< Daniel 6 >

1 Líbilo se pak Dariovi, aby ustanovil nad královstvím úředníků sto a dvadceti, kteříž by byli po všem království.
Ó dára lójú Dariusi láti yan ọgọ́fà àwọn baálẹ̀ sórí ìjọba,
2 Nad těmi pak hejtmany tři, z nichžto Daniel přední byl, kterýmž by úředníci onino vydávali počet, aby se králi škoda nedála.
pẹ̀lú alákòóso mẹ́ta, Daniẹli sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn, kí àwọn baálẹ̀ lè wá máa jẹ́ ààbọ̀ fún wọn, kí ọba má ba à ní ìpalára.
3 Tedy Daniel převyšoval ty hejtmany a úředníky, proto že duch znamenitější v něm byl. Pročež král myslil ustanoviti jej nade vším královstvím.
Daniẹli ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láàrín àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ nítorí ẹ̀mí tí ó tayọ wà lára rẹ̀ dé bi pé ọba sì ń gbèrò láti fi ṣe olórí i gbogbo ìjọba.
4 Tedy hejtmané a úředníci hledali příčiny proti Danielovi s strany království, a však žádné příčiny ani vady nemohli najíti; nebo věrný byl, aniž jaký omyl neb vada nalézala se při něm.
Nítorí èyí, gbogbo àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ ń gbèrò láti wá ẹ̀ṣẹ̀ kà sí Daniẹli lọ́rùn nínú ètò ìṣèjọba rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan kà sí i lọ́rùn, wọn kò rí ìwà ìbàjẹ́ kankan tí ó ṣe, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ kò sì ní ìwà ìjáfara.
5 Protož muži ti řekli: Nenajdeme proti Danielovi tomuto žádné příčiny, jediné leč bychom našli něco proti němu s strany zákona Boha jeho.
Nígbẹ̀yìn ni àwọn ọkùnrin wọ̀nyí sọ wí pé, “Àwa kò ní rí ìdí kankan láti kà ẹ̀ṣẹ̀ sí Daniẹli lọ́rùn, àfi èyí tí ó bá ní í ṣe pẹ̀lú òfin Ọlọ́run rẹ̀.”
6 Tedy hejtmané a úředníci ti shromáždivše se k králi, takto mluvili k němu: Darie králi, na věky buď živ.
Nígbà náà ni àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ lọ gẹ́gẹ́ bí ikọ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n wí pé, “Ìwọ Dariusi ọba, kí o pẹ́!
7 Uradili se všickni hejtmané království, vývodové, úředníci, správcové a vůdcové, abys ustanovil nařízení královské, a utvrdil zápověd: Kdož by koli vložil žádost na kteréhokoli boha neb člověka do třidcíti dnů, kromě na tebe, králi, aby uvržen byl do jámy lvové.
Àwọn alákòóso ọba, ìjòyè, baálẹ̀, olùdámọ̀ràn, àti àwọn olórí gbìmọ̀ pọ̀ wí pé kí ọba kéde òfin kan pé ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn kankan fún ọgbọ̀n ọjọ́, yàtọ̀ fún ìwọ ọba, a ó ju ẹni náà sí inú ihò kìnnìún.
8 Nyní tedy, ó králi, potvrď zápovědi této, a vydej mandát, kterýž by nemohl změněn býti podlé práva Médského a Perského, kteréž jest neproměnitelné.
Nísinsin yìí, ìwọ ọba, gbé òfin yìí jáde, kí o sì kọ ọ́ sínú ìwé kí a má ba à yí i padà ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia, èyí tí kò ní le è parẹ́.”
9 Pročež král Darius vydal mandát a zápověd.
Nígbà náà, ni Dariusi ọba fi ọwọ́ sí ìwé àṣẹ náà.
10 Daniel pak, když se dověděl, že jest vydán mandát, všel do domu svého, kdež otevřená byla okna v pokoji jeho proti Jeruzalému, a třikrát za den klekal na kolena svá, a modlíval se a vyznával se Bohu svému, tak jakož prvé to činíval.
