< 5 Mojžišova 3 >

1 Potom obrátivše se, táhli jsme cestou k Bázan. I vytáhl Og, král Bázan, proti nám, on i všecken lid jeho k bitvě do Edrei.
Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
2 I řekl mi Hospodin: Neboj se ho, nebo v ruce tvé dal jsem jej, i všecken lid jeho i zemi jeho, a učiníš jemu tak, jako jsi učinil Seonovi, králi Amorejskému, kterýž bydlil v Ezebon.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
3 Dal tedy Hospodin Bůh náš v ruce naše i Oga, krále Bázan, a všecken lid jeho, i porazili jsme jej, tak že jsme nepozůstavili po něm žádného živého.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
4 Dobyli jsme také téhož času všech měst jeho; nebylo města, kteréhož bychom jim neodjali, šedesáte měst, všecku krajinu Argob, království Oga v Bázan.
Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
5 Všecka ta města byla ohražená zdmi vysokými, branami a závorami, kromě měst otevřených, jichž bylo velmi mnoho.
Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
6 A vyplénili jsme je, jako jsme učinili Seonovi, králi Ezebon, vyhladivše všecka města, muže, ženy i dítky.
Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
7 Všecka pak hovada a kořisti měst rozebrali jsme sobě.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
8 Vzali jsme také téhož času zemi z ruky dvou králů Amorejských, kteráž byla před Jordánem, od potoku Arnon až k hoře Hermon,
Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
9 (Sidonští říkají Hermonu Sarion, a Amorejští říkají jemu Sanir, )
(Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
10 Všecka města v kraji, a všecken Galád, a všecken Bázan až do Sálecha a Edrei, kteráž byla města království Og v Bázan.
Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
11 Sám toliko Og, král v Bázan, z jiných obrů byl pozůstal. Aj, lůže jeho, lůže železné, ještě zůstává v Rabbat synů Ammon, devíti loktů zdýlí, a čtyř loket zšíří, jakž jest loket muže.
(Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
12 Když tedy zemi tu obdrželi jsme dědičně toho času, krajinu od Aroer, jenž jest při potoku Arnon, a polovici hory Galád i města její, dal jsem pokolení Ruben a Gád.
Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
13 Ostatek pak Galád a všecku zemi Bázan, království Oga, dal jsem polovici pokolení Manassesova, totiž všecku krajinu Argob, všecku Bázan, kteráž sloula země obrů.
Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
14 Jair, syn Manasse, vzal všecku krajinu Argob, až ku pomezí Gessuri a Machati; pročež nazval zemi Bázan od jména svého Havot Jair až do dnešního dne.
Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
15 Machirovi pak dal jsem Galád.
Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
16 A Rubenovu a Gádovu pokolení dal jsem krajinu od Galád až ku potoku Arnon, polovici potoka s pomezím až ku potoku Jabok, kdež jsou hranice synů Ammonitských,
ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
17 A roviny tyto i Jordán s pomezím od Ceneret až k moři pustému, jenž jest moře slané, ležící pod horou Fazga k východu.
Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
18 A přikázal jsem vám toho času, řka: Hospodin Bůh váš dal vám zemi tuto, abyste ji dědičně obdrželi; vezmouce odění na sebe, půjdete před bratřími vašimi, syny Izraelskými, kteřížkoli silní jste.
Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
19 Toliko ženy vaše a dítky vaše, a dobytek váš, ( nebo vím, že mnoho dobytka máte, ) zůstanou v městech vašich, kteráž jsem dal vám,
Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
20 Dokudž by nedal odpočinutí Hospodin bratřím vašim jako i vám, aby i oni dědičně obdrželi zemi, kterouž Hospodin Bůh váš dává jim za Jordánem; tedy navrátíte se jeden každý k dědictví svému, kteréž jsem dal vám.
títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
21 Také i Jozue přikázal jsem toho času, řka: Oči tvé vidí všecko, co učinil Hospodin Bůh váš těm dvěma králům; takť učiní Hospodin všechněm královstvím, do kterýchž ty půjdeš.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
22 Nebojtež se jich, nebo Hospodin Bůh váš, onť jest, kterýž bojuje za vás.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
23 A tehdáž prosil jsem Hospodina, řka:
Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
24 Panovníče Hospodine, ty jsi počal ukazovati služebníku svému velikost svou a ruku svou přesilnou; nebo kdo jest Bůh silný na nebi aneb na zemi, ješto by činiti mohl skutky podobné tvým, a moci podobné tobě?
“Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
25 Prosím, nechť vejdu a uzřím zemi tu výbornou, kteráž jest za Jordánem, horu tu výbornou i Libán.
Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
26 Pohnul se pak Hospodin na mne pro vás a neuslyšel mne, ale řekl mi: Dosti máš, nemluv více o to se mnou.
Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
27 Vstup na vrch hory Fazga, a pozdvihna očí svých k západu a k půlnoci, ku poledni i k východu, hleď očima svýma; nebo nepřejdeš Jordánu tohoto.
Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
28 Ale přikaž Jozue, a posilň ho, i potvrď ho; nebo půjde před lidem tímto, a on uvede jim v dědictví zemi, kterouž uzříš.
Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
29 I zůstali jsme v údolí naproti Betfegor.
Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.

< 5 Mojžišova 3 >