< 1 Královská 10 >

1 Uslyševši pak královna z Sáby pověst o Šalomounovi a jménu Hospodinovu, přijela, aby zkusila jeho v pohádkách.
Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ òkìkí Solomoni àti ì bà ṣe pọ̀ rẹ̀ ní ti orúkọ Olúwa, ó sì wá láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè líle.
2 A přijevši do Jeruzaléma s počtem velmi velikým, s velbloudy nesoucími vonné věci a zlata velmi mnoho i kamení drahého, přišla k Šalomounovi, a mluvila s ním o všecko, což měla v srdci svém.
Ó sì wá sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹgbẹ́ èrò ńlá ńlá, pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ wúrà, àti òkúta iyebíye, ó sì wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni, ó sì bá a sọ gbogbo èyí tí ń bẹ ní ọkàn rẹ̀.
3 Jížto odpověděl Šalomoun na všecka slova její. Nebylo nic skrytého před králem, nač by jí neodpověděl.
Solomoni sì dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyí tí ó ṣòro fún ọba láti ṣàlàyé fún un.
4 Protož uzřevši královna z Sáby všecku moudrost Šalomounovu i dům, kterýž byl ustavěl,
Nígbà tí ayaba Ṣeba sì rí gbogbo ọgbọ́n Solomoni àti ààfin tí ó ti kọ́.
5 Též pokrmy stolu jeho, i sedání a stávání služebníků přisluhujících jemu, i roucha jejich, šeňkýře také jeho, i stupně, kterýmiž vstupoval k domu Hospodinovu, zděsila se náramně.
Oúnjẹ tí ó wà lórí i tábìlì rẹ̀, ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti ìdúró àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti ìwọṣọ wọn, àwọn agbọ́tí rẹ̀, àti ẹbọ sísun tí ó sun ní ilé Olúwa, kò sì sí ẹ̀mí kan nínú rẹ̀ mọ́!
6 A řekla králi: Praváť jest řeč, kterouž jsem slyšela v zemi své, o věcech tvých a o moudrosti tvé,
Ó sì wí fún ọba pé, “Òtítọ́ ni ìròyìn tí mo gbọ́ ní orílẹ̀-èdè mi ní ti iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ.
7 Ješto jsem nechtěla věřiti řečem, až jsem přijela a uzřela očima svýma. Ale aj, není mi praveno ani polovice; převýšil jsi moudrostí a dobrotou pověst tu, kterouž jsem slyšela.
Ṣùgbọ́n èmi kò sì gba nǹkan wọ̀nyí gbọ́ títí ìgbà tí mo wá, tí mo sì fi ojú ara mi rí i. Sì kíyèsi i, a kò sọ ìdajì wọn fún mi; ìwọ sì ti fi ọgbọ́n àti ìrora kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
8 Blahoslavení muži tvoji, a blahoslavení služebníci tvoji, kteříž stojí před tebou vždycky, a slyší moudrost tvou.
Báwo ni inú àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe dùn tó! Báwo ni inú dídùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí wọ́n ń dúró níwájú rẹ nígbà gbogbo, tí wọ́n sì ń gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
9 Budiž Hospodin Bůh tvůj požehnaný, kterýž tě sobě oblíbil, aby tě posadil na stolici Izraelské, proto že miluje Hospodin Izraele na věky, a ustanovil tě králem, abys činil soud a spravedlnost.
Ìbùkún ni fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ní inú dídùn sí ọ, tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ Israẹli. Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn Israẹli títí láé, ni ó ṣe fi ọ́ jẹ ọba, láti ṣe ìdájọ́ àti òdodo.”
10 I dala králi sto a dvadceti centnéřů zlata, a vonných věcí velmi mnoho, i kamení drahého, aniž bylo kdy více přivezeno takových vonných věcí tak mnoho, jako darovala královna z Sáby králi Šalomounovi.
Ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà, tùràrí olóòórùn dídùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, àti òkúta iyebíye. Kò sí irú ọ̀pọ̀lọpọ̀ tùràrí tí a mú wá tí ó dàbí irú èyí tí ayaba Ṣeba fi fún Solomoni ọba.
11 (Lodí také Chíramova, kteráž přinášela zlato z Ofir, přivezla z Ofir dříví almugim velmi mnoho i kamení drahého.
(Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́-ọkọ̀ Hiramu tí ó mú wúrà láti Ofiri wá, wọ́n mú igi algumu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àti òkúta oníyebíye láti Ofiri wá.
12 I nadělal král z toho dříví almugim zábradel k domu Hospodinovu, i k domu královu, též harf a louten zpěvákům, aniž jest kdy přivezeno takového dříví almugim, ani vidíno do dnešního dne.)
Ọba sì fi igi algumu náà ṣe òpó fún ilé Olúwa àti fún ààfin ọba, àti láti ṣe dùùrù pẹ̀lú àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Irú igi algumu bẹ́ẹ̀ kò dé mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò rí wọn títí di òní yìí.)
