< 2 Samuelova 9 >

1 Tedy řekl David: Jest-li ještě kdo pozůstalý z domu Saulova, abych jemu učinil milosrdenství pro Jonatu?
Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.
2 Byl pak služebník domu Saulova, jehož jméno bylo Síba. I zavolali ho k Davidovi. I řekl král jemu: Ty-li jsi Síba? Odpověděl: Jsem služebník tvůj.
Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”
3 Řekl jemu král: Jest-liž ještě kdo z domu Saulova, abych jemu učinil milosrdenství Boží? Odpověděl Síba králi: Ještě jest syn Jonatův chromý na nohy.
Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”
4 I řekl jemu král: Kdež jest? Odpověděl Síba králi: Tam jest v domě Machiry, syna Amielova v Lodebar.
Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”
5 Protož poslav král David, vzal ho z domu Machiry, syna Amielova z Lodebar.
Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.
6 A když přišel Mifibozet syn Jonaty, syna Saulova, k Davidovi, padl na tvář svou a poklonil se. I řekl David: Mifibozete. Kterýž odpověděl: Aj, služebník tvůj.
Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un. Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!” Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”
7 Řekl jemu David: Neboj se, nebo jistě učiním s tebou milosrdenství pro Jonatu otce tvého, a navrátím tobě všecka pole Saule otce tvého, a ty jídati budeš za stolem mým vždycky.
Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”
8 Kterýž pokloniv se, řekl: Co jest služebník tvůj, že jsi se ohlédl na psa mrtvého, jakýž jsem já?
Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”
9 Zatím povolal král Síby, služebníka Saulova a řekl jemu: Cožkoli měl Saul i všecka čeled jeho, to jsem dal synu pána tvého.
Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.
10 Budeš tedy jemu spravovati rolí, ty i synové tvoji i služebníci tvoji, a snášeti budeš, aby měl syn pána tvého pokrm, kterýž by jedl, ale Mifibozet syn pána tvého jídati bude vždycky za stolem mým. (Měl pak Síba patnácte synů a dvadceti služebníků.)
Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)
11 Odpověděl Síba králi: Vedlé všeho, jakž přikázal pán můj král služebníku svému, tak učiní služebník tvůj, ačkoli i Mifibozet mohl by jídati za stolem mým jako jeden z synů královských.
Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”
12 Měl také Mifibozet syna malého, jemuž jméno bylo Mícha; a všickni, kteříž bydlili v domě Síbově, byli za služebníky Mifibozetovi.
Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti.
13 A tak Mifibozet zůstával v Jeruzalémě, proto že vždycky za stolem královským jídal; a byl kulhavý na obě noze.
Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.

< 2 Samuelova 9 >