< 2 Samuelova 22 >

1 Mluvil pak David Hospodinu slova písně této v ten den, když ho vysvobodil Hospodin z ruky všech nepřátel jeho, i z ruky Saulovy.
Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
2 A řekl: Hospodin skála má a hrad můj, i vysvoboditel můj se mnou.
Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
3 Bůh skála má, doufati budu v něho; štít můj a roh spasení mého, vyvýšení mé a útočiště mé, spasitel můj, kterýž od násilí vysvobozuje mne.
Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
4 Chvály hodného vzýval jsem Hospodina, a od nepřátel svých vysvobozen jsem.
“Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
5 Nebo obklíčily mne byly úzkosti smrti, a proudové bezbožných předěsili mne.
Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
6 Bolesti smrtelné obstoupily mne, a osídla smrti zachvátila mne. (Sheol h7585)
Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
7 V úzkosti své vzýval jsem Hospodina, a k Bohu svému volal jsem, i vyslyšel z chrámu svého hlas můj, a křik můj přišel v uši jeho.
“Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
8 Tedy pohnula se a zatřásla země, základové nebes pohnuli se, a třásli se pro rozhněvání jeho.
Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
9 Dým vycházel z chřípí jeho, a oheň zžírající z úst jeho, od něhož se uhlí roznítilo.
Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
10 Nakloniv nebes, sstoupil, a mrákota byla pod nohami jeho.
Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
11 I vsedl na cherubín a letěl, a spatřín jest na peří větrovém.
Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
12 Položil temnosti vůkol sebe jako stany, shrnutí vod, oblaky husté.
Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
13 Od blesku oblíčeje jeho rozpálilo se uhlí řeřavé.
Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
14 Hřímal s nebes Hospodin, a Nejvyšší vydal zvuk svůj.
Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
15 Vystřelil i střely, kterýmiž je rozptýlil, a blýskání, jímž je porazil.
Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
16 I ukázaly se hlubiny mořské, a odkryti jsou základové okršlku, pro zůřivé kárání Hospodinovo, pro dmýchání větru chřípí jeho.
Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
17 Poslav s výsosti, přijal mne, vytáhl mne z vod velikých.
“Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
18 Vysvobodil mne od nepřítele mého silného, od těch, kteříž mne nenáviděli, ačkoli silnější mne byli.
Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
19 Předstihli mne v den trápení mého, ale Hospodin byl mi podpora.
Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
20 Kterýž vyvedl mne na prostranství, vysvobodil mne, nebo sobě oblíbil mne.
Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
21 Odplatil mi Hospodin podlé spravedlnosti mé, podlé čistoty rukou mých odplatil mi.
“Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
22 Nebo jsem ostříhal cest Hospodinových, aniž jsem se bezbožně strhl Boha svého.
Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
23 Všickni zajisté soudové jeho jsou před oblíčejem mým, aniž jsem od kterých ustanovení jeho odstoupil.
Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
24 A tak byv dokonalý před ním, šetřil jsem, abych se nedopustil nepravosti.
Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
25 Protož odplatil mi Hospodin podlé spravedlnosti mé, vedlé čistoty mé před očima jeho.
Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
26 Ty, Pane, s milosrdným milosrdně nakládáš, a k upřímému upřímě se máš.
“Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
27 K sprostnému sprostně se ukazuješ, a s převráceným převráceně zacházíš.
Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
28 Lid pak ssoužený vysvobozuješ, ale před vysokomyslnými oči své sklopuješ.
Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
29 Ty zajisté jsi svíce má, ó Hospodine. Hospodin jistě osvěcuje temnosti mé.
Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
30 Nebo v tobě proběhl jsem vojska, v Bohu svém přeskočil jsem zed.
Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
31 Toho Boha silného cesta jest dokonalá, výmluvnosti Hospodinovy přečištěné; onť jest štít všech, kteříž doufají v něho.
“Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
32 Nebo kdo jest Bohem kromě Hospodina? A kdo jest skalou kromě Boha našeho?
Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
33 Bůh jest síla má i vojska mého, onť působí volnou cestu mou.
Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
34 Èiní nohy mé jako laní, a na vysokých místech mých postavuje mne.
Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
35 Cvičí ruce mé k boji, tak že lámi lučiště ocelivá rukama svýma.
Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
36 Nebo dal mi štít spasení svého, a dobrotivost jeho zvelebila mne.
Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
37 Rozšířil kroky mé pode mnou, aby se nepodvrtly nohy mé.
Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
38 Honil jsem nepřátely své a zahladil jsem je, aniž jsem se navrátil, dokudž jsem jich nevyplénil.
“Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
39 Docela jsem je vyhubil a sprobodal jsem je, tak že nepovstanou; i padli pod nohy mé.
Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
40 Ty zajisté, Bože, přepásals mne udatností k boji, porazils pode mne ty, kteříž povstávají proti mně.
Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
41 Nýbrž dals mi šíji nepřátel mých, těch, kteříž v nenávisti měli mne, a vyplénil jsem je.
Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
42 Ohlédali se, ale nebyl, kdo by vysvobodil, k Hospodinu, ale nevyslyšel jich.
Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
43 I potřel jsem je jako prach země, jako bláto na ulicích potlačil a rozptýlil jsem je.
Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
44 Ty jsi mne vytrhl z různic lidu mého, zachovals mne, abych byl za hlavu národům; lid neznámý mně sloužil.
“Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
45 Cizozemci lhali mi, a jakž zaslechli, uposlechli mne.
Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
46 Cizozemci svadli, a třásli se i v ohradách svých.
Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
47 Živť jest Hospodin, a požehnaná skála má; protož ať jest vyvyšován Bůh, skála spasení mého,
“Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
48 Bůh silný, kterýž dává mi pomsty a podmaňuje mi lidi.
Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
49 Vyvodíš mne z prostřed nepřátel mých, a nad povstávajícími proti mně vyvyšuješ mne, člověka nepravého mne zbavuješ.
Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
50 Protož chváliti tě budu, Hospodine, mezi národy, a jménu tvému žalmy zpívati budu.
Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
51 Onť jest hrad jistého spasení krále svého, a ten, kterýž činí milosrdenství pomazanému svému Davidovi, i semeni jeho až na věky.
“Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”

< 2 Samuelova 22 >