< Jeremiáš 50 >

1 Slovo, kteréž mluvil Hospodin proti Babylonu a proti zemi Kaldejské skrze Jeremiáše proroka:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 Oznamujte mezi národy a rozhlašujte, zdvihněte korouhev, rozhlašujte, netajte, rcete: Vzat bude Babylon, zahanben bude Bél, potřín bude Merodach, zahanbeny budou modly jeho, potříni budou ukydaní bohové jeho.
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Nebo přitáhne na něj národ od půlnoci, kterýž obrátí zemi jeho v pustinu, tak že nebude obyvatele v ní. Od člověka až do hovada vystěhují se, odejdou.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 V těch dnech a toho času, dí Hospodin, přijdou synové Izraelští, oni i synové Judští spolu; plačíce, ochotně půjdou, a Hospodina Boha svého hledati budou.
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 Na cestu k Sionu ptáti se budou, a obrátíce se tam, řeknou: Poďte a připojte se k Hospodinu smlouvou věčnou, nepřicházející v zapomenutí.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 Ovce hynoucí jsou lid můj, pastýři jejich působí to, aby bloudily, a po horách se toulaly, s hůry na pahrbek chodily, zapomenuvše na příbytky své.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Všickni, kteříž je nalézají, zžírají je, a nepřátelé jejich říkají: Nebudeme nic vinni, proto že hřeší proti Hospodinu. Příbytek spravedlnosti a otců jejich naděje jest Hospodin.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 Vystěhujte se z prostředku Babylona, a z země Kaldejské vyjděte, a buďte jako kozlové před stádem.
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 Nebo aj, já vzbudím a přivedu na Babylon shromáždění národů velikých z země půlnoční, kteřížto sšikují se proti němu, i bude dobyt odtud. Kterýchžto střely jsou jako silného, jenž sirobu uvodí; žádnáť se nenavrátí na prázdno.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 I bude země Kaldejských v loupež; všickni, kteříž ji loupiti budou, nasytí se, dí Hospodin.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 Proto že se veselíte, proto že pléšete, ó dráči dědictví mého, proto že jste zbujněli jako jalovice vytylá, a provyskujete jako rekové,
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Zahanbena bude matka vaše velice, a zapýří se rodička vaše: Aj, nejzadnější z národů, poušť, země vyprahlá a pustina.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Pro prchlivost Hospodinovu nebude v ní bydleno, ale velmi spustne všecko. Každý, kdož půjde mimo Babylon, užasne se, a diviti se bude nade všemi ranami jeho.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 Sšikujte se proti Babylonu vůkol všickni, kteříž natahujete lučiště, střílejte proti němu, nelitujte střely; nebo hřešil proti Hospodinu.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Křičte proti němu vůkol: Poddal se, padli základové jeho, pobořeny jsou zdi jeho. Nebo pomsta Hospodinova jest, uveďte pomstu na něj; jakž činíval, učiňte jemu.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Vypleňte rozsevače z Babylona, i držícího srp v čas žně; před mečem hubícím každý nechť se k lidu svému obrátí, a každý do země své nechť uteče.
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Hovádko zahnané jest Izrael, kteréž lvové splašili. Nejprvé zžíral je král Assyrský, tento pak poslednější, Nabuchodonozor král Babylonský, kosti jeho potřel.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Protož toto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Aj, já navštívím krále Babylonského i zemi jeho, jako jsem navštívil krále Assyrského.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 A přivedu zase Izraele do příbytku jeho, aby se pásl na Karmeli a Bázan, a na hoře Efraim, a v Galád aby se sytila duše jeho.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 V těch dnech a toho času, dí Hospodin, byla-li by vyhledávána nepravost Izraelova, nebude žádné, a hříchové Judovi, však nebudou nalezení; nebo odpustím těm, kteréž pozůstavím.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 Proti té zemi zpurných táhni, a proti obyvatelům pomsty; zhub je a zahlaď jako proklaté i utíkající, dí Hospodin. Učiniž, pravím, všecko, jakž přikazuji tobě,
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Ať jest hluk boje v té zemi a potření veliké.
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Jakž by posekáno a polámáno býti mohlo kladivo vší země? Jak by k užasnutí Babylon býti mohl mezi národy?
