< Skutky Apoštolů 28 >

1 A tak zachováni jsouce, teprv poznali, že ostrov ten sloul Melita.
Nígbà tí gbogbo wa sì yọ tan ni àwa tó mọ̀ pé, Mẹlita ni a ń pè erékùṣù náà.
2 Lidé pak toho ostrova velikou přívětivost k nám ukázali. Nebo zapálivše hranici drev, přijali nás všecky, pro déšť, kterýž v tu chvíli byl, a pro zimu.
Kì í ṣe oore díẹ̀ ni àwọn aláìgbédè náà ṣe fún wa. Nítorí ti wọ́n dáná, wọ́n sì gbà gbogbo wa sí ọ̀dọ̀ nítorí òjò ń rọ nígbà náà, àti nítorí òtútù.
3 A když Pavel sebral drahně roždí a kladl na oheň, ještěrka, utíkajíc před horkem, připjala se k ruce jeho.
Nígbà tí Paulu sì ṣa ìdí ìṣẹ́pẹ́ igi jọ, ti ó sì kó o sínú iná, paramọ́lẹ̀ kan ti inú oru-iná jáde, ó di mọ́ ọn ní ọwọ́.
4 A když uzřeli lidé toho ostrovu, ano ještěrka visí u ruky jeho, řekli jedni k druhým: Jistě člověk tento jest vražedlník; neb ač z moře vyšel, však pomsta Boží nedá jemu živu býti.
Bí àwọn aláìgbédè náà sì ti rí ẹranko olóró náà tí ó dì mọ́ ọn lọ́wọ́, wọ́n bá ara wọn sọ pé, “Dájúdájú apànìyàn ni ọkùnrin yìí, ẹni ti ó yọ nínú Òkun tan, ṣùgbọ́n tí ẹ̀san kò sì jẹ́ kí ó wà láààyè.”
5 Ale on střásl tu ještěrku do ohně, a nic se jemu zlého nestalo.
Òun sì gbọn ẹranko náà sínú iná ohunkóhun kan kò sì ṣe é.
6 Oni pak očekávali, že oteče, aneb padna, pojednou umře. A když toho dlouho čekali a viděli, že se mu nic zlého nestalo, změnivše myšlení své, pravili, že jest on bůh.
Ṣùgbọ́n wọn ń wòye ìgbà tí yóò wù, tàbí tí yóò sì ṣubú lulẹ̀ láti kú lójijì; nígbà tí wọ́n wò títí, tí wọn kò sì rí nǹkan kan kí ó ṣe é, wọ́n pa èrò wọn dà pé, òrìṣà kan ni ọkùnrin yìí.
7 Na těch pak místech měl popluží kníže toho ostrova, jménem Publius, kterýžto přijav nás k sobě, za tři dni přátelsky u sebe v hospodě choval.
Ní agbègbè ibẹ̀ ni ilé ọkùnrin ọlọ́lá erékùṣù náà wà, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Pubiliu; ẹni tí ó ti ipa inú rere gbà wá sí ọ̀dọ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
8 I přihodilo se, že otec toho Publia ležel, maje zimnici a červenou nemoc. K němuž všed Pavel, a pomodliv se, vzložil na něj ruce a uzdravil jej.
Ó sì ṣe, baba Pubiliu dùbúlẹ̀ àìsàn ibà àti ìgbẹ́-ọ̀rìn; ẹni tí Paulu wọlé tọ̀ lọ, tí ó sì gbàdúrà fún, nígbà tí ó sì fi ọwọ́ lé e, ó sì mú un láradá.
9 A když se to stalo, tedy i jiní, kteříž na ostrově tom nemocní byli, přistupovali, a byli uzdravováni.
Nígbà tí èyí sì ṣetán, àwọn ìyókù tí ó ni ààrùn ni erékùṣù náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì mú wọn láradá.
10 Ctili nás pak velice, a když jsme se měli pryč plaviti, nakladli nám na lodí toho, čehož potřebí bylo.
Wọ́n sì bu ọlá púpọ̀ fún wa; nígbà tí a ń lọ, wọ́n sì fún wa ní ohun púpọ̀ tí a nílò ní ọ̀nà àjò wa.
11 A po třech měsících plavili jsme se na bárce Alexandrinské, kteráž tu byla na tom ostrově přes zimu, majici za erb Kastora a Polluxa.
