< Jošua 9 >
1 O tim su događajima čuli svi kraljevi s onu stranu Jordana - u Gorju, u Šefeli i duž čitave obale Velikoga mora sve do Libanona: Hetiti, Amorejci, Kanaanci, Perižani, Hivijci, Jebusejci -
Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
2 pa se svi udružiše da složno udare protiv Jošue i Izraela.
wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
3 A stanovnici Gibeona, poučeni onim što Jošua učini Jerihonu i Aju,
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
4 dosjete se lukavstvu. Uzmu hiniti da su putnici: bace na svoje magarce stare vreće i vinske mješine, poderane i zakrpane.
wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
5 Obuli su na noge rabljenu i pokrpanu obuću i vrgli na se staru odjeću. Sav kruh što su ga ponijeli na put bijaše suh i razdrobljen.
Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
6 Stigoše Jošui u gilgalski tabor i rekoše njemu i ljudima Izraelcima: “Dolazimo iz daleke zemlje, sklopite savez s nama.”
Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
7 Ali ljudi Izraelci kažu tim Hivijcima: “Tko zna ne živite li možda među nama? Kako ćemo, dakle, sklopiti savez s vama?”
Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
8 A oni odgovore Jošui: “Tvoje smo sluge!” Jošua ih upita: “Tko ste i odakle dolazite?”
“Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
9 Odgovore: “Daleka je zemlja iz koje dolaze tvoje sluge u ime Jahve, Boga tvojega: čuli smo za slavu njegovu i za sve što je učinio u Egiptu
Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
10 i za ono što je učinio dvojici kraljeva amorejskih koji su vladali s onu stranu Jordana - Sihonu, kralju hešbonskom, i Ogu, kralju bašanskom u Aštarotu.
àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
11 Tada nam rekoše naše starješine i svi u našoj zemlji: 'Opskrbite se hranom za put, pođite im u susret i recite im: Vaše smo sluge, sklopite dakle savez s nama.'
Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
12 Evo našega kruha: vruć smo ponijeli na put od kuća svojih kada smo krenuli k vama, a sada je, evo, suh i razdrobljen.
Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
13 A ovo su vinski mjehovi: nove smo ih nalili, pa su se, evo, već poderali; i haljine naše i obuća već su trošni od dalekog puta.”
Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
14 I povjerovaše im ljudi po putnoj opskrbi, ne pitajući Jahvu što će im reći.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
15 Jošua uglavi s njima mir i sklopi savez s njima da će ih poštedjeti. I glavari se na to zakunu.
Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
16 A poslije tri dana, pošto su sklopili s njima savez, saznalo se da su im susjedi i da žive usred Izraela.
Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
17 Tada krenu Izraelci iz tabora i stignu u njihove gradove, a to su bili Gibeon, Kefira, Beerot i Kirjat Jearim.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
18 Ali ih nisu napali sinovi Izraelovi, jer su im se glavari zajednice zakleli Jahvom, Bogom Izraelovim. Ali sva zajednica poče rogoboriti protiv glavara.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
19 Tada svi glavari rekoše zajednici: “Mi smo im se zakleli Jahvom, Bogom Izraelovim, i zato ih ne smijemo dirati.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
20 Evo što ćemo: pustimo ih da žive, kako nas ne bi stigla srdžba zbog zakletve kojom smo se zakleli.”
Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
21 Još dometnuše glavari: “Neka žive i neka budu drvosječe i vodonoše svoj zajednici.” Sva zajednica prihvati što rekoše glavari.
Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
22 Jošua pozva Gibeonce i reče im: “Zašto nas prevariste govoreći: 'Vrlo smo daleko od vas', kad eto živite usred nas?
Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
23 Zato će sada na vama biti kletva i nikada neće nestati među vama ropstva: bit ćete drvosječe i vodonoše za Dom Boga moga.”
Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
24 Oni odgovore Jošui: “Sa svih strana dolazili su glasovi nama, slugama tvojim, kako je Jahve, Bog tvoj, odredio Mojsiju, sluzi svomu, da će vam dati svu zemlju i da će istrijebiti ispred vas sve stanovnike ove zemlje; silno smo se uplašili od vas za svoje živote i zato smo učinili ovo.
Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
25 I sada smo, evo, u tvojim rukama: učini s nama što misliš da je dobro i pravo.”
Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
26 A on im je učinio ovako: izbavio ih iz ruku sinova Izraelovih te ih nisu pobili.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
27 I od toga dana naredi im Jošua da sijeku drva i nose vodu, sve do danas, za zajednicu i za žrtvenik Jahvin na mjestu koje se god izabere.
Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.