13 Král také Šalomoun dal královně z Sáby vedlé vší vůle její, čehož požádala, nad to, což jí Šalomoun daroval darem královským. Potom se navrátila do země své ona i služebníci její.
Solomoni ọba sì fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ìfẹ́ rẹ̀ àti ohun tí ó béèrè, yàtọ̀ sí èyí tí a fi fún un láti ọwọ́ Solomoni ọba wa. Nígbà náà ni ó yípadà, ó sì lọ sí ìlú rẹ̀, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
14 Byla pak váha toho zlata, kteréž přicházelo Šalomounovi na každý rok, šest set šedesáte šest centnéřů zlata,
Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni ń gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì wúrà,
15 Kromě toho, co přicházelo od kupců a prodavačů vonných věcí, a ode všech králů Arabských i vývod země.
láìka èyí tí ó ń gbà lọ́wọ́ àwọn ajẹ́lẹ̀ àti àwọn oníṣòwò, àti ti gbogbo àwọn ọba Arabia, àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀.
16 A protož nadělal král Šalomoun dvě stě štítů z zlata taženého, šest set zlatých dával na každý štít,
Solomoni ọba sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà ni ó lọ sí asà kan.
17 A tři sta pavéz z taženého zlata, tři libry zlata dal na každou pavézu. I složil je král v domě lesu Libánského.
Ó sì túnṣe ọ̀ọ́dúnrún asà wúrà lílù, pẹ̀lú òsùwọ̀n wúrà mẹ́ta tí ó tàn sí asà kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sí ilé igbó Lebanoni.
18 Udělal také král stolici z kostí slonových velikou, a obložil ji zlatem ryzím.
Nígbà náà ni ọba sì ṣe ìtẹ́ eyín erin ńlá kan, ó sì fi wúrà dídára bò ó.
19 Šest stupňů bylo k té stolici, a vrch okrouhlý byl na stolici od zadní strany její, a zpolehadla rukám s obou stran té stolice, a dva lvové stáli u zpolehadel.
Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, ẹ̀yìn rẹ̀ sì ṣe róbótó lókè. Ní ibi ìjókòó méjèèjì náà ni ìrọpá wà, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn.
20 A dvanácte lvů stálo tu na šesti stupních s obou stran. Nebylo nic takového učiněno v žádných královstvích.
Kìnnìún méjìlá sì dúró níbi àtẹ̀gùn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní òpin àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, kò tí ì sí irú rẹ̀ ní ìjọba kan rí.
21 Nadto všecky nádoby krále Šalomouna, jichž ku pití užívali, byly zlaté, a všecky nádoby v domě lesu Libánského byly z zlata nejčistšího. Nic nebylo od stříbra, aniž ho sobě co vážili ve dnech Šalomounových.
Gbogbo ohun èlò mímu Solomoni ọba sì jẹ́ wúrà àti gbogbo ohun èlò ààfin igbó Lebanoni sì jẹ́ kìkì wúrà. Kò sí nǹkan kan tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
22 Nebo měl král lodí mořské s lodími krále Chírama. Jednou ve třech letech vracely se ty lodí mořské, přinášející zlato a stříbro, kosti slonové, a opice a pávy.
Ọba sì ní ọkọ̀ Tarṣiṣi kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hiramu ní Òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tarṣiṣi ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.
23 I zveleben jest král Šalomoun nad všecky krále zemské v bohatství a v moudrosti.
Solomoni ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.
24 Pročež všickni obyvatelé země žádostivi byli viděti tvář Šalomounovu, aby slyšeli moudrost jeho, kterouž složil Bůh v srdci jeho.
Gbogbo ayé sì ń wá ojú Solomoni láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.
25 A přinášeli jeden každý dary své, nádoby stříbrné a nádoby zlaté, roucha a zbroj, i vonné věci, koně a mezky, a to každého roku,
Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbáaka.
26 Tak že nashromáždil Šalomoun vozů a jezdců, a měl tisíc a čtyři sta vozů a dvanácte tisíc jezdců, kteréž rozsadil v městech vozů, a při králi v Jeruzalémě.
Solomoni sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú ọba ní Jerusalẹmu.
27 I složil král stříbra v Jeruzalémě jako kamení, a cedrového dříví jako planého fíkoví, kteréž roste v údolí u velikém množství.
Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti igi kedari ni ó ṣe kí ó dàbí igi sikamore tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.
28 Přivodili také Šalomounovi koně z Egypta a koupě rozličné; nebo kupci královští brávali koupě rozličné za slušnou mzdu,
A mú àwọn ẹṣin wá fún Solomoni láti Ejibiti àti láti Kue, oníṣòwò ọba rà wọ́n láti Kue fún owó.
29 A vodívali spřež vozníků z Egypta za šest set lotů stříbra, koně pak jednoho za sto a padesáte, a tak všechněm králům Hetejským a králům Syrským oni dodávali.
Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Ejibiti wá fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún àádọ́jọ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hiti àti ọba àwọn ọmọ Aramu.

< 1 Královská 10 >