< 1 Královská 3 >
1 Spříznil se pak Šalomoun s Faraonem králem Egyptským, nebo pojal dceru Faraonovu a uvedl ji do města Davidova, dokudž nedostavěl domu svého, a domu Hospodinova i zdi Jeruzalémské vůkol.
Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
2 Toliko lid obětoval na výsostech, proto že nebyl vystaven dům jménu Hospodinovu až do těch dnů.
Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
3 Nebo miloval Šalomoun Hospodina, chodě v přikázaních Davida otce svého, a toliko na těch výsostech obětoval a kadil.
Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
4 Protož šel král do Gabaon, aby tam obětoval; ta výsost zajisté byla největší. Tisíc obětí zápalných obětoval Šalomoun na tom oltáři.
Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
5 Ukázal se pak Hospodin v Gabaon Šalomounovi ve snách noci té, a řekl Bůh: Žádej začkoli, a dám tobě.
Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
6 I řekl Šalomoun: Ty jsi učinil s služebníkem svým Davidem, otcem mým, milosrdenství veliké, když chodil před tebou v pravdě a v spravedlnosti, a v upřímnosti srdce stál při tobě. Ovšem zachoval jsi jemu zvláštní toto milosrdenství, že jsi dal jemu syna, kterýž by seděl na stolici jeho, jakž se to dnes vidí.
Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
7 Ačkoli pak nyní, ó Hospodine Bože můj, ty jsi ustanovil služebníka svého králem místo Davida otce mého, já však jsa velmi mladý, neumím vycházeti ani vcházeti.
“Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
8 Služebník, pravím, tvůj jest u prostřed lidu tvého, kterýž jsi vyvolil, lidu velikého, kterýž nemůže ani sečten ani sepsán býti pro množství.
Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
9 Dejž tedy služebníku svému srdce rozumné, aby soudil lid tvůj, a aby rozeznal mezi dobrým a zlým; nebo kdo bude moci souditi tento lid tvůj tak mnohý?
Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
10 I líbilo se to Hospodinu, že žádal Šalomoun za tu věc.
Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
11 A řekl jemu Bůh: Proto že jsi žádal věci takové, a neprosils sobě za dlouhý věk, aniž jsi žádal sobě bohatství, aniž jsi žádal bezživotí nepřátel svých, ale žádal jsi sobě rozumnosti, abys slýchati uměl rozepře,
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
12 Aj, učinil jsem vedlé řeči tvé, aj, dalť jsem srdce moudré a rozumné, tak že rovného tobě nebylo před tebou, ani po tobě aby nepovstal rovný tobě.
èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
13 K tomu i to, začež jsi nežádal, dal jsem tobě, totiž bohatství a slávu, tak aby nebylo rovného tobě žádného mezi králi po všecky dny tvé.
Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
14 Přes to jestliže choditi budeš po cestách mých, ostříhaje ustanovení mých a přikázaní mých, jako chodil David otec tvůj, prodlím i dnů tvých.
Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
15 A když procítil Šalomoun, a aj, byl sen. I přišel do Jeruzaléma a stál před truhlou smlouvy Hospodinovy, a obětoval oběti zápalné a oběti pokojné; udělal také hody všechněm služebníkům svým.
Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
16 Tedy přišly dvě ženy hokyně k králi, a stály před ním.
Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
17 I řekla jedna z těch žen: Prosím, pane můj, já a žena tato bydlíme v jednom domě. I porodila jsem u ní v témž domě.
Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
18 Potom stalo se dne třetího po porodu mém, že porodila také žena tato, a byly jsme spolu. Nebylo žádného cizího s námi v domě, kromě nás dvou v témž domě.
Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
19 Umřel pak syn ženy této v noci, nebo spěci, udávila ho.
“Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
20 A vstavši o půl noci, vzala syna mého ode mne, když spala služebnice tvá, a položila jej v lůnu svém, a syna svého mrtvého položila do lůna mého.
Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
21 Ale když jsem vstala ráno, abych přikojila syna svého, a aj, mrtvý. Na kteréhož když jsem ráno pilněji pohleděla, a aj, nebyl syn můj, kteréhož jsem porodila.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
22 I řekla žena druhá: Není tak, ale syn můj jest ten živý, a ten mrtvý jest syn tvůj. Ona pak řekla: Nikoli, ale syn tvůj jest ten mrtvý, a syn můj jest ten živý. A tak se hádaly před králem.
Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
23 I řekl král: Tato praví: Ten živý jest syn můj, a syn tvůj jest ten mrtvý. Tato zase praví: Neníť tak, ale syn tvůj jest ten mrtvý, a syn můj jest ten živý.
Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
24 Protož řekl král: Přineste mi meč. I přinesli meč před krále.
Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
25 Tedy řekl král: Rozetněte to dítě živé na dvé, a dejte jednu polovici jedné, a polovici druhou druhé.
Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
26 Ale žena, jejíž syn byl ten, kterýž živ zůstal, mluvila králi, (nebo pohnula se střeva její nad synem jejím), a řekla: Prosím, pane můj, dejte jí nemluvňátko to živé, a nikoli nezabijejte ho. Druhá pak řekla: Nechť není ani mně ani tobě, rozetněte.
Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
27 K čemuž odpovídaje král, řekl: Dejtež této dítě to živé, a nikoli nezabijejte ho, onať jest matka jeho.
Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
28 Tedy uslyšavše všickni Izraelští soud tento, kterýž vynesl král, báli se krále; nebo viděli, že moudrost Boží jest v srdci jeho k vykonávání soudu.
Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.