< Žalmy 116 >

1 Miluji Hospodina, proto že vyslýchá hlas můj a pokorné modlitby mé.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Nebo naklonil ucha svého ke mně, když jsem ho vzýval ve dnech svých.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Obklíčilyť mne byly bolesti smrti, a úzkosti hrobu potkaly mne; sevření a truchlost přišla na mne. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 I vzýval jsem jméno Hospodinovo, řka: Prosím, ó Hospodine, vysvoboď duši mou.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 Milostivý Hospodin a spravedlivý, Bůh náš lítostivý.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 Ostříhá sprostných Hospodin; znuzen jsem byl, a spomohl mi.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Navratiž se, duše má, do odpočinutí svého, poněvadž Hospodin jest dobrodince tvůj.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Nebo jsi vytrhl duši mou od smrti, oči mé od slz, nohu mou od poklesnutí.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Ustavičně choditi budu před Hospodinem v zemi živých.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 Uvěřil jsem, protož i mluvil jsem, ačkoli jsem byl velmi ztrápený.
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Já jsem byl řekl v pospíchání: Všeliký člověk jest lhář.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Čím se odplatím Hospodinu za všecka dobrodiní jeho mně učiněná?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 Kalich mnohého spasení vezmu, a jméno Hospodinovo vzývati budu.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Sliby své Hospodinu splním, teď přede vším lidem jeho.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Drahá jest před očima Hospodinovýma smrt svatých jeho.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Ó Hospodine, že jsem služebník tvůj, služebník, pravím, tvůj, syn děvky tvé, rozvázal jsi svazky mé.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Tobě obětovati budu obět díků činění, a jméno Hospodinovo vzývati budu.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Sliby své Hospodinu splním, teď přede vším lidem jeho,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 V síňcích domu Hospodinova, u prostřed tebe, Jeruzaléme. Halelujah.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Žalmy 116 >