< Ezechiel 8 >
1 I stalo se léta šestého, v pátý den šestého měsíce, že jsem seděl v domě svém, a starší Judští seděli přede mnou. I připadla na mne tu ruka Panovníka Hospodina.
Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
2 A viděl jsem, a aj, podobenství na pohledění jako oheň. Od bedr jeho dolů oheň, od bedr pak jeho vzhůru na pohledění jako blesk, na pohledění jako nějaká velmi prudká světlost.
Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
3 Tedy vztáh podobenství ruky, vzal mne za kštici hlavy mé, a vyzdvihl mne Duch mezi nebe a mezi zemi, a uvedl mne do Jeruzaléma u viděních Božích, k vratům brány vnitřní, kteráž patří na půlnoci, kdež byla stolice modly k horlivosti a k zůřivosti popouzející.
Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
4 A aj, sláva Boha Izraelského byla tam na pohledění jako ta, kterouž jsem viděl v údolí.
Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
5 I řekl mi: Synu člověčí, pozdvihni nyní očí svých k cestě na půlnoci. Tedy pozdvihl jsem oči svých k cestě na půlnoci, a aj, na půlnoci u brány oltářové ta modla horlení, právě kudyž se vchází.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
6 V tom řekl mi: Synu člověčí, vidíš-liž ty, co tito činí, ohavnosti tak veliké, kteréž činí dům Izraelský tuto, tak že se vzdáliti musím od svatyně své? Ale obrátě se, uzříš ještě větší ohavnosti.
Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
7 I přivedl mne ke dveřům síně, kdež jsem uzřel, a aj, díra jedna byla v stěně.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
8 A řekl mi: Synu člověčí, kopej medle tu stěnu. I kopal jsem stěnu, a aj, dvéře jedny.
Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
9 Tedy řekl mi: Vejdi, a viz ohavnosti tyto nejhorší, kteréž oni činí zde.
Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
10 Protož všed, uzřel jsem, a aj, všeliké podobenství zeměplazů a hovad ohyzdných, i všech ukydaných bohů domu Izraelského vyryto bylo na stěně vůkol a vůkol.
Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
11 A sedmdesáte mužů z starších domu Izraelského, s Jazaniášem synem Safanovým, stojícím u prostřed nich, stáli před nimi, maje každý kadidlnici svou v ruce své, tak že hustý oblak kadění vzhůru vstupoval.
Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
12 I řekl mi: Viděl-lis, synu člověčí, co starší domu Izraelského činí ve tmě, jeden každý v pokojích svých malovaných? Nebo říkají: Nikoli na nás nepatří Hospodin, opustil Hospodin zemi.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
13 Dále mi řekl: Obrátě se, uzříš ještě větší ohavnosti, kteréž oni činí.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
14 I přivedl mne k vratům brány domu Hospodinova, kteráž jest na půlnoci, a aj, ženy seděly tam, plačíce Tammuze.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
15 I řekl mi: Viděl-lis, synu člověčí? Obrátě se, uzříš ještě větší ohavnosti nad tyto.
Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
16 Tedy uvedl mne do síně domu Hospodinova vnitřní, a aj, u vrat chrámu Hospodinova, mezi síňcí a oltářem bylo okolo pětmecítma mužů, jejichž záda byla k chrámu Hospodinovu, tváři pak jejich k východu, kteříž klaněli se proti východu slunce.
Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
17 I řekl mi: Viděl-lis, synu člověčí? Zdali lehká věc jest domu Judovu, aby činili ohavnosti tyto, kteréž činí zde? Nebo naplnivše zemi nátiskem, obrátili se, aby mne popouzeli, a aj, přičinějí ratolest vinnou k nosům svým.
Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
18 Protož i já také učiním podlé prchlivosti; neslitujeť se oko mé, aniž se smiluji. I budou volati v uši mé hlasem velikým, a nevyslyším jich.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”