< Sudcov 21 >

1 Nadto každý z mužů Izraelských přísahou se byli zavázali v Masfa, řkouce: Žádný z nás nedá dcery své Beniaminským za manželku.
Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
2 Protož všel lid do domu Boha silného, a seděli tam až do večera před Bohem, a pozdvihše hlasu svého, plakali pláčem velikým.
Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
3 A řekli: Proč Hospodine, Bože Izraelský, stalo se toto v Izraeli, aby dnes ubylo jedno pokolení z Izraele?
Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
4 Nazejtří pak ráno vstal lid, a vzdělali tam oltář, a obětovali oběti zápalné a pokojné.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
5 Řekli pak synové Izraelští: Jest-li kdo, ješto nepřišel do shromáždění tohoto ze všech pokolení Izraelských k Hospodinu? (Nebo se byli velice zapřisáhli proti tomu, kdož by nepřišel k Hospodinu do Masfa, řkouce: Bez milosti ať umře.
Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
6 Nebo litujíce synové Izraelští Beniamina bratra svého, řekli: Dnes vyhlazeno jest jedno pokolení z Izraele.
Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
7 Jakž tedy učiníme s těmi ostatky, aby ženy měli, poněvadž jsme se přísahou zavázali skrze Hospodina, že jim nedáme dcer svých za manželky?)
Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
8 Řekli tedy: Jest-li kdo z pokolení Izraelských, ješto nepřišel k Hospodinu do Masfa? A aj, nepřišel byl žádný do vojska z Jábes Galád do shromáždění.
Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
9 Nebo když sečten byl lid, a aj, nebylo tam žádného z obyvatelů Jábes Galád.
Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
10 Protož poslalo tam shromáždění to dvanácte tisíc mužů nejsilnějších, a přikázali jim, řkouce: Jděte a pobíte obyvatele Jábes Galád ostrostí meče, ženy i děti.
Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
11 Toto pak učiníte: Všecky mužského pohlaví, a každou ženu, kteráž muže poznala, zamordujete.
Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
12 Nalezli tedy mezi obyvateli Jábes Galád čtyři sta děveček panen, kteréž nepoznaly muže, a přivedli je do vojska v Sílo, kteréž bylo v zemi Kananejské.
Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
13 Tedy poslalo všecko to shromáždění, a mluvili k synům Beniamin, kteříž byli v skále Remmon, a povolali jich v pokoji.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
14 Protož navrátili se Beniaminští toho času. I dali jim ženy, kteréž živé zachovali z žen Jábes Galád, ale ani tak se jim nedostávalo jich.
Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
15 Lidu pak líto bylo Beniamina, proto že učinil Hospodin mezeru v pokoleních Izraelských.
Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
16 Řekli tedy starší shromáždění toho: Jak učiníme s těmi pozůstalými, aby měli ženy? Nebo vyhlazeny jsou ženy z pokolení Beniamin.
Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
17 Řekli také: Dědictví Beniaminovo pozůstalým náleží, aby nezahynulo pokolení z Izraele.
Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
18 My pak nemůžeme jim dáti dcer svých za manželky; (nebo se byli přísahou zavázali synové Izraelští, řkouce: Zlořečený buď, kdož by dal manželku synům Beniamin.)
Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
19 Potom řekli: Aj, slavnost Hospodinova bývá v Sílo každého roku na místě, kteréž jest s půlnoční strany domu Boha silného, k východu slunce cestě, kterouž se chodí od domu Boha silného do Sichem, a Lebnu jest na poledne.
Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
20 Přikázali tedy synům Beniamin, řkouce: Jděte a skrejte se v vinicích.
Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
21 A šetřte, a aj, když vyjdou dcery Sílo plésati v houfích, tedy vyskočíte z vinic a pochytíte sobě každý manželku svou ze dcer Sílo, a odejdete do země Beniamin.
kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
22 Když pak přijdou otcové jejich aneb bratří jejich, aby se před námi soudili, tedy řekneme jim: Slitujte se nad námi místo nich, nebo v té válce nevzali jsme pro každého z nich manželky; také jste vy jim nedali jich, a tak nebudete nic vinni.
Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
23 Tedy učinili tak synové Beniamin, a přivedli sobě manželky vedlé počtu svého z těch plésajících, kteréž uchvátili; a odšedše, navrátili se k dědictví svému, a vzdělavše zase města svá, bydlili v nich.
Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
24 A tak odešli odtud synové Izraelští toho času, jeden každý k svému pokolení a k čeledi své; a vrátili se odtud jeden každý k dědictví svému.
Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
25 Těch dnů nebylo krále v Izraeli, ale každý, což se mu vidělo, to činil.
Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.

< Sudcov 21 >