< Job 40 >

1 I Jahve se obrati Jobu i reče mu:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 “Zar će se s Jakim preti još kudilac? Tužitelj Božji nek' sam odgovori!”
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 A Job odgovori Jahvi i reče:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 “Odveć sam malen: što da odgovorim? Rukom ću svoja zatisnuti usta.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 Riječ rekoh - neću više započeti; rekoh dvije - al' neću nastaviti.”
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Nato Jahve odgovori Jobu iz oluje i reče:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 “Bokove svoje opaši k'o junak, ja ću te pitat', a ti me pouči.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Zar bi i moj sud pogaziti htio, okrivio me da sebe opravdaš?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 Zar ti mišica snagu Božju ima, zar glasom grmjet' možeš poput njega?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Ogrni se sjajem i veličanstvom, dostojanstvom se odjeni i slavom.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Plani dÓe bijesom ognja jarosnoga, pogledom jednim snizi oholnika.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Ponositoga pogledaj, slomi ga, na mjestu satri svakoga zlikovca.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 U zemlju sve njih zajedno zakopaj, u mračnu ih pozatvaraj tamnicu.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Tada ću i ja tebi odat' hvalu što si se svojom desnicom spasio.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 A sada, dÓe promotri Behemota! Travom se hrani poput govečeta,
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 u bedrima je, gle, snaga njegova, a krepkost mu u mišićju trbušnom.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Poput cedra rep podignut ukruti, sva su mu stegna ispreplele žile.
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Mjedene cijevi kosti su njegove, zglobovi mu od željeza kvrge.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Prvenac on je Božjega stvaranja; mačem ga je naoružao tvorac.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Gore mu danak u hrani donose i sve zvijerje što po njima se igra.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Pod lotosom on zavaljen počiva, guštik močvarni i glib kriju ga.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Sjenu mu pravi lotosovo lišće, pod vrbama on hladuje potočnim.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Nabuja li rijeka, on ne strahuje: nimalo njega ne bi zabrinulo da mu u žvale i sav Jordan jurne.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Tko bi za oči uhvatio njega i tko bi mu nos sulicom probio?
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Job 40 >