< Ezekiel 16 >

1 I dođe mi riječ Jahvina:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Sine čovječji! Pokaži Jeruzalemu sve gadosti njegove!
“Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
3 Reci: Ovako Jahve Gospod govori Jeruzalemu, nevjernici: 'Podrijetlom i rodom iz zemlje si kanaanske, otac ti Amorejac, mati Hetitkinja.
Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
4 Kad si svijet ugledala, na dan rođenja tvojega pupka ti ne odrezaše niti te vodom opraše da te očiste; solju te ne osoliše niti te povojima poviše.
Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
5 Nijedno se oko na te ne sažali niti se tko smilova da ti to učini, nego te na dan rođenja tvojega gadnu baciše napolje.
Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
6 A ja prođoh kraj tebe i vidjeh gdje se koprcaš u krvi. I rekoh ti dok si još u krvi bila: 'Živi!' U krvi ti tvojoj rekoh: 'Živi!
“‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
7 Razrasti se kao izdanak u polju!' I umnožih te, i ti se razraste i velika postade, i dođe vrijeme da sazreš. Dojke ti se raspupale, kosa ti narasla, ali si još gola i naga bila.
Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
8 Prođoh kraj tebe i u te se zagledah: i gle, dob tvoja - dob je ljubavi! Raširih na te skute svoje i pokrih ti golotinju. Prisegoh ti i sklopih Savez s tobom - riječ je Jahve Gospoda - i ti moja postade.
“‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Okupah te u vodi, krv saprah s tebe i uljem te pomazah.
“‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
10 Obukoh te u šarene haljine, na noge ti obuh sandale od fine kože; opasah te bezom i pokrih te prijevjesom svilenim.
Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
11 Uresih te nakitima: na ruke ti stavih narukvice, oko vrata ogrlice;
Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
12 prstenom ti nos uresih, uši naušnicama, a glavu ti ovjenčah vijencem najljepšim.
mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
13 I tako se sva u srebru i zlatu pojavi, u haljini od beza, svilom izvezenoj. Za hranu ti dadoh najfinije brašno, med i ulje. Bila si tako lijepa, prelijepa, za kraljicu podobna!
Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
14 Glas o ljepoti tvojoj puče među narodima, jer ti bijaše tako lijepa u nakitu mojem što ga djenuh na tebe - riječ je Jahve Gospoda.
Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Ali te ljepota tvoja zanijela, zbog glasa se svojega bludu podade: blud si svoj nudila obilno svakom prolazniku, njegova si bila.
“‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
16 Od haljina si svojih šarene uzvišice pravila i na njima se bludu odavala ...
Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
17 I nakite uze zlatne i srebrne, kojima te ja bijah uresio, i od njih načini sebi muške likove da s njima bludničiš.
Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
18 Uze šarene, vezene haljine da njima odjeneš kumire svoje i njima si prinosila moje ulje i moj kad.
Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
19 A hranu što ti je dadoh - najfinije brašno, med i ulje kojima te hranjah - pred njih si stavljala na ugodan miris. Da, tako to bijaše - riječ je Jahve Gospoda!
Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
20 Sinove si svoje i kćeri uzimala koje meni porodi i njima ih za hranu klala. Malo ti bijaše tvoga bludničenja,
“‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
21 pa si čak i djecu moju davala da se njima na čast kroz oganj provedu!
Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
22 U svim tim gnusobama i bludu svojemu ne spomenu se dana mladosti svoje, kad si se gola i naga u krvi svojoj koprcala.
Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
23 I povrh svega zla - Jao! Jao! riječ je Jahve Gospoda -
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
24 sagradi sebi humke, posvud diže uzvišice.
ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
25 Na svim raskršćima podiže uzvišice i na njima blatiš svoju ljepotu, nudiš se svakom prolazniku množeć' svoje bludničenje.
Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
26 Bludu se podade sa sinovima Egipta, snažna tijela, bludničenje si množila da me razjariš.
Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
27 Zato, evo, ruku digoh na te, smanjivši ti obrok hrane i predavši te bijesu tvojih mrziteljica, kćeri filistejskih, koje se stide sramotnoga tvojeg vladanja.
Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
28 Tjerala si blud i sa sinovima Asira i nisi se zasitila; i s njima si blud tjerala, ali se nisi zasitila.
Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
29 Umnožila si bludničenje svoje i sa zemljom kanaanskom, sa zemljom kaldejskom, ali se ni onda nisi zasitila.
Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
30 O, kako li slabo bijaše tvoje srce - riječ je Jahve Gospoda - kad činjaše ono što rade bludnice najrazvratnije.
“Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
31 Na svim raskrsnicama humak sebi podiže, posvuda sagradi sebi uzvišice. Ali ne kao druge bludnice, jer si prezirala plaću bludničku,
Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
32 nego kao preljubnica: mjesto muža, strance si primala.
“‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
33 Svima se bludnicama plaća, a ti si sama ljubavnike svoje plaćala i još si ih u bludnosti svojoj darovima mamila da ti dođu odasvuda.
Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
34 Ti bijaše bludnica kakvih nema: nitko za tobom nije trčao da s tobom blud provodi, nego si sama davala plaću bludničku, a nisu je tebi plaćali. Toliko si bila opaka!
Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
35 Stoga, razvratnice, čuj riječ Jahvinu:
“‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
36 Ovako govori Jahve Gospod: Jer si svlačila svoju sramotu i u bludu golotinju otkrivala pred svima svojim ljubavnicima i gnusnim kumirima, i zbog krvi svojih sinova što si ih njima prinosila,
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
37 evo, skupit ću sve tvoje ljubavnike s kojima si se naslađivala, sve koje si voljela i koje si mrzila, skupit ću ih odasvud protiv tebe i razotkriti im tvoju golotinju, neka vide sramotu tvoju.
nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
38 Sudit ću ti kao što se sudi preljubnicama i krvnicama i predati te bijesu njihovu.
Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
39 Predat ću te u ruke njihove da poruše tvoje humke, da razore uzvišice tvoje. I zderat će sa tebe haljine, oteti nakit i ostaviti te golu, sasvim nagu.
Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
40 A zatim će na te dovesti svjetinu da te kamenuje i da te sasiječe mačevima.
Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
41 Kuće će ti ognjem spaliti i naočigled svim ženama izvršiti pravdu nad tobom. Tako ću dokrajčiti tvoje bludničenje, nećeš više davati plaću bludničku.
Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
42 Iskalit ću gnjev svoj nad tobom i povući ću svoju ljubomoru od tebe. Smirit ću se i neću se više gnjeviti.
Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
43 I jer se ne spomenu svoje mladosti, već me svim tim izazivaše, oborit ću ti na glavu sve postupke tvoje - riječ je Jahve Gospoda: nećeš više dodavati bestidnosti na sve svoje gadosti!
“‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
44 I sastavljač poslovica narugat će ti se poslovicom: 'Kakva mati, takva kći.'
“‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
45 Prava si kći svoje matere, koja ostavi muža i djecu; sestra si sestara svojih, koje ostaviše muževe svoje i djecu: Hetitkinja vam mati bijaše, otac Amorejac:
Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
46 Samarija, sestra tvoja starija, sa svojim kćerima tebi slijeva stoji; Sodoma, tvoja mlađa sestra, sa kćerima svojim zdesna ti stoji.
Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
47 A ti ne samo da si njihovim putem hodila i činila njihove gadosti - to bi tebi bilo premalo - već bijaše od njih pokvarenija na svojim putovima.
Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
48 Života mi mojega - riječ je Jahve Gospoda - tvoja sestra Sodoma sa svojim kćerima ne učini što si ti počinila zajedno sa kćerima svojim.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
49 Evo opačina sestre tvoje Sodome: gizdavo, u izobilju kruha i bezbrižno življaše ona i kćeri njezine, a sirotinju i bijednike ne pomagahu.
“‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
50 Uzoholiše se i gadosti pred očima mojim činjahu, i zato ih zatrijeh, kao što vidje!
Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
51 A sestra ti Samarija ne počini ni polovicu grijeha tvojih, i tako ti počini više gadosti nego one obje zajedno, opravdavši sestre svoje svojim gadostima.
Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
52 Zato snosi sad sramotu grijeha kojima si sestre svoje opravdala; zbog grijeha kojima se više od njih nagrdi, one izađoše pravednije. Postidi se, dakle, i snosi sramotu svoju kojom sestre opravda.
Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
53 A ja ću okrenuti udes njihov, udes Sodome i kćeri njenih, udes Samarije i kćeri njenih; i tvoj ću udes okrenuti među njima,
“‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
54 da snosiš sramotu svoju i da se postidiš za sve što si počinila, njima na utjehu.
kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
55 Sestra tvoja Sodoma i kćeri njene vratit će se u stanje prijašnje; sestra tvoja Samarija i kćeri njene vratit će se u stanje prijašnje; ali i ti i kćeri tvoje vratit ćete se u stanje prijašnje.
Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
56 Zar se nije spominjala sestra tvoja Sodoma dok ti bijaše ponosita,
Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
57 prije negoli se golotinja tvoja otkrila? Budi sada za ruglo kćerima edomskim, susjedama njenim i kćerima filistejskim koje ti se sa svih strana rugaju.
kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
58 Snosi, dakle, svoju sramotu i svoje gadosti - riječ je Jahve Gospoda!'
Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
59 Jer ovako govori Jahve Gospod: 'Postupit ću s tobom onako kako ti učini kad pogazi zakletvu i raskinu Savez.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
60 Ali ću se ja ipak spomenuti svojega Saveza s tobom što ga sklopih u dane mladosti tvoje i uspostavit ću s tobom Savez vječan.
Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
61 I ti ćeš se opomenuti svojih putova i postidjet ćeš se kad primiš svoje sestre, stariju i mlađu, koje ću ti dati za kćeri, ali ne snagom tvog Saveza.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
62 Sklopit ću s tobom savez svoj i znat ćeš da sam ja Jahve,
Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
63 da se opomeneš i da se postidiš i da od sramote više ne otvoriš usta kad ti oprostim sve što učini! To je riječ Jahve Gospoda.'”
Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ezekiel 16 >