< Levitski zakonik 20 >

1 Jahve reče Mojsiju:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Kaži Izraelcima: 'Tko god, Izraelac, ili stranac koji živi s Izraelcima, ustupi svoje čedo Moleku, mora se smaknuti; narod zemlje neka ga kamenuje.
“Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
3 Ja ću se okrenuti protiv toga čovjeka i odstraniti ga iz njegova naroda, jer je on, ustupivši svoje čedo Moleku, okaljao moje Svetište i obeščastio moje sveto ime.
Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
4 A ako narod zatvori svoje oči nad tim čovjekom kad svoje čedo ustupi Moleku te ga ne smakne,
Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
5 ja ću se suprotstaviti tome čovjeku i njegovoj obitelji; odstranit ću ih iz njihova naroda, njega i sve koji poslije njega pođu za Molekom da se podaju bludu s Molekom.
Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
6 Ako se tko obrati na zazivače duhova i vračare da se za njima poda javnom bludu, ja ću se okrenuti protiv takva čovjeka i odstranit ću ga iz njegova naroda.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
7 Posvećujte se da budete sveti! TÓa ja sam Jahve, Bog vaš.
“‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
8 Držite moje zakone i vršite ih. Ja, Jahve, posvećujem vas'.”
Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
9 “Tko god prokune svoga oca i svoju majku, neka se smakne. Jer je oca svoga i majku svoju prokleo, neka njegova krv padne na nj.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
10 Čovjek koji počini preljub sa ženom svoga susjeda neka se kazni smrću - i preljubnik i preljubnica.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
11 Čovjek koji bi legao sa ženom svoga oca - otkrio bi golotinju svoga oca - neka se oboje kazne smrću, krv njihova neka padne na njih.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
12 Legne li tko sa svojom snahom, neka se oboje kazne smrću. Učinili su rodoskvrnuće i neka krv njihova padne na njih.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
13 Ako bi muškarac legao s muškarcem kao što se liježe sa ženom, obojica bi počinila odvratno djelo. Neka se smaknu i krv njihova neka padne na njih.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
14 Čovjek koji se oženi kćerju i njezinom majkom - krajnja je to pokvarenost! - neka se u vatri spali i on i one, da među vama ne bude pokvarenosti.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
15 Čovjek koji bi spolno općio sa životinjom ima se smaknuti. Životinju ubijte!
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
16 Ako bi se žena primakla bilo kakvoj životinji da se s njom pari, ubij i ženu i životinju. Neka se smaknu i njihova krv neka padne na njih.
“‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
17 Čovjek koji bi se oženio svojom sestrom, kćerju svoga oca ili kćerju svoje majke te vidio njezinu golotinju, a ona vidjela njegovu - pogrdno je to djelo! - neka se istrijebe pred očima naroda. Otkrio je golotinju svoje sestre, pa neka snosi i posljedice svoje krivnje.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
18 Čovjek koji bi legao sa ženom za njezina mjesečnog pranja te otkrio njezinu golotinju - razgolio izvor njezine krvi i ona sama otkrila izvor svoje krvi - neka se oboje odstrane iz svoga naroda.
“‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
19 Ne otkrivaj golotinje sestre svoje majke niti sestre svoga oca - to je otkrivanje golotinje svoga roda, neka snose posljedice svoje krivnje.
“‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
20 Čovjek koji bi legao sa svojom strinom otkrio bi golotinju svoga strica. Neka snose posljedice svoga grijeha: neka umru bez poroda.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
21 Čovjek koji bi se oženio ženom svoga brata - golotinju bi svoga brata otkrio - i to je nečisto. Neka ostanu bez poroda.”
“‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
22 “Zato držite sve moje zakone, sve moje naredbe i vršite ih da vas ne ispljune zemlja u koju vas vodim da se u njoj nastanite.
“‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
23 Nemojte živjeti po zakonima naroda koje ja ispred vas tjeram. TÓa oni su činili sve to, i zato mi se zgadili.
Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
24 A vama sam ja rekao: vi ćete zaposjesti njihovu zemlju; vama ću je predati u posjed - zemlju kojom teče mlijeko i med. Ja sam Jahve, vaš Bog, koji sam vas odvojio od tih naroda.
Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
25 Pravite, dakle, razliku između čiste životinje i nečiste; između čiste ptice i nečiste. Nemojte sami sebe opoganjivati ni životinjom, ni pticom, ni bilo čim što zemljom puže: što sam vam ja odlučio kao nečisto.
“‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
26 Budite mi dakle sveti, jer sam ja, Jahve, svet; ja sam vas odvojio od tih naroda da budete moji.
Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
27 Čovjek ili žena koji među vama postanu zazivači duhova ili vračari neka se kazne smrću; neka se kamenuju i neka njihova krv padne na njih.”
“‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”

< Levitski zakonik 20 >