< 5 Mojžišova 23 >

1 Nevejde do shromáždění Hospodinova, kdož by měl stlučené aneb odňaté lůno.
Kí ẹnikẹ́ni tí a fọ́ ní kóró ẹpọ̀n nípa rírùn tàbí gígé má ṣe wọ inú ìjọ Olúwa wá.
2 Aniž vejde do shromáždění Hospodinova syn postranní; také i desáté koleno jeho nevejde do shromáždění Hospodinova.
Kí ọmọ àlè má ṣe wọ ìpéjọ Olúwa, pàápàá títí dé ìran kẹwàá.
3 Ammonitský tolikéž ani Moábský nevejde do shromáždění Hospodinova, ani desáté koleno jejich nevejde do shromáždění Hospodinova až na věky.
Kí ọmọ Ammoni tàbí ọmọ Moabu, kì yóò wọ ìjọ Olúwa, àní títí dé ìran kẹwàá, ènìyàn wọn kan kì yóò wọ inú ìjọ ènìyàn Olúwa láéláé.
4 Proto že proti vám nevyšli s chlebem a s vodou na cestě, když jste šli z Egypta, a že ze mzdy najal proti tobě Baláma, syna Beor, z Petor Mezopotamie Syrské, aby zlořečil tobě:
Nítorí wọn kò fi àkàrà àti omi pàdé e yín lójú ọ̀nà nígbà tí ò ń bọ̀ láti Ejibiti àti nítorí wọ́n gba ẹ̀yà iṣẹ́ láti fi ọ́ gégùn ún Balaamu ọmọ Beori ará a Petori ti Aramu-Naharaimu.
5 (Ačkoli nechtěl Hospodin Bůh tvůj slyšeti Baláma, ale obrátil Hospodin Bůh tvůj tobě zlořečení v požehnání, nebo miloval tebe Hospodin Bůh tvůj.)
Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò ní fetí sí Balaamu ṣùgbọ́n ó yí ègún sí ìbùkún fún ọ, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ fẹ́ràn rẹ.
6 Nebudeš hledati pokoje jejich ani dobrého jejich po všecky dny své na věky.
Ìwọ kò gbọdọ̀ wá àlàáfíà, tàbí ire wọn níwọ̀n ìgbà tí o sì wà láààyè.
7 Nebudeš míti v ohavnosti Idumejského, nebo bratr tvůj jest, aniž Egyptského v ohavnosti míti budeš, nebo jsi byl pohostinu v zemi jeho.
Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Edomu kan nítorí arákùnrin rẹ ni. Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Ejibiti, nítorí o gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì ní ilẹ̀ rẹ̀.
8 Synové, kteříž se jim zrodí v třetím kolenu, vejdou do shromáždění Hospodinova.
Ìran kẹta àwọn ọmọ tí a bí fún wọn lè wọ ìpéjọ Olúwa.
9 Když bys vytáhl vojensky proti nepřátelům svým, vystříhej se od všeliké zlé věci.
Nígbà tí o bá dó ti àwọn ọ̀tá rẹ, pa gbogbo ohun àìmọ́ kúrò.
10 Bude-li mezi vámi kdo, ješto by poškvrněn byl příhodou noční, vyjde ven z stanů, a nevejde do nich;
Bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin rẹ bá jẹ́ aláìmọ́ nítorí ìtújáde tí ó ní, o ní láti jáde kúrò nínú àgọ́, kí o má ṣe wọ inú àgọ́.
11 Ale když bude k večerou, umyje se vodou, a po západu slunce vejde do stanů.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá di ìrọ̀lẹ́ o ní láti wẹ ara rẹ, àti ní àṣálẹ́ kí o padà sínú àgọ́.
12 Také místo budeš míti vně za stany, abys tam chodíval ven;
Sàmì sí ibìkan lóde àgọ́, níbi tí o lè máa lọ láti dẹ ara rẹ lára.
13 A budeš míti kolík mezi jinými nástroji svými, a když bys chtěl sednouti vně, vykopáš jím důlek, a obrátě se, zahrabeš nečistotu svou.
Kí ìwọ kí ó sì mú ìwalẹ̀ kan pẹ̀lú ohun ìjà rẹ; yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ yóò bá gbọnṣẹ̀ lẹ́yìn ibùdó, kí ìwọ kí ó mú ìwalẹ̀, kí ìwọ kí ó sì yípadà, kí o sì bo ohun tí ó jáde láara rẹ.
