< Psalmi 105 >

1 Hvalite Jahvu, prizivajte mu ime, navješćujte među narodima djela njegova!
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Pjevajte mu, svirajte mu, pripovijedajte sva njegova čudesa!
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Dičite se svetim imenom njegovim, neka se raduje srce onih što traže Jahvu!
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Tražite Jahvu i njegovu snagu, tražite svagda njegovo lice!
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Sjetite se čudesa koja učini, njegovih čuda i sudova usta njegovih!
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Abrahamov rod sluga je njegov, sinovi Jakovljevi njegovi izabranici!
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 On je Jahve, Bog naš; po svoj su zemlji njegovi sudovi!
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 On se uvijek sjeća svojega Saveza, riječi koju dade tisući naraštaja:
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Saveza koji sklopi s Abrahamom i zakletve svoje Izaku.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Ustanovi je kao zakon Jakovu, Izraelu vječni Savez,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 govoreći: “Tebi ću dati kanaansku zemlju kao dio u baštinu vašu.”
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Kad ih još bješe malo na broju, vrlo malo, i kad bjehu pridošlice u njoj,
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 išli su od naroda do naroda, iz jednoga kraljevstva k drugom narodu,
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 ali ne dopusti nikom da ih tlači, kažnjavaše zbog njih kraljeve:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 “Ne dirajte u moje pomazanike, ne nanosite zla mojim prorocima!”
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 I on pozva glad na zemlju, sve zalihe uništi krušne.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Pred njima čovjeka posla: Josip u ropstvo bijaše prodan.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Sputaše uzama noge njegove, u gvožđe mu vrat staviše,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 dok se ne ispuni proroštvo njegovo, Jahvina ga riječ potvrdi.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Kralj naredi da ga driješe, narÄodÄa poglavar oslobodi njega.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Za domaćina ga stavi kući svojoj, za nadstojnika sveg imanja svoga,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 da velikaše njegove po volji uči i starce njegove mudrosti da vodi.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Tad Izrael u Egipat uđe, Jakov došljak bješe u Kamovoj zemlji.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Narod svoj umnoži veoma, učini ga jačim od dušmana.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Okrenu im srce da zamrze narod njegov, da slugama njegovim opaki budu.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Mojsija posla, slugu svoga, Arona, kog odabra.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Činjahu među njima znake njegove i čudesa u Kamovoj zemlji.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Posla tmine, i smrknu se, al' prkosiše oni riječima njegovim.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 U krv im vode prometnu i pobi ribe njihove.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Zemljom im žabe provrvješe, prodriješe i u dvore kraljevske.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Reče, i muha roj doletje i komarci u sve kraje njine.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Mjesto kiše grÓad im dade, ognjene munje po njihovoj zemlji.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Udari im lozu i smokve, polomi stabla u krajima njinim.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Reče, i skakavci dođoše i bezbrojne gusjenice s njima.
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 U zemlji im proždriješe svu bilinu, proždriješe rod njihovih njiva.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Pobi sve prvorođene u njihovoj zemlji, sve prvine snage njihove.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Izvede ih sa srebrom i zlatom; u plemenima njinim bolesnih ne bješe.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Odlasku njihovu Egipat se obradova, jer ga od njih strah spopade.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Rasprostro je oblak kao pokrov i oganj da se obnoć sja.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Zamoliše, i dovede prepelice, nebeskim ih kruhom tad nahrani.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Hrid rascijepi, i provri voda, pustinjom poteče kao rijeka.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Tad se sjeti svete riječi svoje što je zada sluzi svome Abrahamu.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Puk svoj s klicanjem izvede i s veseljem izabrane svoje.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 I dade im zemlje poganske, trud naroda baštiniše,
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 da čuvaju naredbe njegove i zakone da mu paze. Aleluja!
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalmi 105 >