< 1 Královská 12 >

1 Tedy přibral se Roboám do Sichem; nebo tam sešel se byl všecken Izrael, aby ho ustanovili za krále.
Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
2 Stalo se pak, když uslyšel Jeroboám syn Nebatův, jsa ještě v Egyptě, kamž byl utekl před Šalomounem králem, (bydlel zajisté Jeroboám v Egyptě, )
Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
3 Že poslali a povolali ho; protož přišed Jeroboám i všecko shromáždění Izraelské, mluvili k Roboámovi, řkouce:
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
4 Otec tvůj ztížil jho naše; protož nyní polehč služby otce svého tvrdé a břemena jeho těžkého, kteréž vzložil na nás, a budeme tobě sloužiti.
“Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
5 Kterýž řekl jim: Odejděte, a třetího dne navraťte se ke mně. I odšel lid.
Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
6 Tedy radil se král Roboám s starci, kteříž stávali před Šalomounem otcem jeho ještě za života jeho, řka: Kterak vy radíte, jakou odpověd mám dáti lidu tomuto?
Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
7 I odpověděli jemu, řkouce: Jestliže dnes povolný budeš lidu tomuto a ochotně se jim ukážeš, a odpověd dávaje, mluviti budeš přívětivě, budouť služebníci tvoji po všecky dny.
Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
8 Ale on opustil radu starců, kterouž dali jemu, a radil se s mládenci, kteříž s ním zrostli a stávali před ním.
Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
9 A řekl k nim: Co vy radíte, jakou bychom dali odpověd lidu tomuto, kteříž mluvili ke mně, řkouce: Polehč břemene, kteréž vzložil otec tvůj na nás?
Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
10 I odpověděli jemu mládenci, kteříž zrostli s ním, řkouce: Takto odpovíš lidu tomu, kteříž mluvili k tobě a řekli: Otec tvůj ztížil jho naše, ty pak polehč nám. Takto díš jim: Nejmenší prst můj tlustší jest nežli bedra otce mého.
Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
11 Nyní tedy otec můj těžké břímě vložil na vás, já pak přidám břemene vašeho; otec můj trestal vás bičíky, ale já trestati vás budu biči uzlovatými.
Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
12 Přišel tedy Jeroboám i všecken lid k Roboámovi dne třetího, jakž byl rozkázal král, řka: Navraťte se ke mně dne třetího.
Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
13 I odpověděl král lidu tvrdě, opustiv radu starců, kterouž dali jemu.
Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
14 A mluvil k nim vedlé rady mládenců, řka: Otec můj ztížil jho vaše, já pak přidám břemene vašeho; otec můj trestal vás bičíky, ale já trestati vás budu biči uzlovatými.
Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
15 I neuposlechl král lidu. Nebo byla příčina od Hospodina, aby se naplnila řeč jeho, kterouž mluvil Hospodin skrze Achiáše Silonského k Jeroboámovi synu Nebatovu.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
16 Protož vida všecken Izrael, že by je král oslyšel, odpověděl lid králi v tato slova: Jakýž máme díl v Davidovi? Ani dědictví nemáme v synu Izai. K stanům svým, ó Izraeli! Nyní opatř dům svůj, Davide. Odšel tedy Izrael k stanům svým,
Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
17 Tak že nad syny Izraelskými toliko, kteříž bydlili v městech Judských, kraloval Roboám.
Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
18 I poslal král Roboám Adurama, kterýž byl nad platy, a uházel ho všecken Izrael kamením až do smrti, čímž král Roboám přinucen byl, aby vsedna na vůz, utekl do Jeruzaléma.
Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
19 A tak odstoupili synové Izraelští od domu Davidova až do dnešního dne.
Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
20 I stalo se, když uslyšeli všickni Izraelští, že by se navrátil Jeroboám, poslavše, povolali ho do shromáždění, a ustanovili ho králem nade vším Izraelem. Nezůstávalo při domu Davidovu než samo pokolení Judovo.
Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
21 Když pak přijel Roboám do Jeruzaléma, shromáždil všecken dům Judský a pokolení Beniamin, totiž sto a osmdesáte tisíců výborných bojovníků, aby bojovali proti domu Izraelskému, a aby zase přivedeno bylo království k Roboámovi synu Šalomounovu.
Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
22 Tedy stala se řeč Boží k Semaiášovi muži Božímu, řkoucí:
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
23 Pověz Roboámovi synu Šalomounovu, králi Judskému a všemu domu Judovu i Beniaminovu, a ostatku lidu těmito slovy:
“Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
24 Takto praví Hospodin: Netáhněte a nebojujte proti bratřím svým synům Izraelským. Navraťte se jeden každý do domu svého, nebo ode mne stala se věc tato. I uposlechli rozkazu Hospodinova a navrátili se, aby odešli vedlé řeči Hospodinovy.
‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
25 Potom vystavěl Jeroboám Sichem na hoře Efraim, a bydlil v něm, a vyšed odtud, vystavěl Fanuel.
Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
26 Řekl pak Jeroboám v srdci svém: Tudíž by se navrátilo království toto k domu Davidovu,
Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
27 Když by chodíval lid tento k obětování obětí v domě Hospodinově do Jeruzaléma; i obrátilo by se srdce lidu tohoto ku pánu jeho Roboámovi králi Judskému, a tak zabijíce mne, navrátili by se k Roboámovi králi Judskému.
Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
28 Protož poradiv se král, udělal dvé telat zlatých a řekl lidu: Dosti jste již chodili do Jeruzaléma. Aj, teď bohové tvoji, ó Izraeli, kteříž tě vyvedli z země Egyptské.
Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
29 I postavil jedno v Bethel, a druhé postavil v Dan.
Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
30 Kterážto věc byla příčinou k hřešení, nebo chodíval lid k jednomu z těch až do Dan.
Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
31 Vzdělal zajisté dům výsostí, a ustanovil kněží z lidu obecného, kteříž nebyli z synů Léví.
Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
32 Ustanovil také Jeroboám svátek měsíce osmého, v patnáctý den téhož měsíce, ku podobenství svátku, kterýž byl v Judstvu, a obětoval na oltáři. Takž učinil i v Bethel, obětuje telatům, kteréž byl udělal; také i v Bethel ustanovil kněží výsostí, kteréž byl zdělal.
Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
33 A obětoval na oltáři, kterýž byl udělal v Bethel, v patnáctý den měsíce osmého, toho měsíce, kterýž byl sobě smyslil v srdci svém, a slavil svátek s syny Izraelskými, a přistoupil k oltáři, aby kadil.
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.

< 1 Královská 12 >