14 Nebo Hospodin Bůh tvůj chodí u prostřed stanů tvých, aby tě vysvobodil, a dal tobě nepřátely tvé; protož ať jest příbytek tvůj svatý, tak aby nespatřil při tobě mrzkosti nějaké, pročež by se odvrátil od tebe.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń rìn láàrín àgọ́ láti dáàbò bò ọ́ àti láti fi àwọn ọ̀tá à rẹ lé ọ lọ́wọ́. Àgọ́ rẹ ní láti jẹ́ mímọ́, nítorí kí ó má ba à rí ohun àìtọ́ láàrín yín kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ yín.
15 Nevydáš služebníka pánu jeho, kterýž k tobě utekl od pána svého.
Bí ẹrú kan bá ti gba ààbò lọ́dọ̀ rẹ, má ṣe fi lé ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
16 S tebou bydliti bude u prostřed tebe na místě, kteréž by vyvolil v některém městě tvém, kdežkoli jemu se líbiti bude; nebudeš ho mocí utiskati.
Jẹ́ kí ó máa gbé láàrín rẹ níbikíbi tí ó bá fẹ́ àti èyíkéyìí ìlú tí ó bá mú. Má ṣe ni í lára.
17 Nebude nevěstka žádná z dcer Izraelských, ani nečistý smilník z synů Izraelských.
Kí ọkùnrin tàbí obìnrin Israẹli má ṣe padà di alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
18 Nepřineseš mzdy nevěstky, a mzdy psa do domu Hospodina Boha svého z jakéhokoli slibu, nebo to obé ohavnost jest Hospodinu Bohu tvému.
Ìwọ kò gbọdọ̀ mú owó iṣẹ́ panṣágà obìnrin tàbí ọkùnrin wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ láti fi san ẹ̀jẹ́ kankan; nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra àwọn méjèèjì.
19 Nedáš na lichvu bratru svému ani peněz, ani pokrmu, ani jakékoli věci, kteráž se dává na lichvu.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ka èlé sí arákùnrin rẹ lọ́rùn, bóyá lórí owó tàbí oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tí ó lè mú èlé wá.
20 Cizímu půjčíš na lichvu, ale bratru svému nedáš na lichvu, aby požehnal tobě Hospodin Bůh tvůj při všech věcech, k kterýmž bys vztáhl ruku svou v zemi, do níž vejdeš, abys dědičně obdržel ji.
Ìwọ lè ka èlé sí àlejò lọ́rùn, ṣùgbọ́n kì í ṣe arákùnrin ọmọ Israẹli, nítorí kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún ọ nínú ohun gbogbo tí o bá dáwọ́lé ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
21 Když bys učinil slib Hospodinu Bohu svému, neprodlévej splniti ho; nebo konečně toho vyhledávati bude Hospodin Bůh tvůj od tebe, a byl by na tobě hřích.
Bí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, má ṣe lọ́ra láti san án, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, o sì máa jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.
22 Pakli nebudeš slibovati, nebude na tobě hříchu.
Ṣùgbọ́n tí o bá fàsẹ́yìn láti jẹ́ ẹ̀jẹ́, o kò ní jẹ̀bi.
23 Což jednou vyšlo z úst tvých, to splníš, a učiníš, jakž jsi slíbil Hospodinu Bohu svému dobrovolně, což jsi vynesl ústy svými.
Rí i dájú pé o ṣe ohunkóhun tí o bá ti ètè rẹ jáde, nítorí pé ìwọ fi tinútinú rẹ jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú ẹnu ara rẹ.
24 Všel-li bys do vinice bližního svého, jísti budeš hrozny podlé žádosti své do sytosti své, ale do nádoby své nevložíš.
Bí ìwọ bá wọ inú ọgbà àjàrà aládùúgbò rẹ, o lè jẹ gbogbo èso àjàrà tí o bá fẹ́, ṣùgbọ́n má ṣe fi nǹkan kan sínú agbọ̀n rẹ.
25 Všel-li bys do obilí bližního svého, natrháš sobě klasů rukou svou, ale srpem nebudeš žíti obilí bližního svého.
Bí ìwọ bá wọ inú oko ọkà aládùúgbò rẹ, o lè fi ọwọ́ rẹ ya síírí rẹ̀, ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ki dòjé bọ ọkà tí ó dúró.

< 5 Mojžišova 23 >