< 2 Královská 3 >

1 Joram pak syn Achabův počal kralovati nad Izraelem v Samaří léta osmnáctého Jozafata krále Judského, a kraloval dvanácte let.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 A činil to, což jest zlého před očima Hospodinovýma, ač ne tak jako otec jeho a jako matka jeho; nebo odjal modly Bál, kterýchž byl nadělal otec jeho.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 A však v hříších Jeroboáma syna Nebatova, kterýž k hřešení přivodil Izraele, vždy vězel, a neodstoupil od nich.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 Mésa pak král Moábský měl hojnost dobytka, a dával králi Izraelskému sto tisíc beranů, a sto tisíc skopců i s vlnou.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 I stalo se, když umřel Achab, že se zprotivil král Moábský králi Izraelskému.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Tedy vytáhl v ten čas král Joram z Samaří, a sečtl všecken Izrael.
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 A když táhl, poslal k Jozafatovi králi Judskému, aby mu řekli: Král Moábský zprotivil mi se. Potáhneš-li se mnou proti Moábovi na vojnu? Odpověděl: Potáhnu. Jako jsem já, tak jsi ty, jako lid můj, tak lid tvůj, jakž koni moji, tak koni tvoji.
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 Zatím řekl: Kterouž pak cestou potáhneme? Odpověděl: Cestou pouště Idumejské.
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 A tak vytáhl král Izraelský a král Judský i král Idumejský. A když objížděli cestou za sedm dní, nedostávalo se vody vojsku a hovadům jejich, kteráž měli s sebou.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 I řekl král Izraelský: Ach, běda! Nebo povolal Hospodin tří králů těchto, aby je vydal v ruku Moábovu.
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Ale Jozafat řekl: Není-liž zde proroka Hospodinova, abychom se otázali Hospodina skrze něho? Odpovídaje pak jeden z služebníků krále Izraelského, řekl: Jestiť zde Elizeus syn Safatův, kterýž líval vodu na ruce Eliášovy.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 Tedy řekl Jozafat: U tohoť jest slovo Hospodinovo. I šli k němu, král Izraelský a Jozafat, i král Idumejský.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 I řekl Elizeus králi Izraelskému: Co mně do tebe? Jdi k prorokům otce svého a k prorokům matky své. Řekl jemu král Izraelský: Nikoli, nebo povolal Hospodin tří králů těchto, aby je vydal v ruku Moábovu.
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 K tomu řekl Elizeus: Živť jest Hospodin zástupů, před jehož oblíčejem stojím, bychť sobě nevážil Jozafata krále Judského, nepohleděl bych na tě, ani popatřil.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Ale nyní přiveďte mi toho, kterýž by uměl hráti na harfu. A když on hral, byla nad ním ruka Hospodinova.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 I řekl: Takto praví Hospodin: Nadělej v tomto potoku množství dolů.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Nebo toto dí Hospodin: Neuzříte větru, aniž uzříte přívalu, však potok tento naplněn bude vodou, tak že píti budete i vy i množství vaše, i hovada vaše.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 A i to málo jest před oblíčejem Hospodinovým, nebo i Moábské dá v ruku vaši.
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 A zkazíte všeliké město hrazené, i všeliké město výborné, též všecko stromoví dobré zporážíte, a všecky studnice vod zasypete, a všeliké pole dobré kamením přiházíte.
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 I stalo se ráno, když obětována bývá obět suchá, a aj, vody přicházely cestou od strany Idumejské, a naplněna jest země vodami.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 Všecken pak Moáb uslyšev, že by vytáhli králové, aby bojovali proti nim, svolali se všickni, od toho, kterýž se pasem opásati může, a výše, a postavili se na pomezí.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 Potom ráno vstavše, když slunce vzešlo nad těmi vodami, uzřeli Moábští naproti ty vody rdějící se jako krev.
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 A řekli: Krev jest. Jistě žeť jsou se pohubili ti králové, a zabil jeden každý bližního svého; protož nyní k loupežem, ó Moábští! A přišli až k ležení Izraelskému.
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Tedy povstavše Izraelští, porazili Moábské, kteříž utíkali před nimi, a oni porazili je porážkou velikou, také i v jejich krajině.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Nebo města jejich zbořili, a na všeliké pole výborné házejíce jeden každý kamením svým, naplnili je, i všecky studnice vod zasypali, a všecko stromoví dobré zporáželi, tak že toliko nechali u Kirchareset zdi jeho. Protož shlukše se prakovníci, dobývali ho.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 A vida král Moábský, že jsou mu silní bojovníci ti, vzal s sebou sedm set mužů bojovných, chtě se probiti skrze vojska krále Idumejského. Ale nemohli.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Pročež jav syna jeho prvorozeného, kterýž měl kralovati místo něho, obětoval jej v obět zápalnou na zdi. I stalo se rozhněvání veliké proti Izraelovi; protož odtrhše od něho, navrátili se do země své.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

< 2 Královská 3 >