< 2 Kronická 23 >

1 Léta pak sedmého posilnil se Joiada, a pojal s sebou v smlouvu setníky, Azariáše syna Jerochamova, a Izmaele syna Jochananova, a Azariáše syna Obédova, a Maaseiáše syna Adaiášova, a Elizafata syna Zichri,
Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
2 Kteříž obcházejíce zemi Judskou, shromáždili Levíty ze všech měst Judských, a přední z otcovských čeledí Izraelských, a přišli do Jeruzaléma.
Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
3 I učinilo všecko to shromáždění smlouvu v domě Božím s králem. Byl pak jim řekl Joiada: Aj, syn králův kralovati bude, jakož mluvil Hospodin o synech Davidových.
Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
4 Tatoť jest věc, kterouž učiníte: Třetí díl vás, kteříž přicházíte v sobotu z kněží a z Levítů, budou vrátnými.
Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
5 Třetí pak díl bude při domě královu, a třetí díl u brány přední, ale všecken lid bude v síních domu Hospodinova.
Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
6 Aniž kdo vcházej do domu Hospodinova kromě kněží a těch Levítů, kteříž konají služby. Ti ať vcházejí, nebo svatí jsou, všecken pak lid ať drží stráž Hospodinovu.
Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
7 I obstoupí Levítové krále vůkol, jeden každý maje braň svou v rukou svých, a kdož by koli všel do domu, ať umře. A buďte při králi, když bude vcházeti, i když bude vycházeti.
Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
8 Tedy učinili Levítové a všecken Juda všecko, cožkoli přikázal Joiada kněz, a vzali jeden každý muže své, kteříž přicházeli v sobotu, a kteříž odcházeli v sobotu; nebo byl nepropustil Joiada kněz žádné střídy.
Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
9 I dal Joiada kněz setníkům kopí a pavézy i štíty, kteříž byli krále Davida, jenž byli v domě Božím.
Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
10 A postavil všecken lid, (a jeden každý měl braň v ruce své), od pravé strany domu až do levé strany domu, proti oltáři a proti domu, při králi všudy vůkol.
Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
11 A tak vyvedli syna králova, a vstavili na něj korunu královskou a ozdobu. I ustanovili jej králem, a pomazali ho Joiada a synové jeho, a říkali: Živ buď král!
Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
12 V tom uslyševši Atalia hřmot sbíhajícího se lidu, a chválícího krále, vešla k lidu do domu Hospodinova.
Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
13 A když pohleděla, a aj, král stál na místě vyšším, kudyž se vchází, a knížata i trubači podlé krále, a všecken lid země veselící se, a zvučící na trouby, a zpěváci s nástroji hudebnými, a ti, kteříž předčili v zpívání. Tedy roztrhla Atalia roucho své, a řekla: Spiknutí, spiknutí!
Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
14 Ale Joiada kněz rozkázal vyjíti setníkům, hejtmanům vojska, řka jim: Vyveďte ji prostředkem řadů, a kdož by za ní šel, ať jest zabit mečem. Nebo byl řekl kněz: Nezabijejte jí v domě Hospodinově.
Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
15 A když se jí rozstoupili s obou stran, šla, kudy se chodí k bráně koňské k domu královskému, a tu ji zabili.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
16 Tedy Joiada učinil smlouvu mezi Hospodinem a mezi vším lidem, i mezi králem, aby byli lid Hospodinův.
Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
17 Potom šel všecken lid do domu Bálova a zbořili jej i oltáře jeho, a obrazy stroskotali. Matana pak kněze Bálova zabili před oltáři.
Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
18 I uvedl zase Joiada úředníky domu Hospodinova pod moc kněží a Levítů, kteréž byl rozdělil David v domě Hospodinově, aby obětovali zápaly Hospodinu, (jakož psáno jest v zákoně Mojžíšově), s veselím a zpíváním podlé nařízení Davidova.
Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
19 Postavil také vrátné u vrat domu Hospodinova, aby tam nevcházel poškvrněný jakoužkoli věcí.
Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
20 A pojav setníky a znamenitější, a ty, kteříž správu drželi nad lidem, i všecken lid země, provázel krále z domu Hospodinova. I šli branou hořejší do domu královského, a posadili krále na stolici královské.
Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
21 I veselil se všecken lid země, a město se upokojilo, jakž Atalii zabili mečem.
Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.

< 2 Kronická 23 >