< 2 Mojžišova 2 >
1 Odšed pak muž jeden z domu Léví, vzal dceru z pokolení Léví.
Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
2 I počala žena ta, a porodila syna; a viduci, že jest krásný, kryla ho za tři měsíce.
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
3 A když ho nemohla déle tajiti, vzala mu ošitku z sítí, a omazala ji klím a smolou; a vložila do ní to dítě, a vyložila do rákosí u břehu řeky.
Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
4 A postavila sestru jeho zdaleka, aby zvěděla, co se s ním díti bude.
Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
5 A v tom sešla dcera Faraonova, aby se myla v řece; a děvečky její procházely se po břehu řeky. A uzřevši ošitku mezi rákosím, poslala děvečku svou, a vzala ji.
Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
6 A když otevřela, uzřela dítě; a aj, plakalo pacholátko. A slitovavši se nad ním, řekla: Z dětí Hebrejských jest toto.
ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
7 I řekla sestra jeho k dceři Faraonově: Mám-li jíti a zavolati tobě chůvy z žen Hebrejských, kteráž by odchovala tobě dítě?
Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
8 Odpověděla dcera Faraonova: Jdi. Tedy šla děvečka a zavolala matky toho dítěte.
Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
9 I řekla jí dcera Faraonova: Vezmi toto dítě, a odchovej mi je; a jáť dám mzdu tvou. I vzala žena dítě, a chovala je.
Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
10 A když odrostlo pachole, dovedla je k dceři Faraonově, kteráž jej měla za syna; a nazvala jméno jeho Mojžíš, řkuci: Nebo jsem ho z vody vytáhla.
Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
11 I stalo se ve dnech těch, když vyrostl Mojžíš, že vyšel k bratřím svým, a hleděl na trápení jejich. Uzřel také muže Egyptského, an tepe muže Hebrejského, jednoho z bratří jeho.
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
12 A sem i tam se ohlédna, vida, že žádného tu není, zabil Egyptského, a zahrabal jej v písku.
Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
13 Vyšed potom druhého dne, a aj, dva muži Hebrejští vadili se. I řekl tomu, kterýž křivdu činil: Proč tepeš bližního svého?
Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
14 Kterýžto odpověděl: Kdo tě ustanovil knížetem a soudcí nad námi? Zdali zabiti mne myslíš, jako jsi zabil Egyptského? Protož ulekl se Mojžíš a řekl: Jistě známá jest ta věc.
Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
15 A uslyšav Farao tu věc, hledal zabiti Mojžíše. Ale Mojžíš utekl od tváři Faraonovy, a bydlil v zemi Madianské; i usadil se podlé studnice.
Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
16 Kníže pak Madianské mělo sedm dcer. Kteréžto přišedše, vážily vodu, a nalívaly do koryt, aby napájely dobytek otce svého.
Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
17 I přišli pastýři, a odehnali je. Tedy Mojžíš vstav, pomohl jim a napojil dobytek jejich.
Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
18 A když se navrátily k Raguelovi, otci svému, řekl on: Jakž jste to dnes tak brzo přišly?
Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
19 Odpověděly: Muž Egyptský vysvobodil nás z ruky pastýřů; ano také ochotně navážil nám vody, a napojil dobytek.
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
20 I řekl dcerám svým: Kdež pak jest? Pročež jste pustily muže toho? Povolejte ho, ať pojí chleba.
Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
21 A svolil Mojžíš k tomu, aby bydlil s mužem tím. Kterýžto dal Zeforu, dceru svou, Mojžíšovi.
Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
22 I porodila syna, a nazval jméno jeho Gerson; nebo řekl: Příchozí jsem byl v zemi cizí.
Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
23 Stalo se pak po mnohých časích, že umřel král Egyptský; a synové Izraelští úpěli pro roboty, a křičeli. I vstoupil k Bohu křik jejich pro roboty.
Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
24 A uslyšel Bůh naříkání jejich, a rozpomenul se Bůh na smlouvu svou s Abrahamem, Izákem a Jákobem.
Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
25 I vzhlédl Bůh na syny Izraelské, a poznal Bůh.
Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.