< Ezechiel 12 >

1 I stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu člověčí, u prostřed domu zpurného ty bydlíš, kteříž mají oči, aby viděli, však nevidí; uši mají, aby slyšeli, však neslyší, proto že dům zpurný jsou.
“Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
3 Protož ty, synu člověčí, připrav sobě to, s čím bys se stěhoval, a stěhuj se ve dne před očima jejich. Přestěhuješ se pak z místa svého na místo jiné před očima jejich, zdaby aspoň viděli; nebo dům zpurný jsou.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
4 Vynesa pak své věci, jakožto ty, s nimiž se stěhovati máš ve dne před očima jejich, vyjdi u večer před očima jejich, jako ti, kteříž se stěhují.
Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
5 Před očima jejich prokopej sobě zed, a vynes skrze ni.
Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
6 Před očima jejich na rameni nes, po tmě vynes, tvář svou přikrej, a nehleď na zemi; nebo za zázrak dal jsem tě domu Izraelskému.
Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
7 I učinil jsem tak, jakž rozkázáno bylo. Věci své vynesl jsem, jakožto ty, s nimiž bych se stěhoval ve dne, u večer pak prokopal jsem sobě zed rukou; po tmě jsem je vynesl, na rameni nesa před očima jejich.
Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
8 Opět stalo se slovo Hospodinovo ke mně ráno, řkoucí:
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
9 Synu člověčí, zdaližť řekli dům Izraelský, dům ten zpurný: Co ty děláš?
“Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
10 Rciž jim: Takto praví Panovník Hospodin: Na kníže v Jeruzalémě vztahuje se břímě toto a na všecken dům Izraelský, kteříž jsou u prostřed něho.
“Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
11 Rciž jim: Já jsem zázrakem vaším. Jakož jsem činil, tak se stane jim, postěhují se a v zajetí půjdou.
Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
12 A kníže, kteréž jest u prostřed nich, na rameni ponese po tmě a vyjde. Zed prokopají, aby jej vyvedli skrze ni; tvář svou zakryje, tak že nebude viděti okem svým země.
“Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
13 Nebo roztáhnu sít svou na něj, a polapen bude do vrše mé, a zavedu jej do Babylona, země Kaldejské, kteréž neuzří, a tam umře.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
14 Všecky také, kteříž jsou vůkol něho na pomoc jemu, i všecky houfy jeho rozptýlím na všecky strany, a mečem dobytým budu je stihati.
Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
15 I zvědí, že já jsem Hospodin, když je rozptýlím mezi národy, a rozženu je po krajinách.
“Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
16 Pozůstavím pak z nich muže nemnohé po meči, po hladu a po moru, aby vypravovali všecky ohavnosti své mezi národy, kamž se dostanou, i zvědí, že já jsem Hospodin.
Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
17 Opět stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 Synu člověčí, chléb svůj s strachem jez, a vodu svou s třesením a s zámutkem pí,
“Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
19 A rci lidu země této: Takto praví Panovník Hospodin o obyvatelích Jeruzalémských, o zemi Izraelské: Chléb svůj s zámutkem jísti budou, a vodu svou s předěšením píti, aby obloupena byla země jeho z hojnosti své, pro nátisk všech přebývajících v ní.
Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
20 Města také, v nichž bydlejí, zpustnou, a země pustá bude, a tak zvíte, že já jsem Hospodin.
Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
21 Opět stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
22 Synu člověčí, jaké to máte přísloví o zemi Izraelské, říkajíce: Prodlí se dnové, aneb zahyne všeliké vidění?
“Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
23 Protož rci jim: Takto praví Panovník Hospodin: Učiním, aby přestalo přísloví toto, aniž užívati budou přísloví toho více v Izraeli. Rci jim: Nýbrž přiblížili se dnové ti a splnění všelikého vidění.
Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
24 Nebo nebude více žádného vidění marného, a hádání pochlebníka u prostřed domu Izraelského,
Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
25 Proto že já Hospodin mluviti budu, a kterékoli slovo promluvím, stane se. Neprodlíť se dlouho, ale za dnů vašich, dome zpurný, mluviti budu slovo, a naplním je, praví Panovník Hospodin.
Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
26 I stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
27 Synu člověčí, aj, dům Izraelský říkají: Vidění to, kteréž vidí tento, ke dnům mnohým patří, a na dlouhé časy tento prorokuje.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
28 Protož rci jim: Takto praví Panovník Hospodin: Neprodlíť se dlouho všeliké slovo mé, ale slovo, kteréž mluviti budu, stane se, praví Panovník Hospodin.
“Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”

< Ezechiel 12 >