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Polékl jsem na tě, ó Babylone, pročež vzat budeš, než zvíš. Nalezen, ano i polapen budeš, proto že jsi směl potýkati se s Hospodinem.
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Otevřel Hospodin poklad svůj, a vynesl nástroje hněvu svého; nebo dílo toto jest Panovníka Hospodina zástupů v zemi Kaldejské.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Přitáhněte na ni od konce země, zotvírejte obilnice její, šlapejte po ní jako po stozích, a zahlaďte ji jako proklatou, tak aby z ní ničeho nepozůstalo.
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Zbíte mečem všecky volky její, nechť sstoupí k zabití; běda jim, když přijde den jejich, čas navštívení jejich.
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Hlas utíkajících a ucházejících z země babylonské, aby oznámili na Sionu pomstu Hospodina Boha našeho, pomštění chrámu jeho.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 Shromažďte proti babylonu nejudatnější, všickni natahující lučiště, položte se proti němu vůkol, ať nelze jemu ujíti. Odplaťte jemu podlé skutků jeho, všecko, jakž dělával, učiňte jemu; nebo proti Hospodinu pýchal, proti Svatému Izraelskému.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Protož padnou mládenci jeho na ulicích jeho, a všickni muži bojovní jeho vypléněni budou v ten den, dí Hospodin.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 Aj, já jsem proti tobě, ó pýcho, praví Panovník Hospodin zástupů; neboť přišel den tvůj, čas, abych tě navštívil.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Poklesne se zajisté ten pyšný a padne, a nebude žádného, kdo by jej zdvihl; a zanítím oheň v městech jeho, kterýžto zžíře všecka vůkolí jeho.
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 Takto praví Hospodin zástupů: Utištěni jsou synové Izraelští, i s syny Judskými, a všickni, kteříž je zjímali, drží je, nechtí propustiti jich.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Ale vykupitel jejich silný, jehož jméno jest Hospodin zástupů, jistotně povede při jejich, aby pokoj způsobil této zemi, a pohnul obyvateli Babylonskými.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 Meč na Kaldejské, dí Hospodin, a na obyvatele Babylonské, i na knížata jeho i na mudrce jeho.
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Meč na lháře, aby se zbláznili, meč na silné jeho, aby potříni byli.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Meč na koně jeho a na vozy jeho, i na všecku tu směsici, kteráž jest u prostřed něho, aby byli jako ženy; meč na poklady jeho, aby rozchvátáni byli.
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Sucho na vody jeho, aby vyschly; nebo země plná jest rytin, a při modlách bláznívají.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 Protož bydliti budou tam šelmy s hroznými potvorami, bydliti budou v ní i mladé sovy; a nebude tam bydleno na věky, ani přebýváno od národu až do pronárodu.
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Podobná bude k podvrácení hroznému Sodomy a Gomory i sousedů jejich, dí Hospodin; neosadí se tam žádný, aniž bydliti bude v ní syn člověka.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 Aj, lid přitáhne od půlnoci, a národ veliký, i králové znamenití, vzbuzeni jsouce od stran země.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Lučiště a kopí pochytí, ukrutní budou, a neslitují se; hlas jejich jako moře zvučeti bude, a na koních pojedou, sšikovaní jako muž udatný k boji proti tobě, ó dcero Babylonská.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 Král Babylonský jakž uslyší pověst o nich, opadnou ruce jeho, úzkost zachvátí jej, bolest jako rodičku.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Aj, jako lev vystupuje, více než zdutí Jordána proti příbytku Nejsilnějšího, a však v okamžení zaženu jej z této země, a toho, kterýž jest vyvolený, ustanovím nad ní. Nebo kdo jest mně rovný? A kdo mi složí rok? A kdo jest ten pastýř, kterýž by se postavil proti mně?
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Protož slyšte radu Hospodinovu, kterouž zavřel o Babylonu, a to, což myslil proti zemi Kaldejské: Zajisté žeť je vyvlekou nejmenší tohoto stáda, zajisté že je popléní i příbytek jejich.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 Od zvuku při dobývání Babylona třásti se bude ta země, a křik mezi národy slyšán bude.
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jeremiáš 50 >