< 5 Mojžišova 9 >
1 Slyš, Izraeli, ty přejdeš dnes přes Jordán, abys vejda, dědičně vládl národy většími a silnějšími, než jsi ty, městy velikými a ohrazenými až k nebi,
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 Lidem velikým a vysokým, syny Enakovými, o kterýchž víš, a o kterýchž jsi slyšel praviti: Kdo se postaví proti synům Enakovým?
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 Protož věziž dnes, že Hospodin Bůh tvůj, kterýž jde před tebou, jest jako oheň spalující. On vyhladí je, a on sníží je před tebou; i vyženeš je a vyhladíš je rychle, jakož mluvil tobě Hospodin.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Neříkejž v srdci svém, když by je zapudil Hospodin Bůh tvůj od tváři tvé, řka: Pro spravedlnost mou uvedl mne Hospodin, abych dědičně obdržel zemi tuto, tak jako pro bezbožnost národů těch Hospodin vyhnal je od tváři tvé.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Ne pro spravedlnost svou a pravost srdce svého ty jdeš, abys dědičně obdržel zemi jejich, ale pro bezbožnost národů těch Hospodin Bůh tvůj vyhání je od tváři tvé, a aby splnil slovo, kteréž s přísahou zaslíbil otcům tvým, Abrahamovi, Izákovi a Jákobovi.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Protož věziž, že ne pro spravedlnost tvou Hospodin Bůh tvůj dává tobě zemi tu výbornou, abys dědičně držel ji, poněvadž jsi lid tvrdé šíje.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Pamatujž a nezapomínej, že jsi k hněvu popouzel Hospodina Boha svého na poušti; hned od toho dne, když jsi vyšel z země Egyptské, až jste přišli na místo toto, odporni jste byli Hospodinu.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Také i na Orébě popudili jste k hněvu Hospodina, a rozhněval se na vás Hospodin, aby vás shladil.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Když jsem vstoupil na horu, abych vzal dsky kamenné, dsky smlouvy, kterouž učinil s vámi Hospodin, tehdáž jsem trval na hoře čtyřidceti dní a čtyřidceti nocí, chleba nejeda a vody nepije.
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 I dal mi Hospodin dvě dsky kamenné, psané prstem Božím, na nichž byla všecka ta slova, kteráž mluvil vám Hospodin na hoře z prostředku ohně v den shromáždění.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 Po skonání pak čtyřidceti dnů a čtyřidceti nocí dal mi Hospodin dvě dsky kamenné, dsky smlouvy.
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 I řekl mi Hospodin: Vstana, sstup rychle odsud, nebo poškvrnil se lid tvůj, kterýž jsi vyvedl z Egypta; sešli brzy s cesty, kterouž jsem jim přikázal, a učinili sobě slitinu.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Mluvil také Hospodin ke mně, řka: Viděl jsem lid ten, a jistě lid tvrdošijný jest.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 Pusť mne, ať je setru, a zahladím jméno jejich pod nebem, tebe pak učiním v národ větší a silnější, nežli jest tento.
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 Tedy obrátiv se, sstoupil jsem s hory, (hora pak hořela ohněm), dvě dsky smlouvy maje v obou rukou svých.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 Když jsem pak pohleděl a uzřel jsem, že jste zhřešili Hospodinu Bohu vašemu, udělavše sobě tele lité, (brzy jste byli sešli s cesty, kterouž přikázal vám Hospodin):
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Pochytiv ty dvě dsky, povrhl jsem je z obou rukou svých, a polámal jsem je před očima vašima.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 A padna, ležel jsem před Hospodinem jako i prvé, čtyřidceti dní a čtyřidceti nocí, chleba nejeda a vody nepije, pro všecky hříchy vaše, kterýmiž jste byli zhřešili, činíce to, což zlého jest před očima Hospodinovýma, a popouzejíce jeho.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Nebo bál jsem se prchlivosti a hněvu, kterýmž se byl popudil Hospodin proti vám, aby zahladil vás, a uslyšel mne Hospodin i tehdáž.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Na Arona též rozhněval se byl Hospodin náramně, tak že ho zahladiti chtěl; tedy modlil jsem se také za Arona téhož času.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 Hřích pak váš, kterýž jste byli učinili, totiž tele, vzav, spálil jsem je ohněm a zdrobil jsem je, tluka je dobře, dokudž nebylo setříno na prach. Potom vsypal jsem prach jeho do potoka, kterýž tekl s té hory.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 Ano i v Tabbera a v Massah a v Kibrot Hattáve popouzeli jste Hospodina k hněvu.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 A když vás poslal Hospodin z Kádesbarne, řka: Vstupte a opanujte zemi tu, kterouž jsem vám dal, odporni jste byli řeči Hospodina Boha svého, a nevěřili jste jemu, aniž jste uposlechli hlasu jeho.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 Odporni jste byli Hospodinu od toho dne, jakž jsem vás poznal.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 A padna, ležel jsem před Hospodinem čtyřidceti dní a čtyřidceti nocí, v nichž jsem rozprostíral se; nebo řekl Hospodin, že vás chce zahladiti.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 I modlil jsem se Hospodinu, řka: Panovníče Hospodine, nezatracujž lidu svého, a to dědictví svého, kteréž jsi vykoupil velikomocností svou, kteréž jsi vyvedl z Egypta v ruce silné.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Rozpomeniž se na služebníky své, Abrahama, Izáka a Jákoba; nepatřiž na tvrdost lidu tohoto, na bezbožnost jeho a na hříchy jeho,
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 Aby neřekli obyvatelé země té, z níž jsi nás vyvedl: Proto že nemohl Hospodin uvésti jich do země, kterouž zaslíbil jim, aneb že je měl v nenávisti, vyvedl je, aby je pobil na poušti.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 Však oni jsou lid tvůj a dědictví tvé, kteréž jsi vyvedl v síle své veliké a v rameni svém vztaženém.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”