kain byl oráč.
Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
3 Po mnohých pak dnech stalo se, že obětoval Kain z úrody zemské obět Hospodinu.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
4 Ano i Abel také obětoval z prvorozených věcí stáda svého, a z tuku jejich. I vzhlédl Hospodin na Abele a na obět jeho.
Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
5 Na Kaina pak a na obět jeho nevzhlédl. Protož rozlítil se Kain náramně, a opadla tvář jeho.
ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
6 I řekl Hospodin Kainovi: Proč jsi se tak rozpálil hněvem? A proč jest opadla tvář tvá?
Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
7 Zdaliž nebudeš příjemný, budeš-li dobře činiti? Pakli nebudeš dobře činiti, hřích ve dveřích leží; a pod mocí tvou bude žádost jeho, a ty panovati budeš nad ním.
Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
8 I mluvil Kain k Abelovi bratru svému. Stalo se pak, když byli na poli, že povstav Kain proti Abelovi bratru svému, zabil jej.
Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
9 I řekl Hospodin Kainovi: Kdež jest Abel bratr tvůj? Kterýž odpověděl: Nevím. Zdaliž jsem já strážným bratra svého?
Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
10 I řekl Bůh: Co jsi učinil? Hlas krve bratra tvého volá ke mně z země.
Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
11 Protož nyní zlořečený budeš i od té země, kteráž otevřela ústa svá, aby přijala krev bratra tvého z ruky tvé.
Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
12 Když budeš dělati zemi, nebude více vydávati moci své tobě; tulákem a běhounem budeš na zemi.
Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
13 I řekl Kain Hospodinu: Většíť jest nepravost má, než aby mi odpuštěna býti mohla.
Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
14 Aj, vyháníš mne dnes z země této, a před tváří tvou skrývati se budu, a budu tulákem a běhounem na zemi. I přijde na to, že kdo mne koli nalezne, zabije mne.
Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
15 I řekl mu Hospodin: Zajisté kdo by koli zabil Kaina, nad tím sedmnásobně mštěno bude. Pročež vložil Hospodin znamení naKaina, aby ho žádný nezabil, kdo by jej koli nalezl.
Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
16 Tedy odšed Kain od tváři Hospodinovy, bydlil v zemi Nód, k východní straně naproti Eden.
Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
17 Poznal pak Kain ženu svou, kterážto počala a porodila Enocha. I stavěl město, a nazval jméno města toho jménem syna svého Enoch.
Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
18 I narodil se Enochovi Irád, a Irád zplodil Maviaele, Maviael pak zplodil Matuzaele, a Matuzael zplodil Lámecha.
Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
19 Vzal sobě pak Lámech dvě ženy; jméno jedné Ada, a jméno druhé Zilla.
Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
20 I porodila Ada Jábale, kterýž byl otec přebývajících v staních a stádo pasoucích.
Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
21 A jméno bratra jeho Jubal; ten byl otec všech hrajících na harfu a nástroje hudebné.
Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
22 A Zilla také porodila Tubalkaina, kterýž byl řemeslník všelikého díla od mědi a od železa. Sestra pak Tubalkainova byla Noéma.
Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
23 I řekl Lámech ženám svým, Adě a Zille: Slyšte hlas můj, ženy Lámechovy, poslouchejte řeči mé, že jsem zabil muže k ráně své a mládence k zsinalosti své.
Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24 Jestližeť sedmnásobně pomštěno bude pro Kaina, tedy pro Lámecha sedmdesátekrát sedmkrát.
Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
25 Poznal pak ještě Adam ženu svou, i porodila syna a nazvala jméno jeho Set; nebo řekla: Dal mi Bůh jiné símě místo Abele, kteréhož zabil Kain.
Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
26 Setovi pak také narodil se syn, a nazval jméno jeho Enos. Tehdáž začalo se vzývání jména Hospodinova.
Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

< 1 Mojžišova 4 >