< Jób 5 >

1 Zavolejž tedy, dá-liť kdo odpověd? A k kterému se z svatých obrátíš?
“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
2 Pakli k bláznu, zahubí ho rozhněvání, a nesmyslného zabije prchlivost.
Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
3 Jáť jsem viděl blázna, an se vkořenil, ale hned jsem zle tušil příbytku jeho, řka:
Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
4 Vzdáleniť jsou synové jeho od spasení; nebo potříni budou v bráně, aniž bude, kdo by je vytrhl.
Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
5 Obilé jeho zžíře hladovitý, a i z prostřed trní je vychvátí; nadto sehltí násilník statek takových.
Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
6 Neboť nepochází z prachu trápení, aniž se z země pučí bída.
Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
7 Ale člověk rodí se k bídě, tak jako jiskry z uhlí zhůru létají.
Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 Jistě žeť bych já hledal Boha silného, a jemu bych předložil při svou,
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 Kterýž činí věci veliké, nezpytatelné, divné, a jimž počtu není,
Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
10 Kterýž dává déšť na zemi, a spouští vody na pole,
Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
11 Kterýž sází opovržené na místě vysokém, a žalostící vyvyšuje spasením,
Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 Kterýž v nic obrací myšlení chytráků, tak aby nemohli k skutku přivésti ruce jejich ničeho,
Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
13 Kterýž lapá moudré v chytrosti jejich; nebo rada převrácených bláznová bývá.
Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
14 Ve dne motají se jako ve tmách, a jako v noci šámají o poledni.
Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
15 Kterýž zachovává od meče a od úst jejich, a chudého od ruky násilníka.
Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Máť zajisté nuzný naději, ale nepravost musí zacpati ústa svá.
Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
17 Aj, jak blahoslavený jest člověk, kteréhož tresce Bůh! A protož káráním Všemohoucího nepohrdej.
“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
18 Onť zajisté uráží, on i obvazuje; raní, ruka jeho také léčí.
Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
19 Z šesti úzkostí vysvobodil by tebe, ano i v sedmi nedotklo by se tebe zlé.
Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
20 V hladu vykoupil by tě od smrti, a v boji od moci meče.
Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 Když utrhá jazyk, byl bys skryt, aniž bys se bál zhouby, když by přišla.
A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
22 Zhouba a hlad buď tobě za smích, a nestrachuj se ani líté zvěři zemské.
Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
23 Nebo s kamením polním příměří tvé, a zvěř lítá polní pokoj zachová k tobě.
Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
24 A shledáš, žeť stánek tvůj bude bezpečný, a navrátíš se zase k příbytku svému, a nezhřešíš.
Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
25 Shledáš také, žeť se rozmnoží símě tvé, a potomci tvoji jako bylina zemská.
Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
26 Vejdeš v šedinách do hrobu, tak jako odnášíno bývá zralé obilí časem svým.
Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
27 Aj, toť jsme vyhledali, a takť jest; poslechniž toho, a schovej sobě to.
“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

< Jób 5 >