< 1 Královská 13 >

1 A aj, muž Boží přišel z Judstva s slovem Hospodinovým do Bethel, tehdáž když Jeroboám, stoje u oltáře, kadil.
Sì kíyèsi i, ènìyàn Ọlọ́run kan wá láti Juda sí Beteli nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, bì Jeroboamu sì ti dúró lẹ́bàá a pẹpẹ láti fi tùràrí jóná.
2 I zvolal proti oltáři slovem Hospodinovým, řka: Oltáři, oltáři, toto praví Hospodin: Hle, syn narodí se domu Davidovu, jménem Joziáš, kterýž obětovati bude na tobě kněží výsostí, jenž zapalují kadidlo na tobě; i kosti lidské páliti budou na tobě.
Ó sì kígbe sí pẹpẹ náà nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, “Pẹpẹ! Pẹpẹ! Báyìí ni Olúwa wí: ‘A ó bí ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Josiah ní ilé Dafidi. Lórí rẹ ni yóò sì fi àwọn àlùfáà ibi gíga wọ̀n-ọn-nì tí ń fi tùràrí lórí rẹ̀ rú ẹbọ, a ó sì sun egungun ènìyàn lórí rẹ.’”
3 I dal téhož dne znamení, řka: Totoť jest znamení, že mluvil Hospodin: Aj, oltář roztrhne se a vysype se popel, kterýž jest na něm.
Ní ọjọ́ kan náà ènìyàn Ọlọ́run sì fún wọn ní àmì kan wí pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa ti kéde: kíyèsi i, pẹpẹ náà yóò ya, eérú tí ń bẹ lórí rẹ̀ yóò sì dànù.”
4 V tom uslyšev král Jeroboám slovo muže Božího, že zvolal proti oltáři v Bethel, vztáhl ruku svou od oltáře a řekl: Jměte ho. I uschla ruka jeho, kterouž vztáhl proti němu, a nemohl ji zase přitáhnouti k sobě.
Nígbà tí Jeroboamu ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run, tí ó kígbe sí pẹpẹ náà ní Beteli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde nínú pẹpẹ, ó sì wí pé, “Ẹ mú un!” ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ tí ó nà sí i sì kákò, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le fà á padà mọ́.
5 Oltář také se roztrhl, a vysypal se popel z oltáře podlé znamení, kteréž byl předpověděl muž Boží slovem Hospodinovým.
Lẹ́sẹ̀kan náà, pẹpẹ ya, eérú náà sì dànù kúrò lórí pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bí àmì tí ènìyàn Ọlọ́run ti fi fún un nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
6 Protož mluvil král a řekl tomu muži Božímu: Pomodl se medle Hospodinu Bohu svému a pros za mne, abych mohl přitáhnouti ruku svou k sobě. I modlil se muž Boží Hospodinu, a přitáhl král ruku zase k sobě, a byla jako prvé.
Nígbà náà ní ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì gbàdúrà fún mi kí ọwọ́ mi lè padà bọ̀ sípò.” Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa, ọwọ́ ọba sì padà bọ̀ sípò, ó sì padà sí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀.
7 Tedy řekl král muži Božímu: Poď se mnou domů a posilň se, a dámť dar.
Ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Wá bá mi lọ ilé, kí o sì wá nǹkan jẹ, èmi yóò sì fi ẹ̀bùn fún ọ.”
8 I řekl muž Boží králi: Bys mi dal polovici domu svého, nešel bych s tebou, aniž bych jedl chleba, aniž bych pil vody na místě tomto.
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run náà dá ọba lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá tilẹ̀ fún mi ní ìdajì ìní rẹ, èmi kì yóò lọ pẹ̀lú rẹ tàbí kí èmi jẹ oúnjẹ tàbí mu omi ní ibí yìí.
9 Nebo tak mi přikázal slovem svým Hospodin, řka: Nebudeš jísti chleba, ani píti vody, aniž se navrátíš tou cestou, kterouž jsi přišel.
Nítorí a ti pa á láṣẹ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi tàbí padà ní ọ̀nà náà tí o gbà wá.’”
10 A tak odšel jinou cestou, a nenavrátil se tou cestou, kterouž byl přišel do Bethel.
Bẹ́ẹ̀ ni ó gba ọ̀nà mìíràn, kò sì padà gba ọ̀nà tí ó gbà wá sí Beteli.
11 Prorok pak jeden starý bydlil v Bethel, jehož syn přišed, vypravoval mu všecky věci, kteréž učinil muž Boží toho dne v Bethel; i slova, kteráž mluvil králi, vypravovali otci svému.
