< 2 Kronická 2 >

1 A umíniv Šalomoun stavěti dům jménu Hospodinovu, a dům svůj královský,
Solomoni pinnu láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa àti ilé kan fún ìjọba rẹ̀
2 Odečtl Šalomoun sedmdesát tisíc nosičů a osmdesát tisíc těch, kteříž tesali na hoře, a úředníků nad nimi tři tisíce a šest set.
Solomoni sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin àwọn ọkùnrin láti ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ bi olùgé-òkúta ní àwọn òkè àti ẹgbẹ̀rún mẹ́rìndínlógójì gẹ́gẹ́ bí àwọn alábojútó lórí wọn.
3 Poslal také Šalomoun k Chíramovi králi Tyrskému, řka: Jakž jsi se choval k Davidovi otci mému, posílaje mu dříví cedrové, aby sobě stavěl dům k bydlení, tak čiň i mně.
Solomoni rán iṣẹ́ yìí sí Hiramu ọba Tire: “Rán àwọn igi kedari sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe fún baba à mi Dafidi. Nígbà tí ó fi igi kedari ránṣẹ́ sí i láti kọ́ ààfin tí ó ń gbé.
4 Nebo aj, já stavěti chci dům jménu Hospodina Boha svého, aby posvěcen byl jemu k tomu, aby se před ním kadilo vonnými věcmi, a k ustavičnému předkládání chlebů, i k zápalným obětem, ranním i večerním, ve dny sobotní a novoměsíčné, i na slavnosti Hospodina Boha našeho, což v Izraeli na věky trvati má.
Nísinsin yìí, èmi n kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi àti láti yà á sí mímọ́ fún un àti láti sun tùràrí olóòórùn dídùn níwájú rẹ̀, fún gbígbé àkàrà ìfihàn ìgbàkúgbà, àti fún ṣíṣe ẹbọ sísun ní gbogbo àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti ní ọjọọjọ́ ìsinmi àti oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn ti Olúwa Ọlọ́run wa. Èyí ni àṣẹ fún Israẹli láéláé.
5 Dům pak, kterýž stavěti chci, veliký býti má; nebo Bůh náš větší jest nade všecky bohy.
“Ilé Olúwa tí èmi yóò kọ́ yóò tóbi, nítorí pé Ọlọ́run wa tóbi ju gbogbo àwọn ọlọ́run mìíràn lọ.
6 Ač kdo jest, ješto by mohl dům jemu vystavěti, poněvadž ho nebe i nebesa nebes obsáhnouti nemohou? Ano i já kdo jsem, abych jemu dům vystavěti měl, než toliko k tomu, aby se kadilo před ním?
Ṣùgbọ́n ta ni ó le è kọ́ ilé fún Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run tó ga jùlọ, kò le è gbà á? Ta ni èmi nígbà náà láti kọ́ ilé fún Olúwa, bí kò ṣe kìkì àti sun ẹbọ sun ẹbọ níwájú rẹ̀?
7 Protož nyní pošli mi muže umělého, kterýž by uměl dělati na zlatě, na stříbře, na mědi, na železe, i z zlatohlavu a z červce, a z postavce modrého, a kterýž by uměl řezati řezby s jinými umělými, kteříž jsou u mne v Judstvu a v Jeruzalémě, kteréž zjednal David otec můj.
“Nítorí náà, rán ọkùnrin kan sí mi, tí a kọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà àti idẹ àti irin, àti ní àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti ní àwọ̀ ojú ọ̀run, tí ó jẹ́ onímọ̀ nínú iṣẹ́ igi gbígbẹ́ láti ṣiṣẹ́ ní Juda àti Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn onímọ̀ oníṣọ̀nà tí baba à mi Dafidi pèsè.
8 Přes to pošli mi také dříví cedrového a jedlového, a algumim z Libánu; nebo vím, že služebníci tvoji umějí sekati dříví Libánské. A hle, služebníci moji budou s služebníky tvými,
“Fi ìtì igi kedari, junifa àti algumu ránṣẹ́ sí mi, láti Lebanoni, nítorí tí mo mọ̀ pé àwọn ọkùnrin rẹ ní ìmọ̀ nínú gígé igi rírẹ́. Àwọn ọkùnrin mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ.
9 Aby mi připravili dostatek dříví; nebo dům, kterýž já stavěti chci, veliký býti má a slavný.
Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nítorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀.
