< Jeremija 5 >

1 Prođite ulicama jeruzalemskim, pogledajte dobro i raspitajte se, tražite po njegovim trgovima, pa ako nađete ijednoga čovjeka koji čini pravo i traži istinu, oprostit ću ovom gradu” - riječ je Jahvina.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Pa kad i govore: “Živoga mi Jahve!” doista se krivo zaklinju.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Jahve, nisu li oči tvoje upravljene k istini? Biješ ih, ali njih ne boli; zatireš ih, al' oni odbijaju pouku tvoju. Čelo im je tvrđe od litice, odbijaju da se obrate.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Rekoh: “Samo siromasi tako ludo postupaju, jer ne znaju puta Jahvina ni pravo Boga svojega.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Poći ću, dakle, velikima i njima ću govoriti, jer oni poznaju put Jahvin i pravo Boga svojega.” Ali oni svi složno razbiše jaram i sve veze pokidaše.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 I zato ih šumski lav napada, vuk pustinjski razdire, leopardi vrebaju gradove njihove, tko god iziđe iz njih bit će rastrgan. Jer su grijesi njihovi mnogobrojni, mnogostruki otpadi njihovi.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 “Zašto da ti oprostim? Sinovi me tvoji napustiše, zaklinju se lažnim bogovima. Ja ih nasitih, oni preljub učiniše, u bludničinu kuću nagrnuše.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Oni su k'o ugojeni, sileni konji: ržu za ženom bližnjega svoga.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Pa da to ne kaznim - riječ je Jahvina - narodu takvu da se ne osvetim?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Popnite se na zidove! Razarajte! Uništite, ali ne posvema! Iščupajte sve čokote jer nisu Jahvini.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Da, podlo me izdadoše dom Izraelov i dom Judin” - riječ je Jahvina.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Zanijekaše Jahvu, rekoše: “Nema ga! Zlo nas neće snaći, nećemo iskusiti ni gladi ni mača!
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 [13a] A proroci su poput vjetra, govornika nema među njima!”
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Zato ovako govori Jahve, Bog nad Vojskama: “Zato što su tako govorili, [13b] evo što će im se zbiti: U oganj ću pretvoriti svoje riječi u tvojim ustima, a narod ovaj u drvo da ga oganj proždre.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Evo, dovest ću na vas narod izdaleka, dome Izraelov - riječ je Jahvina. Narod nepobjediv, narod drevan, narod kojega jezik nećeš znati, ni razumjeti što govori.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Tobolac mu je razjapljen grob. Svi su oni po izboru junaci.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 On će proždrijet' tvoju žetvu, tvoj kruh, sinove i kćeri tvoje, ovce i goveda tvoja, grožđe i smokve tvoje, razorit će ti gradove tvrde u koje se sada uzdaš.”
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 “Ali ni tada - riječ je Jahvina - neću te posve uništiti.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 A kad budu pitali: 'Zašto nam Jahve, Bog naš, učini sve ovo?' ti ćeš im odgovoriti: 'Jer ste mene ostavili da biste služili tuđim bogovima u svojoj zemlji, služit ćete tuđincu u zemlji koja nije vaša!'”
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 “Objavite ovo domu Jakovljevu i obznanite po Judeji:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Čujte, dakle, ovo, narode ludi i nerazumni: oči imaju, a ne vide, uši imaju, a ne čuju!
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Zar se mene nećete bojati - riječ je Jahvina - zar nećete drhtati preda mnom koji sam stavio pijesak moru za granicu, za vječnu među koje nikad neće prijeći: ono se biba, al' je nemoćno, valovi mu huče, ali prijeći neće.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 No, u naroda ovog srce je prkosno, nepokorno; oni se udaljiše - to je snaga njihova!
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Ne rekoše u srcu svome: 'Bojmo se Jahve, Boga svojega, koji nam u pravi čas šalje dažd rani i kišu kasnu i koji nam čuva tjedne određene za žetvu.'
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Vaša bezakonja narušiše ovo, vaši vam grijesi uništiše blagostanje.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 Da, u mome narodu ima zlikovaca: kao ptičari vrebaju iz zasjede, postavljaju zamke, hvataju ljude.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Kao što je krletka puna ptica, tako su njihove kuće pune grabeža; postadoše tako veliki i bogati,
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 tusti i ugojeni. Da, prevršila se mjera zla, ne brane prava, prava sirote ne sreću, ne mare za pravo sirotinje.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Pa da to ne kaznim - riječ je Jahvina - narodu takvu da se ne osvetim?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Strahote i grozote zbivaju se u ovoj zemlji:
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 proroci laž proriču, a svećenici poučavaju na svoju ruku. A mojem narodu to omilje! Al' što ćete raditi na kraju?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jeremija 5 >