Wòlíì àgbà kan wà tí ń gbé Beteli, ẹni tí àwọn ọmọ rẹ̀ dé, tí ó sì ròyìn gbogbo ohun tí ènìyàn Ọlọ́run náà ti ṣe ní Beteli ní ọjọ́ náà fún un. Wọ́n sì tún sọ fún baba wọn ohun tí ó sọ fún ọba.
12 Tedy řekl jim otec jejich: Kterou cestou šel? I ukázali mu synové jeho cestu, kterouž šel ten muž Boží, kterýž byl z Judstva přišel.
Baba wọn sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ọ̀nà wo ni ó gbà?” Àwọn ọmọ rẹ̀ sì fi ọ̀nà tí ènìyàn Ọlọ́run láti Juda gbà hàn án.
13 Zatím řekl synům svým: Osedlejte mi osla. Kteříž osedlali mu osla, a on vsedl na něj.
Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un tán, ó sì gùn ún.
14 A jel za mužem Božím a nalezl jej, an sedí pod dubem. I řekl jemu: Ty-li jsi ten muž Boží, kterýž jsi přišel z Judstva? A on odpověděl: Jsem.
Ó sì tẹ̀lé ènìyàn Ọlọ́run náà lẹ́yìn. Ó sì rí i tí ó jókòó lábẹ́ igi óákù kan, ó sì wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá bí?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Èmi ni.”
15 Kterýž řekl jemu: Poď se mnou domů, a pojíš chleba.
Nígbà náà ni wòlíì náà sì wí fún un pé, “Bá mi lọ ilé, kí o sì jẹun.”
16 Ale on odpověděl: Nemohuť se navrátiti, ani jíti s tebou, aniž budu jísti chleba, ani píti vody s tebou na místě tomto.
Ènìyàn Ọlọ́run náà sì wí pé, “Èmi kò le padà sẹ́yìn tàbí bá ọ lọ ilé, tàbí kí èmi kí ó jẹ oúnjẹ tàbí mu omi pẹ̀lú rẹ níhìn-ín.
17 Nebo stala se ke mně řeč slovem Hospodinovým: Nebudeš tam jísti chleba, ani píti vody; nenavrátíš se, jda touž cestou, kterouž jsi šel.
A ti sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi níhìn-ín tàbí kí o padà lọ nípa ọ̀nà tí ìwọ bá wá.’”
18 Jemuž odpověděl: Takéť já prorok jsem jako i ty, a mluvil ke mně anděl slovem Hospodinovým, řka: Navrať ho s sebou do domu svého, ať pojí chleba a napije se vody. To pak sklamal jemu.
Wòlíì àgbà náà sì wí fún un pé, “Wòlíì ni èmi náà pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìwọ. Angẹli sì sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Mú un padà wá sí ilé rẹ, kí ó lè jẹ oúnjẹ àti kí ó lè mu omi.’” (Ṣùgbọ́n ó purọ́ fún un ni.)
19 Takž se navrátil s ním, a jedl chléb v domě jeho a pil vodu.
Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà sì padà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì jẹ oúnjẹ ó sì mu omi ní ilé rẹ̀.
20 Když pak oni seděli za stolem, stalo se slovo Hospodinovo k proroku tomu, kterýž onoho byl zase navrátil.
Bí wọ́n sì ti jókòó ti tábìlì, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ wòlíì tí ó mú un padà wá pé;
21 A zvolal na muže Božího, kterýž byl přišel z Judstva, řka: Toto praví Hospodin: Proto že jsi na odpor učinil řeči Hospodinově, a neostříhal jsi přikázaní, kteréžť vydal Hospodin Bůh tvůj,
Ó sì kígbe sí ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́, ìwọ kò sì pa àṣẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́.
22 Ale navrátils se a jedls chléb, a pils vodu na místě, o kterémžť řekl: Nebudeš jísti chleba, ani píti vody: nebudeť pochováno tělo tvé v hrobě otců tvých.
Ìwọ padà, ìwọ sì ti jẹ oúnjẹ, ìwọ sì ti mu omi níbi tí ó ti sọ fún ọ pé kí ìwọ kí ó má ṣe jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Nítorí náà, a kì yóò sin òkú rẹ sínú ibojì àwọn baba rẹ.’”
23 Tedy když pojedl chleba a napil se, osedlal mu osla, totiž tomu proroku, kteréhož byl navrátil.
Nígbà tí ènìyàn Ọlọ́run sì ti jẹun tán àti mu omi tan, wòlíì tí ó ti mú u padà sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un.