Lẹ́yìn oṣù mẹ́ta, a wọ ọkọ̀ ojú omi kan èyí tí ó lo àkókò òtútù ní erékùṣù náà. Ó jẹ́ ọkọ̀ ojú omi ti Alekisandiria, èyí tí àmì rẹ̀ jẹ́ tí òrìṣà ìbejì ti Kasitoru òun Polukisu.
12 A když jsme přijeli do Syrakusis, zůstali jsme tu za tři dni.
Nígbà tí a sì gúnlẹ̀ ní Sirakusi, a gbé ibẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
13 A odtud okolo plavíce se, přišli jsme do Regium; a po jednom dni, když vál vítr od poledne, druhý den přijeli jsme do Puteolos.
Láti ibẹ̀ nígbà tí a lọ yíká; a dé Regiomu: nígbà tí ó sì di ọjọ́ kejì, afẹ́fẹ́ gúúsù bẹ̀rẹ̀ sí ní fẹ́, ní ọjọ́ kejì rẹ̀ a sì dé Puteoli.
14 Kdežto nalezli jsme bratří, kteříž nás prosili, abychom pobyli u nich za sedm dní. A tak jsme šli k Římu.
A sì rí àwọn arákùnrin kan níbẹ̀, tí wọ́n sì bẹ̀ wá láti bá wọn gbé fún ọjọ́ méje: bẹ́ẹ̀ ni a sì lọ sí ìhà Romu.
15 Odkudž, když o nás uslyšeli bratří, vyšli proti nám až na rynk Appiův a ke Třem krčmám. Kteréžto uzřev Pavel, poděkoval Bohu a počal býti dobré mysli.
Àwọn arákùnrin ibẹ̀ gbúròó pé a ń bọ̀, wọ́n sì rìnrìn àjò títí wọ́n fi dé Apii Foroni àti sí ilé èrò mẹ́ta láti pàdé wa: nígbà tí Paulu sì rí wọn, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ó sì mú ọkàn le.
16 A když jsme přišli do Říma, setník dal vězně v moc hejtmanu vojska, ale Pavlovi dopuštěno, aby sám bydlil s žoldnéřem, kterýž ho ostříhal.
Nígbà tí a sì dé Romu, olórí àwọn ọmọ-ogun fi àwọn òǹdè lé olórí ẹ̀ṣọ́ lọ́wọ́, ṣùgbọ́n wọ́n gba Paulu láààyè láti máa dágbé fún ara rẹ̀ pẹ̀lú ọmọ-ogun tí ó ń ṣọ́ ọ.
17 I stalo se po třech dnech, svolal Pavel muže přední z Židů. A když se sešli, řekl k nim: Muži bratří, já nic neučiniv proti lidu ani proti obyčejům otcovským, jat jsa, z Jeruzaléma vydán jsem v ruce Římanům,
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta, Paulu pe àwọn olórí Júù jọ. Nígbà tí wọ́n sì péjọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ara, bí ó ti ṣe pé èmi kò ṣe ohun kan lòdì sí àwọn ènìyàn, tàbí sí àṣà àwọn baba wa, síbẹ̀ wọ́n fi mí lé àwọn ara Romu lọ́wọ́ ní òǹdè láti Jerusalẹmu wá.
18 Kteříž vyslyševše mne, chtěli mne propustiti, protože žádné viny hodné smrti na mně nebylo.
Nígbà tí wọ́n sì wádìí ọ̀ràn mi, wọ́n fẹ́ jọ̀wọ́ mi lọ́wọ́ lọ, nítorí tí wọn kò rí ẹ̀sùn kan tí ó tọ́ sí ikú pẹ̀lú mi.
19 Ale když Židé tomu odpírali, přinucen jsem odvolati se k císaři, ne jako bych měl co národ svůj žalovati.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù sọ̀rọ̀ lòdì sí i, èyí sún mí láti fi ọ̀ràn náà lọ Kesari, kì í ṣe pe mo ní ẹ̀sùn kan láti fi kan àwọn ènìyàn mi.
20 A protož z té příčiny povolal jsem vás, žádostiv jsa viděti vás a s vámi promluviti; nebo pro naději lidu Izraelského řetězem tímto svázán jsem.
Ǹjẹ́ nítorí ọ̀ràn yìí ni mo ṣe ránṣẹ́ pè yín, láti rí yín àti láti bá yín sọ̀rọ̀ nítorí pé, nítorí ìrètí Israẹli ni a ṣe fi ẹ̀wọ̀n yìí dè mí.”