10 A aj, dám na dělníky, kteříž sekati mají dříví, pšenice semlené služebníkům tvým dvadcet tisíc měr, a dvadcet tisíc měr ječmene, a dvadcet tisíc lák vína, a dvadcet tisíc tun oleje.
Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin agégi tí ó ń gé ìtì igi náà ni ogún ẹgbẹ̀rún, alikama ilẹ̀ àti ogún ẹgbẹ̀rún, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti barle; ogún ẹgbẹ̀rún, bati ọtí wáìnì àti ogún ẹgbẹ̀rún bati òróró olifi.”
11 I odpověděl Chíram král Tyrský psáním, kteréž poslal k Šalomounovi: Jistě, žeť miluje Hospodin lid svůj, protož tě ustanovil nad nimi za krále.
Hiramu ọba Tire fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Solomoni: “Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti ṣe ọ́ ní ọba wọn.”
12 Řekl dále Chíram: Požehnaný Hospodin Bůh Izraelský, kterýž učinil nebe i zemi, a kterýž dal králi Davidovi syna moudrého, umělého, rozumného a opatrného, aby vystavěl dům Hospodinu a dům svůj královský.
Hiramu fi kún un pe, “Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dafidi ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.
13 Protož posílámť teď muže moudrého, umělého a opatrného, kterýž byl u Chírama otce mého,
“Èmi ń rán Huramu-Abi, ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye sí ọ.
14 Syna jedné ženy ze dcer Dan, otce pak měl Tyrského, kterýž umí dělati na zlatě, na stříbře, na mědi, železe, kamení a na dříví, i z šarlatu, z postavce modrého, z kmentu a z červce, tolikéž řezati všelijaké řezby, a vymysliti všelijaké dílo, kteréž dáno mu bude s moudrými tvými, a s moudrými pána mého Davida otce tvého.
Ọmọbìnrin kan nínú àwọn ọmọbìnrin Dani àti tí baba a rẹ̀ wá láti Tire tí ó gbọ́ngbọ́n àti ṣiṣẹ́ ní wúrà àti ní fàdákà, ní idẹ, ní irin, ní òkúta àti ní ìtì igi, ní èse-àlùkò, ní aláró, àti ní ọ̀gbọ̀ tí ó dára, àti òdòdó, láti gbẹ́ onírúurú ohun gbígbẹ́ pẹ̀lú, àti láti ṣe àwárí ìmọ̀ ẹ̀rọ irú ẹ̀yàkẹ́yà tí a ó fún un ṣe. Òun yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n olúwa mi, Dafidi baba a rẹ.
15 Pšenice však toliko a ječmene, oleje a vína, což řekl pán můj, nechť pošle služebníkům svým.
“Nísinsin yìí, jẹ́ kí olúwa mi rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní alikama àti barle àti òróró Olifi náà àti ọtí tí ó ti ṣe ìlérí.
16 My pak nasekáme dříví z Libánu, což ho koli bude potřebí tobě, a připlavíme je tobě v vořích po moři k Joppe, a ty dáš je voziti do Jeruzaléma.
Àwa yóò sì gé gbogbo àwọn ìtí igi láti Lebanoni tí ìwọ yóò lò pẹ̀lú a ó gbé wọn fò lójú omi òkun lọ sí Joppa. Lẹ́yìn náà ìwọ lè kó wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu.”
17 A tak sečtl Šalomoun všecky cizozemce, kteříž byli v zemi Izraelské po sečtení tom, kterýmž sečtl je David otec jeho, a nalezeno jich sto a padesát tisíc, tři tisíce a šest set.
Solomoni ka iye àwọn àjèjì tí ó wà ní Israẹli lẹ́yìn kíka iye wọn tí baba a rẹ̀ Dafidi ti ṣe; a sì ka iye wọn sí ọ̀kẹ́ mẹ́jọ ó dín egbèjìlélọ́gbọ̀n.
18 I vybral z nich sedmdesát tisíc nosičů, a osmdesát tisíc těch, kteříž sekali na hoře, tři pak tisíce a šest set úředníků, kteříž lid k dílu přídrželi.
Ó sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin nínú wọn láti ru ẹrù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin láti ṣe àgọ́ òkúta lórí òkè, àti egbèjìdínlógún alábojútó láti kó àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́.

< 2 Kronická 2 >