24 A když odšel, trefil na něj lev na cestě a udávil jej. I leželo tělo jeho na cestě, a osel stál podlé něho; lev také stál vedlé těla mrtvého.
Bí ó sì ti ń lọ ní ọ̀nà rẹ̀, kìnnìún kan pàdé rẹ̀ ní ọ̀nà, ó sì pa á, a sì gbé òkú rẹ̀ sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró tì í lẹ́gbẹ̀ẹ́.
25 A aj, muži někteří jdouce tudy, uzřeli tělo mrtvé ležící na cestě, a lva, an stojí vedlé něho. Kteříž přišedše, pověděli v městě, v kterémž ten starý prorok bydlil.
Àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá sì rí pé ó gbé òkú náà sọ sí ojú ọ̀nà, kìnnìún náà sì dúró ti òkú náà; wọ́n sì wá, wọ́n sì sọ ọ́ ní ìlú tí wòlíì àgbà náà ń gbé.
26 Což když uslyšel ten prorok, kterýž ho byl navrátil s cesty, řekl: Muž Boží jest, kterýž na odpor učinil řeči Hospodinově; protož vydal jej Hospodin lvu, kterýž potřev ho, udávil jej vedlé řeči Hospodinovy, kterouž mluvil jemu.
Nígbà tí wòlíì tí ó mú un padà wá láti ọ̀nà rẹ̀ sì gbọ́ èyí, ó sì wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run náà ni tí ó ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́. Olúwa sì ti fi lé kìnnìún lọ́wọ́, tí ó sì fà á ya, tí ó sì pa á, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti kìlọ̀ fún un.”
27 Zatím mluvě k synům svým, řekl: Osedlejte mi osla. I osedlali.
Wòlíì náà sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi,” wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
28 A odjev, nalezl mrtvé tělo jeho ležící na cestě, a osla i lva, an stojí u toho těla; a nejedl lev těla toho, aniž co uškodil oslu.
Nígbà náà ni ó sì jáde lọ, ó sì rí òkú náà tí a gbé sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Kìnnìún náà kò sì jẹ òkú náà, tàbí fa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà ya.
29 Protož vzav prorok tělo muže Božího, vložil je na osla, a přinesl je. I přišel do města svého, aby ho plakal a pochoval.
Nígbà náà ni wòlíì náà gbé òkú ènìyàn Ọlọ́run náà, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì gbé e padà wá sí ìlú ara rẹ̀ láti ṣọ̀fọ̀ fún un àti láti sin ín.
30 Položil pak tělo jeho v hrobě svém, a plakali ho: Ach, bratře můj.
Nígbà náà ni ó gbé òkú náà sínú ibojì ara rẹ̀, wọ́n sì ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ó ṣe, arákùnrin mi!”
31 A pochovav ho, mluvil k synům svým, řka: Když já umru, pochovejte mne v témž hrobě, v němž muž Boží jest pochován, vedlé kostí jeho položte kosti mé.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú rẹ̀ tán, ó sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Nígbà tí mo bá kú, ẹ sin mí ní ibojì níbi tí a sin ènìyàn Ọlọ́run sí; ẹ tẹ́ egungun mi lẹ́bàá egungun rẹ̀.
32 Neboť se jistě stane to, což ohlásil slovem Hospodinovým proti oltáři, kterýž jest v Bethel, a proti všechněm domům výsostí, kteréž jsou v městech Samařských.
Nítorí iṣẹ́ tí ó jẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Olúwa sí pẹpẹ tí ó wà ní Beteli àti sí gbogbo ojúbọ lórí ibi gíga tí ń bẹ ní àwọn ìlú Samaria yóò wá sí ìmúṣẹ dájúdájú.”
33 Po těchto příbězích neodvrátil se Jeroboám od cesty své zlé, ale opět nadělal z lidu obecného kněží výsostí. Kdo jen chtěl, posvětil ruky jeho, a ten byl knězem výsostí.
Lẹ́yìn nǹkan yìí, Jeroboamu kò padà kúrò nínú ọ̀nà búburú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún yan àwọn àlùfáà sí i fún àwọn ibi gíga nínú gbogbo àwọn ènìyàn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di àlùfáà, a yà á sọ́tọ̀ fún ibi gíga wọ̀nyí.
34 I byla ta věc domu Jeroboámovu příčinou k hřešení, aby vypléněn a vyhlazen byl se svrchku země.
Èyí sì ni ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó yọrí sí ìṣubú rẹ̀, a sì pa á run kúrò lórí ilẹ̀.

< 1 Královská 13 >