< 4 Mojžišova 27 >

1 Tehdy přistoupily dcery Salfada, syna Heferova, syna Galád, syna Machir, syna Manasse, z pokolení Manasse, syna Jozefova. Tato pak jsou jména dcer jeho: Mahla, Noa, Hegla, Melcha a Tersa.
Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
2 A postavily se před Mojžíšem a před Eleazarem knězem, i před knížaty a vším množstvím, u dveří stánku úmluvy, a řekly:
Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
3 Otec náš umřel na poušti, kterýž však nebyl z spolku těch, kteříž se zrotili proti Hospodinu v rotě Chóre; nebo pro hřích svůj umřel, synů žádných nemaje.
“Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
4 Což vyhlazeno býti má jméno otce našeho z čeledi jeho, proto že neměl syna? Dej nám dědictví mezi bratřími otce našeho.
Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
5 I vznesl tu věc Mojžíš na Hospodina.
Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
6 Kterýž odpověděl Mojžíšovi, řka:
Olúwa sì wí fún un pé,
7 Dobře mluví dcery Salfad. Dejž jim bez odporu právo dědictví mezi bratřími otce jejich, a přenes dědictví otce jejich na ně.
“Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
8 K synům pak Izraelským toto mluviti budeš: Když by kdo umřel, nemaje syna, tedy přenesete dědictví jeho na dceru jeho.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
9 Pakli by ani dcery neměl, tedy dáte dědictví jeho bratřím jeho.
Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
10 Pakli by ani bratří neměl, tedy dáte dědictví jeho bratřím otce jeho.
Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
11 Pakli by ani strýců neměl, tedy dáte dědictví jeho příteli jeho, kterýž jest nejbližší jemu v rodu jeho, aby dědičně obdržel je. A bude to synům Izraelským za ustanovení soudné, jakož přikázal Hospodin Mojžíšovi.
Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
12 Řekl také Hospodin Mojžíšovi: Vstup na horu tuto Abarim, a spatř zemi, kterouž jsem dal synům Izraelským.
Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
13 A když spatříš ji, připojen budeš k lidu svému i ty, jako připojen jest Aron bratr tvůj,
Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
14 Poněvadž jste odporovali řeči mé na poušti Tsin, při odporování všeho množství, kdež jste mne měli posvětiti při vodách před očima jejich. To jsou ty vody sváru v Kádes, na poušti Tsin.
nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
15 I řekl Mojžíš Hospodinu, řka:
Mose sọ fún Olúwa wí pé,
16 Opatřiž Hospodin Bůh duchů, Bůh všelikého těla, shromáždění toto mužem hodným,
“Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
17 Kterýž by vycházel před nimi, a kterýž by vcházel před nimi, kterýž by vyvodil a zase uvodil je, aby nebylo shromáždění Hospodinovo jako ovce, kteréž nemají pastýře.
láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
18 I řekl Hospodin Mojžíšovi: Vezmi k sobě Jozue, syna Nun, muže, v kterémž jest duch můj, a vlož ruku svou na něj.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
19 A postavě jej před Eleazarem knězem a přede vším shromážděním, dáš jemu naučení před očima jejich,
Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
20 A udělíš jemu slávy své, aby ho poslouchalo všecko množství synů Izraelských.
Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
21 Kterýž před Eleazarem knězem postavě se, ptáti se ho bude na soud urim před Hospodinem. K rozkazu jeho vyjdou, a k rozkazu jeho vejdou, on i všickni synové Izraelští s ním, a všecko shromáždění.
Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
22 I učinil Mojžíš tak, jakž mu byl rozkázal Hospodin, a pojav Jozue, postavil jej před Eleazarem knězem a přede vším shromážděním.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
23 A vloživ ruce své na něj, dal jemu naučení, jakž mluvil Hospodin skrze Mojžíše.
Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< 4 Mojžišova 27 >