Lóòótọ́, Daniẹli mọ̀ pé a ti fi ọwọ́ sí ìwé òfin náà, síbẹ̀ ó wọ ilé e rẹ̀ lọ, nínú yàrá òkè, ó ṣí fèrèsé èyí tí ó kọjú sí Jerusalẹmu sílẹ̀. Ó kúnlẹ̀ lórí orúnkún un rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójoojúmọ́, ó gbàdúrà, ó fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ tẹ́lẹ̀.
11 Tedy muži ti shromáždivše se a nalezše Daniele, an se modlí a pokorně prosí Boha svého,
Nígbà náà ni, àwọn ọlọ̀tẹ̀ yìí kó ara wọn jọ, wọ́n sì rí Daniẹli tí ó ń gba àdúrà, ó sì ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
12 Tedy přistoupili a mluvili k králi o zápovědi královské: Zdaliž jsi nevydal mandátu, aby každý člověk, kdož by koli něčeho žádal od kterého boha neb člověka až do třidcíti dnů, kromě od tebe, králi, uvržen byl do jámy lvové? Odpověděv král, řekl: Pravéť jest slovo to, podlé práva Médského a Perského, kteréž jest neproměnitelné.
Wọ́n lọ sí iwájú ọba, wọ́n sì rán ọba létí nípa òfin tí ó ṣe pé, “Ìwọ kò ha fi ọwọ́ sí òfin wí pé ní ìwọ̀n ọgbọ̀n ọjọ́ ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn, láì bá ṣe ìwọ ọba, a ó gbé e jù sínú ihò kìnnìún?” Ọba sì dáhùn pé, “Àṣẹ náà dúró síbẹ̀, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn ará Media àti Persia, èyí tí a kò le è parẹ́.”
13 Tedy odpovídajíce, řekli králi: Daniel ten, kterýž jest z zajatých synů Judských, nechtěl dbáti na tvé, ó králi, nařízení, ani na mandát tvůj, kterýž jsi vydal, ale třikrát za den modlívá se modlitbou svou.
Nígbà náà, ni wọ́n sọ fún ọba pé, “Daniẹli, ọ̀kan lára ìgbèkùn Juda, kò ka ìwọ ọba sí, tàbí àṣẹ ẹ̀ rẹ tí o fi ọwọ́ sí. Òun sì tún ń gba àdúrà ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójúmọ́.”
14 Tedy král, jakž uslyšel tu řeč, velmi se zarmoutil nad tím, a uložil král v mysli své vysvoboditi Daniele, a až do západu slunce usiloval ho vytrhnouti.
Nígbà tí ọba gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi; ó pinnu láti kó Daniẹli yọ, títí oòrùn fi rọ̀, ó sa gbogbo ipá a rẹ̀ láti gba Daniẹli sílẹ̀.
15 Ale muži ti shromáždivše se k králi, mluvili jemu: Věz, králi, že jest takové právo u Médských a Perských, aby každá výpověd a nařízení, kteréž by král ustanovil, neproměnitelné bylo.
Nígbà náà, ni àwọn ọlọ̀tẹ̀ wọ̀nyí kó ara wọn jọ wá sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ọba rántí pé, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia kò sí àṣẹ tàbí ìkéde tí ọba ṣe tí a le è yí i padà.”
16 I řekl král, aby přivedli Daniele, a uvrhli jej do jámy lvové. Mluvil pak král a řekl Danielovi: Bůh tvůj, kterémuž sloužíš ustavičně, on vysvobodí tebe.
Nígbà náà, ni ọba pàṣẹ, wọ́n sì mú Daniẹli, wọ́n sì sọ ọ́ sínú ihò kìnnìún. Ọba sì sọ fún Daniẹli pé, “Kí Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn nígbà gbogbo kí ó gbà ọ́!”
17 A přinesen jest kámen jeden, a položen na díru té jámy, a zapečetil ji král prstenem svým a prsteny knížat svých, aby nebyl změněn ortel při Danielovi.
A sì gbé òkúta kan wá, wọ́n sì fi dí ẹnu ihò náà, ọba sì dì í pa pẹ̀lú òrùka èdìdì rẹ̀ àti pẹ̀lú òrùka àwọn ọlọ́lá rẹ̀, nítorí kí a má ṣe yí ohunkóhun padà nítorí i Daniẹli.
18 I odšel král na palác svůj, a šel ležeti, nic nejeda, a ničímž se obveseliti nedal, tak že i sen jeho vzdálen byl od něho.
