< Hošea 4 >

1 Čujte riječ Jahvinu, sinovi Izraelovi, jer Jahve se parbi sa stanovnicima zemlje.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
2 Nema više vjernosti, nema ljubavi, nema znanja Božjega u zemlji, već proklinjanje i laž, ubijanje i krađa, preljub i nasilje, jedna krv drugu stiže.
àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
3 Stoga tuguje zemlja i ginu svi stanovnici s poljskim zvijerima i pticama nebeskim te ugibaju i ribe u moru.
Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
4 Ipak neka se nitko ne parbi, neka nitko ne kori! Ali s tobom se moram parbiti, svećeniče.
“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
5 Danju ti posrćeš, a noću s tobom posrće i prorok; pogubit ću mater tvoju.
Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
6 Moj narod gine: nema znanja; jer si ti znanje odbacio, i ja odbacujem tebe iz svećenstva svoga; jer si Zakon svoga Boga zaboravio, i ja ću tvoje zaboraviti sinove.
àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
7 Što ih je više bivalo, više su protiv mene griješili, Slavu su svoju Sramotom zamijenili.
Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
8 Grijesima mog naroda oni se hrane, duša im hlepi za bezakonjem njegovim.
wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
9 I sa svećenikom bit će k'o i s narodom; kaznit ću ga za njegove putove i naplatit ću mu za njegova djela.
Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
10 Jest će, ali se nasititi neće; bludničit će, ali se neće množiti, jer oni su prestali štovati Jahvu -
“Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
11 blud, mošt i vino zarobiše im srce.
fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
12 Narod moj savjet traži od drva, palica mu njegova daje odgovore: jer duh razvratni njih zavodi te se od Boga svoga bludu odaju.
Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
13 Oni žrtvuju na gorskim vrhuncima i na bregovima pale kad, pod hrastom, jablanom i dubom; jer je tako lagodno pod njihovom sjenom. I zato, odaju li se vaše kćeri bludu, čine li preljub vaše nevjeste,
Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
14 neću vam kazniti kćeri što bludniče niti nevjeste vaše što preljub čine; jer oni sami idu nasamo s bludnicama i žrtvuju s milosnicama hramskim. Tako, bez razuma narod u propast srlja!
“Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
15 Ako li se ti bludu odaješ, Izraele, neka bar Juda ne griješi! I ne idite u Gilgal, ne penjite se u Bet Aven, ne kunite se “živoga mi Jahve.”
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
16 Jer poput junice tvrdoglave Izrael tvrdoglav postade, pa kako da ga Jahve sad pase k'o janje na prostranoj livadi?
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
17 Efrajim se udružio s kumirima: pusti ga!
Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
18 A kad završe pijanku, bluda se prihvaćaju, Sramotu vole više nego Slavu svoju.
Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
19 Vihor će ih svojim krilima stegnuti i njihovi će ih osramotit' žrtvenici.
Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.

< Hošea 4 >