< 2 Mojžišova 16 >
1 Když se pak hnuli z Elim, přišlo všecko množství synů Izraelských na poušť Sin, kteráž jest mezi Elim a Sinai, v patnáctý den druhého měsíce po vyjití z země Egyptské.
Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
2 I reptalo všecko shromáždění synů Izraelských proti Mojžíšovi a proti Aronovi na poušti.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
3 A mluvili jim synové Izraelští: Ó bychom byli zemřeli od ruky Hospodinovy v zemi Egyptské, když jsme sedávali nad hrnci masa, když jsme se najídali chleba do sytosti! A teď vyvedli jste nás na tuto poušť, abyste zmořili všecko shromáždění toto hladem.
Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
4 I řekl Hospodin Mojžíšovi: Aj, já dám vám chleba s nebe jako déšť, a vycházeti bude lid a sbírati, což by postačilo na každý den, abych ho zkusil, bude-li choditi v zákoně mém, či nebude.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
5 V den pak šestý přistrojí sobě to, co přinesou; a bude toho dvakrát více, než toho, což sbírati mají na každý den.
Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
6 Tedy mluvil Mojžíš a Aron všechněm synům Izraelským: U večer poznáte, že Hospodin vyvedl vás z země Egyptské.
Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
7 A ráno uzříte slávu Hospodinovu; neboť jest slyšel reptání vaše proti Hospodinu. My zajisté co jsme, že repcete proti nám?
Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
8 Mluvil dále Mojžíš: Z toho, pravím, poznáte, když vám dá Hospodin u večer masa, abyste se najedli, a chleba ráno do sytosti, poněvadž slyšel Hospodin reptání vaše, jimiž jste na něj reptali. Nebo my co jsme? Ne proti námť jsou reptání vaše, ale proti Hospodinu.
Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
9 I řekl Mojžíš Aronovi: Mluv ke všemu shromáždění synů Izraelských: Přistuptež před oblíčej Hospodinův; neboť jest slyšel reptání vaše.
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
10 Stalo se pak, když mluvil Aron ke všemu shromáždění synů Izraelských, že se obrátili tváří k poušti, a aj, sláva Hospodinova ukázala se v oblaku.
Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
11 (A již byl mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
Olúwa sọ fún Mose pé,
12 Slyšelť jsem reptání synů Izraelských. Mluviž jim a pověz: K večerou jísti budete maso, a ráno chlebem nasyceni budete, abyste poznali, že já jsem Hospodin Bůh váš.)
“Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
13 Tedy stalo se u večer, že přiletěly křepelky a přikryly tábor; ráno pak spadla rosa okolo táboru.
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
14 A když přestalo padání rosy, aj, ukázalo se po vrchu pouště drobného cosi a okrouhlého, drobného jako jíní na zemi.
Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
15 Což vidouce synové Izraelští, řekli jeden druhému: Man jest toto. Nebo nevěděli, co by bylo. Tedy řekl jim Mojžíš: To jest ten chléb, kterýž vám dal Hospodin ku pokrmu.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
16 To jest, o čemž přikázal Hospodin: Nasbírejte sobě toho každý k svému pokrmu; gomer na jednoho člověka vedlé počtu osob vašich, každý na ty, kteříž jsou v stanu jeho, vezmete.
Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
17 I učinili tak synové Izraelští, a nasbírali jiní více, jiní méně.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
18 Potom měřili na gomer. A nezbylo tomu, kdo nasbíral mnoho, a ten, kdo nasbíral málo, neměl nedostatku; ale každý, což mohl snísti, nasbíral.
Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
19 I řekl jim Mojžíš: Žádný ať nic z toho nepozůstavuje k jitru.
Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
20 Ale neuposlechli Mojžíše. Nebo někteří zanechali díl z toho až do jitra; i zčervivělo a zsmradilo se. Pročež rozhněval se na ně Mojžíš.
Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
21 Tak tedy sbírali to každého jitra, každý což snísti mohl. A když horké bylo slunce, tedy se ta manna rozpouštěla.
Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
22 Když pak bylo v den šestý, nasbírali toho chleba dvojnásobně, po dvou gomer na každého; protož přišla všecka knížata toho shromáždění, a pověděli Mojžíšovi.
Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
23 Kterýžto řekl jim: Toť jest, což mluvil Hospodin: Odpočinutí soboty svaté Hospodinu bude zítra. Což byste měli péci, pecte, a což byste vařiti měli, vařte dnes; což pak koli zbude, nechte sobě a schovejte to k jitru.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
24 Protož schovali to do rána, jakž přikázal Mojžíš; a nezsmradilo se, ani v něm červů nebylo.
Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
25 I řekl Mojžíš: Jeztež to dnes, poněvadž sobota jest dnes Hospodinu; dnes toho nenaleznete na poli.
Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
26 Po šest dní budete to sbírávati, den pak sedmý sobota jest; nebude bývati manny v ní.
Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
27 Stalo se pak dne sedmého, že vyšli někteří z lidu sbírat, a nenašli.
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
28 Tedy řekl Hospodin Mojžíšovi: I dokudž zpěčovati se budete přikázaní mých ostříhati a zákonů mých?
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
29 Viztež, žeť Hospodin vám dal sobotu, a proto on vám dává v den šestý chleba na dva dni. Zůstaňte každý v svém, aniž kdo vycházej z místa svého v den sedmý.
Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
30 I odpočinul lid v den sedmý.
Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
31 Nazval pak lid Izraelský jméno toho chleba man; kterýž byl jako símě koliandrové, a bílý, a chut jeho jako koláče s medem.
Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
32 Řekl také Mojžíš: Toť jest, což přikázal Hospodin: Naplň gomer tou mannou, aby chována byla na budoucí věky vaše, aby viděli pokrm, kterýž jsem vám dával jísti na poušti, když jsem vás vyvedl z země Egyptské.
Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
33 I řekl Mojžíš Aronovi: Vezmi jedno věderce, a vsyp do něho plné gomer manny; a nech jí před tváří Hospodinovou, aby chována byla na budoucí věky vaše.
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
34 A protož jakž byl přikázal Hospodin Mojžíšovi, nechal jí Aron před svědectvím, aby tu chována byla.
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
35 Jedli pak synové Izraelští mannu za čtyřidceti let, dokudž nevešli do země, v níž bydliti měli; mannu jedli, dokudž nepřišli k končinám země Kananejské.
Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
36 Gomer pak jest desátý díl efi.
(Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)