< 5 Mojžišova 6 >

1 Toto pak jest přikázaní, ustanovení a soudové, kteréž přikázal Hospodin Bůh váš, abych učil vás, abyste činili je v zemi, do kteréž jdete k dědičnému držení jí,
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
2 Abys se bál Hospodina Boha svého, ostříhaje všech ustanovení jeho a přikázaní jeho, kteráž já přikazuji tobě, ty i syn tvůj i vnuk tvůj, po všecky dny života svého, aby se prodlili dnové tvoji.
Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
3 Slyšiž tedy, Izraeli, a hleď tak skutečně činiti, aby tobě dobře bylo, a abyste se velmi rozmnožili, (jakož mluvil Hospodin Bůh otců tvých tobě, ) v zemi oplývající mlékem a strdí.
Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
4 Slyš, Izraeli, Hospodin Bůh náš, Hospodin jeden jest.
Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
5 Protož milovati budeš Hospodina Boha svého z celého srdce svého, a ze vší duše své, a ze vší síly své.
Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
6 A budou slova tato, kteráž já přikazuji tobě dnes, v srdci tvém.
Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
7 A budeš je často opětovati synům svým, a mluviti o nich, když sedneš v domě svém, když půjdeš cestou, a léhaje i vstávaje.
Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
8 Uvážeš je za znamení na ruce své, a jako náčelník mezi očima svýma.
Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
9 Napíšeš je také na veřejích domu svého a na branách svých.
Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
10 A když tě uvede Hospodin Bůh tvůj do země, kterouž s přísahou zaslíbil otcům tvým, Abrahamovi, Izákovi a Jákobovi, že ji tobě dá, i města veliká a výborná, kterýchžs nestavěl,
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
11 A domy plné všech dobrých věcí, kterýchž jsi nenaplnil, a studnice vykopané, kterýchž jsi nekopal, a vinice i olivoví, jichž jsi neštípil, a jedl bys a nasytil se:
àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
12 Varuj se, abys nezapomenul na Hospodina, kterýž tě vyvedl z země Egyptské, z poroby těžké.
ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
13 Hospodina Boha svého báti se budeš, a jemu sloužiti, a ve jméno jeho přisahati.
Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
14 Neodejdeš po bozích cizích, z bohů jiných národů, kteříž vůkol vás jsou,
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
15 (Nebo Bůh silný, horlivý, Hospodin tvůj u prostřed tebe jest, ) aby se neroznítila prchlivost Hospodina Boha tvého na tebe, a shladil by tě se svrchku země.
torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
16 Nebudete pokoušeti Hospodina Boha svého, jako jste pokoušeli v Massah.
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
17 Pilně ostříhejte přikázaní Hospodina Boha svého, a svědectví jeho, i ustanovení jeho, kteráž přikázal tobě,
Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
18 A čiň to, což pravého a dobrého jest před očima Hospodinovýma, aby tobě dobře bylo, a vejda, abys dědičně obdržel zemi výbornou, kterouž s přísahou zaslíbil Hospodin otcům tvým,
Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
19 Aby vypudil všecky nepřátely tvé od tváři tvé, jakož mluvil Hospodin.
Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
20 Když by se potom syn tvůj otázal tebe, řka: Co jsou to za svědectví a ustanovení i soudy, kteréž přikázal Hospodin Bůh náš vám?
Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
21 Tedy díš synu svému: Služebníci jsme byli Faraonovi v Egyptě, i vyvedl nás Hospodin z Egypta v ruce silné.
Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
22 A činil Hospodin znamení a zázraky veliké a škodlivé v Egyptě proti Faraonovi, a proti všemu domu jeho před očima našima,
Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
23 Nás pak vyvedl odtud, aby uvedl nás, a dal nám zemi, kterouž s přísahou zaslíbil otcům našim.
Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
24 Protož přikázal nám Hospodin, abychom ostříhali všech ustanovení těchto, bojíce se Hospodina Boha svého, aby nám dobře bylo po všecky dny, a aby zachoval nás při životu, jakž to činí i v dnešní den.
Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
25 A spravedlnost míti budeme, když ostříhati budeme a činiti všecka přikázaní tato před Hospodinem Bohem svým, jakož přikázal nám.
Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”

< 5 Mojžišova 6 >