Nígbà náà ni ọba padà sí ààfin rẹ̀, ó sì lo gbogbo òru náà láì jẹun, kò sì gbọ́ orin kankan, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le è sùn ní òru ọjọ́ náà.
19 Tedy král hned ráno vstav na úsvitě, s chvátáním šel k jámě lvové.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, ni ọba dìde ó sì sáré lọ sí ibi ihò kìnnìún náà.
20 A jakž se přiblížil k jámě, hlasem žalostným zavolal na Daniele, a promluviv král, řekl Danielovi: Danieli, služebníče Boha živého, Bůh tvůj, kterémuž ty sloužíš ustavičně, mohl-liž tě vysvoboditi od lvů?
Nígbà tí ó súnmọ́ ibi ihò náà ní ibi tí Daniẹli wà, ó pe Daniẹli pẹ̀lú ìtara pé, “Daniẹli, ìránṣẹ́ Ọlọ́run alààyè, ṣé Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn tọ̀sán tòru, lè gbà ọ́ lọ́wọ́ kìnnìún bí?”
21 Tedy Daniel mluvil s králem, řka: Králi, na věky buď živ.
Daniẹli sì dáhùn wí pé, “Ọba kí ẹ pẹ́!
22 Bůh můj poslal anděla svého, kterýž zavřel ústa lvů, aby mi neuškodili; nebo před ním nevina nalezena jest při mně, nýbrž ani proti tobě, králi, nic zlého jsem neučinil.
Ọlọ́run mi rán angẹli i rẹ̀, ó sì dí àwọn kìnnìún lẹ́nu. Wọn kò le è pa mí lára, nítorí a rí mi gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀ ní iwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò hu ìwà ìbàjẹ́ kan níwájú rẹ ìwọ ọba.”
23 Tedy král velmi se z toho zradoval, a rozkázal Daniele vytáhnouti z jámy. I vytažen byl Daniel z jámy, a žádného úrazu není nalezeno na něm; nebo věřil v Boha svého.
Inú ọba dùn gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a mú Daniẹli jáde wá láti inú ihò. Nígbà tí a mú Daniẹli jáde nínú ihò, kò sí ojú ọgbẹ́ kan ní ara rẹ̀, nítorí tí ó gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
24 I rozkázal král, aby přivedeni byli muži ti, kteříž osočili Daniele, a uvrženi jsou do jámy lvové, oni i synové jejich i ženy jejich, a prvé než dopadli dna té jámy, zmocnili se jich lvové, a všecky kosti jejich zetřeli.
Ọba pàṣẹ pé, kí a mú àwọn alátakò Daniẹli wá, kí a jù wọ́n sí inú ihò kìnnìún, pẹ̀lú ìyàwó àti àwọn ọmọ wọn. Kí wọn tó dé ìsàlẹ̀ ihò, kìnnìún lágbára lórí i wọn, wọ́n sì fọ́ gbogbo egungun wọn.
25 Tedy Darius král napsal všechněm lidem, národům a jazykům, kteříž bydlili po vší zemi: Pokoj váš rozmnožen buď.
Nígbà náà ni Dariusi ọba kọ̀wé sí gbogbo ènìyàn orílẹ̀-èdè, àti gbogbo jákèjádò ilẹ̀ náà: “Kí ìre yín máa pọ̀ sí i!
26 Ode mne vyšlo nařízení toto, aby na všem panství království mého třásli a báli se před Bohem Danielovým; nebo on jest Bůh živý a zůstávající na věky, a království jeho nebude zrušeno, ani panování jeho až do konce.
“Mo gbé àṣẹ kan jáde wí pé, ní gbogbo agbègbè ìjọba mi, gbogbo ènìyàn gbọdọ̀ bẹ̀rù, kí wọn kí ó sì bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Daniẹli.
27 Vysvobozuje a vytrhuje, a činí znamení a divy na nebi i na zemi, kterýž vysvobodil Daniele z moci lvů.
Ó ń yọ ni, ó sì ń gbani là;
28 Danielovi pak šťastně se vedlo v království Dariovu, a v království Cýra Perského.
Daniẹli sì ṣe rere ní àkókò ìjọba Dariusi àti àkókò ìjọba Kirusi ti Persia.

< Daniel 6 >