< Žalmy 35 >

1 Žalm Davidův. Suď se, Hospodine, s těmi, kteříž se se mnou soudí; bojuj proti těm, kteříž proti mně bojují.
Ti Dafidi. Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí; kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!
2 Pochyť štít a pavézu, a povstaň mi ku pomoci.
Di asà àti àpáta mú, kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!
3 Vezmi i kopí, a vyjdi vstříc těm, kteříž táhnou proti mně. Rciž duši mé: Spasení tvé jáť jsem.
Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi. Sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”
4 Nechať se zahanbí a zapýří ti, kteříž hledají duše mé; zpět ať jsou obráceni a zahanbeni ti, kteříž mi zlé obmýšlejí.
Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú; kí a sì mú wọn padà, kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.
5 Ať jsou jako plevy před větrem, a anděl Hospodinův rozptylujž je.
Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.
6 Cesta jejich budiž temná a plzká, a anděl Hospodinův stihej je.
Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!
7 Nebo jsou bez příčiny polékli v jámě osídlo své, bez příčiny vykopali jámu duši mé.
Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi, ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.
8 Připadniž na ně setření, jehož se nenadáli, a sít jejich, kterouž ukryli, ať je uloví; s hřmotem ať do ní vpadnou.
Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì. Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀; kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.
9 Duše má pak ať se veselí v Hospodinu, a ať raduje se v spasení jeho.
Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa, àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.
10 A tuť všecky kosti mé řeknou: Hospodine, kdo jest podobný tobě, ješto vytrhuješ ztrápeného z moci toho, kterýž nad něj silnější jest, tolikéž chudého a nuzného od toho, kterýž ho násilně loupí?
Gbogbo egungun mi yóò wí pé, “Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa? O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ, tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
11 Povstávají svědkové lživí, a na to, o čemž nevím, dotazují se mne.
Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde; wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.
12 Zlým za dobré mi se odplacují, duše mé zbaviti mne chtíce,
Wọ́n fi búburú san ìre fún mi; láti sọ ọkàn mi di òfo.
13 Ježto já v nemoci jejich pytlem jsem se přiodíval, duši svou postem trápil, a sám u sebe za ně často se modlil.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀; mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú. Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;
14 Jako k příteli, jako k bratru vlastnímu jsem chodíval; jakožto ten, kterýž po matce kvílí, smutek nesa, tak jsem se ponižoval.
èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀ bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni. Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́ bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.
15 Ale oni z mého zlého radovali se, a rotili se; shromažďovali se proti mně i ti nejnevážnější, o čemž jsem nevěděl; utrhali mi, a nemlčeli.
Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ; wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀. Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.
16 S pokrytci, posměvači, fatkáři škřipěli na mne zuby svými.
Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.
17 Pane, dlouho-liž se dívati budeš? Vytrhni duši mou od zhouby jejich, od lvů jedinkou mou.
Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ? Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn, àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.
18 I budu tě oslavovati v shromáždění velikém, ve množství lidu tebe chváliti budu.
Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá; èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
19 Nechažť se nade mnou neradují ti, kteříž bezprávně ke mně se nepřátelsky mají; ti, kteříž mne nenávidí bez příčiny, ať nemhourají očima.
Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ lórí ì mi; bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.
20 Neboť nemluví ku pokoji, ale proti pokojným na zemi slova lstivá vymýšlejí.
Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà, ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.
21 Anobrž rozdírají proti mně ústa svá, a říkají: Hahá, hahá, jižť vidí oko naše.
Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà! Ojú wa sì ti rí i.”
22 Vidíš ty to, Hospodine, neodmlčujž se, Pane, nevzdalujž se ode mne.
Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́! Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!
23 Probudiž se a prociť k soudu mému, Bože můj a Pane můj, k obhájení pře mé.
Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi, àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!
24 Suď mne podlé spravedlnosti své, Hospodine Bože můj, ať se neradují nade mnou.
Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!
25 Ať neříkají v srdci svém: Měhoděk duši naší; ať neříkají: Sehltili jsme jej.
Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!” Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”
26 Ale ať se zahanbí a zapýří všickni radující se mému zlému, v stud a hanbu ať jsou oblečeni ti, kteříž se zpínají proti mně.
Kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀, àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.
27 Ti pak, kteříž mi přejí mé spravedlnosti, ať plésají, a radují se, a ať říkají vždycky: Veleslaven budiž Hospodin, kterýž přeje pokoje služebníku svému.
Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú; kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa, sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”
28 I můj jazyk ohlašovati bude spravedlnost tvou, a na každý den chválu tvou.
Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ, àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.

< Žalmy 35 >