21 A oni řekli jemu: Myť jsme žádného psaní neměli o tobě z Židovstva, aniž kdo z bratří přijda, vypravoval nám, aneb mluvil co zlého o tobě.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò rí ìwé gbà láti Judea nítorí rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan nínú àwọn arákùnrin tí ó ti ibẹ̀ wá kò ròyìn, tàbí kí ó sọ̀rọ̀ ibi kan sí ọ.
22 Ale žádámeť od tebe slyšeti, jak smyslíš; nebo víme o té sektě, že se jí všudy odpírá.
Ṣùgbọ́n àwa ń fẹ́ gbọ́ lẹ́nu rẹ ohun tí ìwọ rò nítorí bí ó ṣe ti ẹgbẹ́ ìlànà yìí ní, àwa mọ̀ pé, níbi gbogbo ni a ń sọ̀rọ̀ lòdì sí i.”
23 A když jemu uložili den, sešlo se jich mnoho do hospody k němu, jimžto s osvědčováním vypravoval o království Božím, slouže jim k víře o Ježíšovi z Zákona Mojžíšova a Proroků, od jitra až do večera.
Àwọn fi ẹnu kò lórí ọjọ́ tí wọn yóò ṣe ìpàdé pẹ̀lú Paulu, ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni ó tọ̀ ọ́ wa ni ilé àgbàwọ̀ rẹ̀; àwọn ẹni tí òun sọ àsọyé ọ̀rọ̀ ìjọba Ọlọ́run fún, ó ń yí wọn padà nípa ti Jesu láti inú òfin Mose àti àwọn wòlíì, láti òwúrọ̀ títí ó fi di àṣálẹ́.
24 A někteří uvěřili tomu, což Pavel vypravoval, někteří pak nevěřili.
Àwọn ẹlòmíràn gba ohun tí ó wí gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlòmíràn kò sì gbà á gbọ́.
25 A tak nejsouce mezi sebou svorní, rozešli se, k nimžto promluvil Pavel toto jedno slovo: Jistě žeť jest dobře Duch svatý skrze proroka Izaiáše mluvil k otcům našim,
Nígbà tí ohùn wọn kò ṣọ̀kan láàrín ara wọn, wọ́n túká, lẹ́yìn ìgbà tí Paulu sọ̀rọ̀ kan pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ sọ òtítọ́ fún àwọn baba yín nígbà tí ó sọ láti ẹnu wòlíì Isaiah wí pé:
26 Řka: Jdi k lidu tomuto a rciž jim: Sluchem slyšeti budete, a nesrozumíte, a hledíce hleděti budete, a neuzříte.
“‘Tọ àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ, kí ó sì wí pé, “Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; à ti ní rí rí ẹ̀yin yóò rí, ẹ̀yin kì yóò sí wòye.”
27 Nebo zhrublo srdce lidu tohoto, a ušima těžce slyšeli, a oči své zamhouřili, aby snad neviděli očima, a ušima neslyšeli, a srdcem nerozuměli, a neobrátili se, abych jich neuzdravil.
Nítorí ti àyà àwọn ènìyàn yìí yigbì, etí wọn sì wúwo láti fi gbọ́, ojú wọn ni wọn sì ti di. Nítorí kí wọn má ba à fi ojú wọn rí, kí wọn kí ó má ba à fi etí wọn gbọ́, àti kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀, kí wọn kí ó má ba à yípadà, àti kí èmi má ba à mú wọn láradá.’
28 Budiž vám tedy známo, že jest pohanům posláno toto spasení Boží, a oniť slyšeti budou.
“Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin mọ́ èyí pé, a rán ìgbàlà Ọlọ́run sí àwọn kèfèrí wọ́n ó sì gbọ́!”
29 A když on to propověděl, odešli Židé, majíce mezi sebou mnohé hádky.
30 Pavel pak trval za celé dvě létě v hospodě své, a přijímal všecky, kteříž přicházeli k němu,
Paulu sì gbé ilé àgbàwọ̀ rẹ̀ lọ́dún méjì gbáko, ó sì ń gbà gbogbo àwọn tí ó wọlé tọ̀ ọ́ wá.
31 Káže o království Božím a uče těm věcem, kteréž jsou o Pánu Ježíši Kristu, se vší doufanlivostí bez překážky.
Ó ń wàásù ìjọba Ọlọ́run, ó ń fi ìgboyà kọ́ni ní àwọn ohun tí i ṣe ti Jesu Kristi Olúwa, ẹnìkan kò si dá a lẹ́kun.

< Skutky Apoštolů 28 >