< 1 Petrův 4 >

1 Poněvadž tedy Kristus trpěl za nás na těle, i vy také týmž myšlením odíni buďte, že ten, kdož trpěl na těle, přestal od hříchu,
Ǹjẹ́ bí Kristi ti jìyà fún wa nípa ti ará, irú kan náà ni kí ẹ̀yin fi hámọ́ra; nítorí ẹni tí ó bá ti jìyà nípa ti ara, ó ti bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.
2 K tomu, aby již nebyl více tělesným žádostem, ale vůli Boží v těle živ, po ten čas, což ho ještě zůstává.
Kí ẹ̀yin má ṣe fi ìgbà ayé yín ìyókù wà nínú ara mọ́ sí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ènìyàn bí kò ṣe sí ìfẹ́ Ọlọ́run.
3 Dostiť jest zajisté nám na tom přeběhlém času života, v němž jsme líbosti pohanů páchali, chodivše v nestydatých chlipnostech, v žádostech, v zbytečném pití vína, v hodování, v opilství, a v ohyzdném modlosloužení.
Nítorí ìgbà tí ó ti kọjá ti tó fún ṣíṣe ìfẹ́ àwọn aláìkọlà, rínrìn nínú ìwà wọ̀bìà, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, ọtí àmupara, ìréde òru, kíkó ẹ̀gbẹ́ ọ̀mùtí, àti ìbọ̀rìṣà tí í ṣe ohun ìríra.
4 A protož když s nimi neběháte k takovému vydávání se v rozpustilost, zdá se jim to cosi nového býti, a rouhají se tomu.
Èyí tí ó yà wọ́n lẹ́nu pé ẹ̀yin kò ba wọn súré sínú irú àṣejù ìwà wọ̀bìà wọ́n, tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ yín ní búburú.
5 Tiť vydadí počet tomu, kterýž hotov jest souditi živé i mrtvé.
Àwọn ẹni tí yóò jíyìn fún ẹni tí ó ti múra láti ṣe ìdájọ́ alààyè àti òkú.
6 Proto jest zajisté i mrtvým kázáno evangelium, aby souzeni byli podlé lidí z strany těla, ale živi byli podlé Boha duchem.
Nítorí èyí ní a sá ṣe wàásù ìyìnrere fún àwọn òkú, kí a lè ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nípa ti ara, ṣùgbọ́n kí wọ́n lè wà láààyè si Ọlọ́run nípa tí Ẹ̀mí.
7 Všemuť se pak přibližuje konec.
Ṣùgbọ́n òpin ohun gbogbo kù sí dẹ̀dẹ̀; nítorí náà kí ẹ̀yin wà ní àìrékọjá, kí ẹ sì máa ṣọ́ra nínú àdúrà.
8 A protož buďte středmí a bedliví k modlitbám. Přede vším pak lásku jedni k druhým opravdovou mějte; nebo láska přikryje množství hříchů.
Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tí ó gbóná láàrín ara yín, nítorí ìfẹ́ ni ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
9 Buďte vespolek přívětiví k hostem, bez reptání.
Ẹ máa ṣe ara yín ni àlejò láìsí ìkùnsínú.
10 Jeden každý jakž vzal dar, tak vespolek tím sobě přisluhujte, jako dobří šafáři rozličné milosti Boží.
Bí olúkúlùkù ti rí ẹ̀bùn gbà, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ máa ṣe ìpín fún ni rẹ̀ láàrín ara yín, bí ìríjú rere tí onírúurú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
11 Mluví-li kdo, mluviž jako řeči Boží; jestliže kdo přisluhuje, čiň to jako z moci, kteréž jemu uděluje Bůh, aby ve všem slaven byl Bůh skrze Jezukrista, kterýž má slávu a císařství na věky věků. Amen. (aiōn g165)
Bí ẹnikẹ́ni ba ń sọ̀rọ̀, kí o máa sọ bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bí ẹnikẹ́ni bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí ó ṣe é bí agbára tí Ọlọ́run fi fún un, kí a lè máa yin Ọlọ́run lógo ní ohun gbogbo nípa Jesu Kristi, ẹni tí ògo àti ìjọba wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
12 Nejmilejší, nebudiž vám divný ten přišlý na vás oheň, pro zkušení vás, jako by se vám něco nového přihodilo.
Olùfẹ́, ẹ má ṣe ka ìdánwò gbígbóná ti ń bẹ láàrín yín láti dán yín wò bi ẹni pé ohun àjèjì ni ó dé bá yín.
13 Ale z toho, že jste účastni utrpení Kristových, radujte se, abyste i při zjevení slávy jeho radovali se s veselím.
Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ̀yin tí jẹ́ alábápín ìyà Kristi, ẹ máa yọ̀, kí ẹ̀yin lè yọ ayọ̀ púpọ̀ nígbà tí a bá fi ògo rẹ̀ hàn.
14 Trpíte-li pohanění pro jméno Kristovo, blahoslavení jste. Nebo Duch ten slávy a Boží na vás odpočívá, kterýž z strany jich zajisté rouhán, ale z strany vaší oslavován bývá.
Bí a bá gàn yín nítorí orúkọ Kristi, ẹni ìbùkún ni yín: nítorí Ẹ̀mí Ògo àti ti Ọlọ́run bà lé yín.
15 Žádný pak z vás netrp jako vražedlník, neb zloděj, neb zločinec, neb všetečný.
Ṣùgbọ́n ẹ má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú yín jìyà bí apànìyàn, tàbí bí olè, tàbí bí olùṣe búburú, tàbí bí ẹni tí ń tojú bọ̀ ọ̀ràn ẹlòmíràn.
16 Jestliže pak jako křesťan, nestyď se za to, ale oslavuj Boha v té částce.
Ṣùgbọ́n bí ó bá jìyà bí Kristiani kí ojú má ṣe tì í, ṣùgbọ́n kí ó kúkú yin Ọlọ́run lógo nítorí ti o orúkọ yìí.
17 Nebo jest čas, aby se začal soud od domu Božího. A poněvadž nejprv od nás, jakýž bude konec těch, kteříž nejsou povolni evangelium Božímu?
Nítorí ti ìgbà náà dé, tí ìdájọ́ yóò bẹ̀rẹ̀ láti ilé Ọlọ́run wá, bí ó bá sì tètè tí ọ̀dọ̀ wa bẹ̀rẹ̀, ìgbẹ̀yìn àwọn tí kò gba ìyìnrere Ọlọ́run yó ha ti rí?
18 A poněvadž spravedlivý sotva k spasení přichází, bezbožný a hříšník kde se ukáže?
“Bí ó bá ṣe pé agbára káká ni a fi gba olódodo là, níbo ni aláìwà-bí-Ọlọ́run àti ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò yọjú sí?”
19 A protož i ti, kteříž trpí podlé vůle Boží, jakožto věrnému stvořiteli ať poroučejí duše své, dobře činíce.
Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwọn tí ń jìyà gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run ni ṣíṣe rere, fi ọkàn wọn lè Ẹlẹ́dàá olóòtítọ́ lọ́wọ́.

< 1 Petrův 4 >