< 1 Samuelova 12 >
1 Mluvil pak Samuel ke všemu Izraelovi: Aj, uposlechl jsem hlasu vašeho ve všem, což jste mluvili ke mně, a ustanovil jsem nad vámi krále.
Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
2 A nyní aj, král jde před vámi, já pak zstaral jsem se a ošedivěl, a synové moji, aj, mezi vámi jsou. Já také chodil jsem před vámi od své mladosti až do dnešního dne.
Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
3 A však aj, teď jsem. Vydejte svědectví proti mně před Hospodinem a před pomazaným jeho, vzal-li jsem čího vola, aneb vzal-li jsem čího osla, utiskl-li jsem koho, ublížil-li jsem komu, aneb vzal-li jsem od koho úplatek, abych na něm přehlédl něco, a navrátím vám.
Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
4 Odpověděli: Neutiskl jsi nás, aniž jsi ublížil nám, aniž jsi co vzal z ruky kterého člověka.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
5 Řekl ještě jim: Svědek jest Hospodin proti vám, svědek jest i pomazaný jeho v tento den, že jste nenalezli při mně ničehož. I řekl lid: Svědek jest.
Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
6 Tedy řekl Samuel lidu: Hospodin jest svědek, kterýž učinil Mojžíše a Arona, a kterýž vyvedl otce vaše z země Egyptské.
Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
7 Protož nyní postavte se, ať s vámi v soud vejdu před Hospodinem o všecky spravedlivé skutky Hospodinovy, kteréž učinil s vámi i s otci vašimi.
Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
8 Když byl všel Jákob do Egypta, volali otcové vaši k Hospodinu; i poslal Hospodin Mojžíše a Arona, kteříž vyvedli otce vaše z Egypta, a osadili je na tomto místě.
“Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
9 A když se zapomenuli na Hospodina Boha svého, vydal je v ruku Zizary, knížete vojska Azor, a v ruku Filistinských, též v ruku krále Moábského, kteříž bojovali proti nim.
“Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
10 Ale když volali k Hospodinu a řekli: Zhřešili jsme, nebo jsme opustili Hospodina, a sloužili jsme Bálim a Astarot, protož nyní vysvoboď nás z ruky nepřátel našich, a sloužiti budeme tobě:
Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
11 I poslal Hospodin Jerobále a Bedana a Jefte a Samuele, a vytrhl vás z ruky nepřátel vašich okolních, a bydlili jste bezpečně.
Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
12 Potom vidouce, že Náhas král synů Ammon přitáhl proti vám, řekli jste mi: Nikoli, ale král bude kralovati nad námi; ješto Hospodin Bůh váš jest králem vaším.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
13 Nyní tedy, aj, král, kteréhož jste zvolili, za něhož jste žádali, a aj, Hospodin ustanovil ho nad vámi králem.
Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
14 Budete-li se báti Hospodina, a jemu sloužiti a poslouchati hlasu jeho, a nebudete-li se zpěčovati řeči Hospodinově, tak i vy i král, kterýž kraluje nad vámi, ostojíte, jdouce za Hospodinem Bohem vaším.
Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
15 Pakli nebudete poslouchati hlasu Hospodinova, ale odporni budete řeči jeho, bude ruka Hospodinova proti vám, jako i proti otcům vašim.
ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
16 Ještě se teď pozastavte, a vizte věc tuto velikou, kterouž učiní Hospodin před očima vašima.
“Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
17 Zdaliž není dnes žeň pšeničná? Volati budu k Hospodinu, i vydá hřímání a déšť, tak že poznati a viděti musíte, jak jest to velmi zlá věc, kteréž jste se dopustili před očima Hospodinovýma, žádavše sobě krále.
Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
18 Protož volal Samuel k Hospodinu, a vydal Hospodin hřímání a déšť v ten den. I bál se všecken lid Hospodina velmi i Samuele.
Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
19 A řekl všecken lid Samuelovi: Modl se za služebníky své Hospodinu Bohu svému, abychom nezemřeli; nebo jsme přidali ke všem hříchům našim i toto zlé, že jsme sobě žádali krále.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
20 I řekl Samuel lidu: Nebojte se. Učiniliť jste sic všecko to zlé, však proto neodstupujte zpět od Hospodina, ale služte Hospodinu celým srdcem svým.
Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
21 Neodstupujte, pravím, následujíce marnosti, totiž cizích bohů, kteříž nic neprospívají, aniž vysvobozují, nebo jsou marnost.
Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
22 Neopustíť zajisté Hospodin lidu svého pro jméno své veliké; nebo zalíbilo se Hospodinu, aby vás sobě vzdělal v lid.
Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
23 Ode mne také odstup to, abych měl hřešiti proti Hospodinu, a přestávati modliti se za vás, nýbrž navoditi vás budu na cestu dobrou a přímou.
Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
24 A však bojte se Hospodina a služte jemu v pravdě celým srdcem svým; nebo vidíte, jak veliké věci učinil s vámi.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
25 Jestliže pak předce zle činiti budete, i vy i král váš zahynete.
Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”