< Józua 20 >

1 I mluvil Hospodin k Jozue, řka:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 Mluv k synům Izraelským, a rci jim: Oddejte z těch měst vašich města útočišťná, o nichž jsem mluvil vám skrze Mojžíše,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
3 Aby tam utekl vražedlník, kterýž by zabil člověka nechtě a z nevědomí. I budou vám útočiště před přítelem zabitého.
kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
4 A když by utekl do jednoho z těch měst, stane u vrat v bráně města, a oznámí starším města toho při svou; i přijmou ho do města k sobě, a dají mu místo, i bydliti bude u nich.
Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
5 Když by jej pak honil přítel toho zabitého, nevydají vražedlníka v ruce jeho; nebo nechtě udeřil bližního svého, neměv ho prvé v nenávisti.
Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
6 A bydliti bude v městě tom, dokudž nestane před shromážděním k soudu, až do smrti kněze velikého, kterýž by byl toho času; nebo tehdáž navrátí se vražedlník, a přijde do města svého a do domu svého, do města, odkudž utekl.
Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
7 I oddělili Kádes v Galilei na hoře Neftalím, a Sichem na hoře Efraim, a město Arbe, (jenž jest Hebron, ) na hoře Juda.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
8 Před Jordánem pak proti Jerichu k východu oddělili Bozor, kteréž leží na poušti v rovině pokolení Rubenova, a Rámot v Galád z pokolení Gádova, a Golan v Bázan z pokolení Manassesova.
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
9 Ta města byla útočišťná všechněm synům Izraelským, i příchozímu, kterýž pohostinu jest mezi nimi, aby utekl tam, kdo by koli zabil někoho nechtě, a nesešel od ruky přítele toho zabitého prvé, než by stál před shromážděním.
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.

< Józua 20 >