< Nehemiáš 8 >
1 I shromáždil se všecken lid jednomyslně do ulice, kteráž jest proti bráně vodné, a řekli Ezdrášovi učiteli, aby přinesl knihu zákona Mojžíšova, kterýž vydal Hospodin lidu Izraelskému.
gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
2 Tedy přinesl Ezdráš kněz zákon před to shromáždění mužů i žen i všech, kteříž by rozumně poslouchati mohli, prvního dne měsíce sedmého.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
3 I četl v něm na té ulici, kteráž jest proti bráně vodné, od jitra až do poledne, při přítomnosti mužů i žen, i kteřížkoli rozuměti mohli. A uši všeho lidu obráceny byly k knize zákona.
Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
4 Stál pak Ezdráš učitel na kazatelnici dřevěné, kterouž byli udělali k té věci, a stál podlé něho Mattitiáš, Sema, Anaiáš, Uriáš, Helkiáš a Maaseiáš, po pravé ruce jeho, po levé pak Pedaiáš, Misael, Malkiáš, Chasum, Chasbaddana, Zachariáš a Mesullam.
Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
5 Otevřel tedy Ezdráš knihu před očima všeho lidu, (nebo výše stál než všecken lid). Kterouž jakž otevřel, povstal všecken lid.
Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
6 I dobrořečil Ezdráš Hospodinu Bohu velikému, a všecken lid odpovídal: Amen, amen, pozdvihujíce rukou svých, a skloňujíce hlavy, poklonu učinili Hospodinu tváří k zemi.
Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
7 Tak i Jesua, Báni, Serebiáš, Jamin, Akkub, Sabbetai, Hodiáš, Maaseiáš, Kelita, Azariáš, Jozabad, Chanan, Pelaiáš, a Levítové vyučovali lid zákonu. Lid pak byl na místě svém.
Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
8 Nebo čtli v té knize v zákoně Božím srozumitelně, a vykládajíce smysl, vysvětlovali to, což čtli.
Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
9 Potom řekl Nehemiáš, jinak Tirsata, a Ezdráš kněz, učitel, a Levítové, kteříž lid vyučovali, všemu lidu: Den tento posvěcený jest Hospodinu Bohu vašemu, nekvěltež, ani plačte. (Nebo plakal všecken lid, když slyšeli slova zákona.)
Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
10 Ale jděte, řekl jim, a jezte tučné věci, a píte sladké, sdílejíce se s těmi, kteříž nemají nic připraveno. Den zajisté tento svatý jest Pánu našemu, protož nermuťtež se, nýbrž radost Hospodinova budiž síla vaše.
Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
11 A když tak Levítové pospokojili všeho lidu, mluvíce: Mlčte, nebo den svatý jest, a nermuťte se,
Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
12 Odšel všecken lid, aby jedli a pili, a aby se sdíleli. I veselili se velmi, proto že srozuměli slovům těm, kteráž jim v známost uvedli.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
13 Potom nazejtří sešla se knížata čeledí otcovských ze všeho lidu, kněží i Levítové k Ezdrášovi učiteli, aby vyrozuměli slovům zákona.
Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
14 Našli pak napsáno v zákoně, že přikázal Hospodin skrze Mojžíše, aby bydlili synové Izraelští v stáncích na slavnost měsíce sedmého,
Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
15 A aby dali prohlásiti a provolati po všech městech svých i v Jeruzalémě, řkouce: Vyjděte na hory, a přineste ratolestí olivových a ratolestí dříví borového, a ratolestí myrtových, i ratolestí palmových, a ratolestí dříví hustého, abyste nadělali stánků, tak jakž psáno jest.
àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
16 Protož vyšed lid, přinesli a nadělali sobě stánků, jeden každý na střeše své, i v síních svých, i v síních domu Božího, i v ulici brány vodné, i v ulici brány Efraim.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
17 A tak nadělali stánků všecko shromáždění těch, jenž se vrátili z zajetí, a bydlili v nich, (ačkoli nečinili tak synové Izraelští ode dnů Jozue syna Nun, až do dne toho). I byla radost velmi veliká.
Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
18 Četl pak v knize zákona Božího na každý den, od prvního dne až do posledního, a drželi slavnost za sedm dní. Osmého pak dne byl svátek podlé obyčeje.
Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.