< 1 Kronická 15 >

1 Když pak sobě nastavěl domů v městě Davidově, a připravil místo pro truhlu Boží, a roztáhl jí stánek,
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
2 Tehdy řekl David: Nemáť nositi žádný truhly Boží kromě Levítů, ty zajisté vyvolil Hospodin, aby nosili truhlu Boží, a aby přisluhovali jemu až na věky.
Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
3 Protož shromáždil David všecken lid Izraelský do Jeruzaléma, aby přenesl truhlu Hospodinovu na místo její, kteréž jí byl připravil.
Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
4 Shromáždil také David syny Aronovy a Levíty.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
5 Z synů Kahat byli Uriel kníže, a bratří jeho sto a dvadceti.
Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
6 Z synů Merari Asaiáš kníže, a bratří jeho dvě stě a dvadceti.
Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
7 Z synů Gersomových Joel kníže, a bratří jeho sto a třidceti.
Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
8 Z synů Elizafanových Semaiáš kníže, a bratří jeho dvě stě.
Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
9 Z synů Hebronových Eliel kníže, a bratří jeho osmdesát.
Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
10 Z synů Uzielových Aminadab kníže, a bratří jeho sto a dvanáct.
Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
11 Tedy povolal David Sádocha a Abiatara, kněží, též i Levítů: Uriele, Asaiáše, Joele, Semaiáše, Eliele a Aminadaba,
Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
12 A řekl jim: Vy jste přední z otcovských čeledí mezi Levíty, posvěťte sebe i bratří svých, abyste vnesli truhlu Hospodina Boha Izraelského tu, kdež jsem jí připravil.
Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
13 Nebo že spočátku ne vy jste spravovali toho, obořil se Hospodin Bůh náš na nás; nebo jsme ho nehledali náležitě.
Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
14 I posvětili se kněží i Levítové, aby přenesli truhlu Hospodina Boha Izraelského.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
15 A nesli synové Levítů truhlu Boží, jakož byl přikázal Mojžíš, podlé slova Hospodinova, na ramenou svých na sochořích.
Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
16 Řekl také David předním z Levítů, aby ustanovili z bratří svých zpěváky s nástroji muzickými, loutnami, harfami a cymbály, aby zvučeli, povyšujíce hlasu s radostí.
Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
17 Takž ustanovili Levítové Hémana syna Joelova, a z bratří jeho Azafa syna Berechiášova, a z synů Merari bratří jejich Etana syna Kusaiova.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
18 A s nimi bratří jejich z druhého pořádku: Zachariáše, Béna, Jaaziele, Semiramota, Jechiele, Unni, Eliaba, Benaiáše, Maaseiáše, Mattitiáše, Elifele, Mikneiáše, Obededoma a Jehiele, vrátné.
àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
19 Nebo zpěváci Héman, Azaf a Etan hrali hlasitě na cymbálích měděných,
Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
20 A Zachariáš, Aziel, Semiramot, Jechiel, Unni, Eliab, Maaseiáš a Benaiáš na loutnách, při zpěvu vysokém.
Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
21 A Mattitiáš, Elifele, Mikneiáš, Obededom, Jehiel a Azaziáš hrali na harfách při zpěvu nízkém.
àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
22 Chenaniáš pak, přední z Levítů nesoucích truhlu, spravoval, jak by nésti měli; nebo byl umělý.
Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
23 Berechiáš pak a Elkána byli vrátní u truhly.
Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
24 Sebaniáš také a Jozafat, Natanael, Amazai, Zachariáš, Benaiáš a Eliezer kněží, troubili na trouby před truhlou Boží; ale Obededom a Jechiáš byli též vrátní u truhly.
Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
25 A tak vypravil se David a starší Izraelští a hejtmané, aby přenesli truhlu smlouvy Hospodinovy z domu Obededomova s veselím.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
26 I stalo se, poněvadž Bůh pomáhal Levítům nesoucím truhlu smlouvy Hospodinovy, že obětovali sedm volů a sedm beranů.
Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
27 David pak odín byl pláštěm kmentovým, tolikéž všickni Levítové, kteříž nesli truhlu, i zpěváci, i Chenaniáš, správce nesoucích, mezi zpěváky. Měl také David na sobě efod lněný.
Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
28 Takž všecken lid Izraelský provázeli truhlu smlouvy Hospodinovy s plésáním a zvukem trouby, a pozaunů a cymbálů, a hrali na loutny a na harfy.
Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
29 Když pak truhla smlouvy Hospodinovy vcházela do města Davidova, Míkol dcera Saulova vyhlédla z okna, a viduci krále Davida poskakujícího a plésajícího, pohrdla jím v srdci svém.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.

< 1 Kronická 15 >