< Ponovljeni zakon 12 >

1 Ovo su zakoni i uredbe što vam ih valja držati i vršiti u zemlji koju vam Jahve, Bog otaca vaših, daje u posjed za sve dane što budete živjeli na zemlji.
Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
2 Sravnite sa zemljom sva mjesta na kojima su narodi koje ćete protjerati iskazivali štovanje svojim bogovima, nalazila se ona na visokim brdima, na humovima ili pod kakvim zelenim drvetom.
Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
3 Porušite njihove žrtvenike, porazbijajte njihove stupove, spalite im ašere; smrvite kipove njihovih bogova, zatrite im imena s onih mjesta.
Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
4 Jahvi, Bogu svome, nemojte onako iskazivati štovanje.
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
5 Jahvu, Boga svoga, tražite jedino na mjestu koje je on odabrao, sred svih vaših plemena, da ondje stavi svoje ime i da ondje prebiva;
Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
6 onamo donosite svoje paljenice i svoje klanice, svoje desetine i darove svojih ruku, svoje zavjetne i dragovoljne prinose i prvine od svoga krupnoga i sitnoga blaga.
Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
7 Blagujte ondje, vi i vaše obitelji, u nazočnosti Jahve, Boga svoga; veselite se svime što su vaše ruke namaknule i što vam je Jahve, Bog vaš, blagoslovom udijelio.
Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
8 Nemojte raditi čak ni kako radimo ovdje danas - svatko što se njemu čini dobro -
Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
9 jer još niste stigli u Počivalište, u baštinu koju ti daje Jahve, Bog tvoj.
Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
10 Ali kad prijeđete preko Jordana i nastanite se u zemlji koju vam Jahve, Bog vaš, daje u baštinu, kad vas smiri od svih neprijatelja koji budu oko vas te budete živjeli bez straha,
Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
11 onda ćete donositi sve što vam naređujem: svoje paljenice, svoje klanice, svoje desetine, darove svojih ruku i sve svoje izabrane zavjetnice koje budete zavjetovali Jahvi - na mjesto koje Jahve, Bog vaš, odabere da ondje nastani svoje ime.
Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
12 Veselite se tada pred Jahvom, Bogom svojim, vi, vaši sinovi i kćeri, vaše sluge i sluškinje i levit koji bude u vašim gradovima, jer on nema s vama udjela ni baštine.
Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
13 Pazi da ne prinosiš svojih žrtava paljenica na bilo kojem mjestu što ga zamijetiš,
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
14 nego samo na mjestu što ga odabere Jahve, u jednome od tvojih plemena. Tu prinosi svoje paljenice i tu obavljaj sve što ti naređujem.
Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
15 Ali svaki put kad ti srce zaželi, možeš zaklati i jesti mesa u svim svojim gradovima, prema blagoslovu koji ti Jahve, Bog tvoj, bude davao. I nečist i čist može ga jesti, kao da je od srne ili jelena.
Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
16 Ali krvi nemojte blagovati; istočite je na zemlju kao vodu.
Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
17 Po svojim gradovima nemojte jesti desetine svoga žita, svoga vina, svoga ulja ni prvine svoga krupnog ili sitnog blaga; niti išta od svojih zavjetovanih i od svojih dragovoljnih prinosa, ni od prinosa svojih ruku,
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
18 nego ćeš to blagovati pred Jahvom, Bogom svojim, u mjestu koje Jahve, Bog tvoj, odabere, ti, tvoj sin, tvoja kći, tvoj sluga, tvoja sluškinja i levit koji bude u tvojim gradovima. Proveseli se u nazočnosti Jahve, Boga svoga, svime što ti ruka namakne.
Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
19 Pazi da nikad ne zaboraviš levita dok si na svojoj zemlji.
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
20 Kad ti Jahve, Bog tvoj, proširi tvoje područje, kao što ti je rekao, i ti rekneš: 'Ja bih jeo mesa' - jer želiš jesti mesa - možeš ga jesti koliko ti duša želi.
Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
21 Bude li mjesto koje Jahve, Bog tvoj, odabere da u njemu svoje ime smjesti daleko od tebe, onda možeš zaklati bilo što od svoje krupne ili sitne stoke što ti je Jahve dadne - kako sam ti već naredio - te jesti u bilo kojem svome gradu koliko ti duša želi.
Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
22 Jedi ga ipak onako kako se jede srna ili jelen: neka ga jedu zajedno čisti i nečisti.
Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
23 Samo, pazi da ne jedeš krvi! Ta krv je život. Ne smiješ jesti život s mesom.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
24 Ne blaguj je; istoči je na zemlju kao vodu.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
25 Ne smiješ je jesti, da bude dobro i tebi i tvojim sinovima poslije tebe kad činiš što je pravo u očima Jahvinim.
Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
26 Ali svoje posvećene prinose i svoje zavjetne prinose uzmi i nosi na mjesto koje Jahve odabere.
Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
27 Tu prinesi svoje paljenice, meso i krv, na žrtveniku Jahve, Boga svoga. Ali krv od svojih klanica istoči na žrtvenik Jahve, Boga svoga, a meso pojedi.
Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
28 Drži i vrši sve ove naredbe što ti ih propisujem, da bude dobro zauvijek tebi i tvojim sinovima poslije tebe kad činiš što je dobro i pravedno u očima Jahve, Boga svoga.
Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
29 A kad Jahve, Bog tvoj, istrijebi narode na koje ideš da ih otjeraš s posjeda ispred sebe i kad ih otjeraš te se u njihovoj zemlji nastaniš,
Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
30 čuvaj se da ne padneš u zamku; ne pođi za njima pošto budu uništeni ispred tebe. Ne istražuj o njihovim bogovima i ne govori: 'Kako su oni narodi štovali svoje bogove, tako ću i ja.'
Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
31 Nemoj onako postupati prema Jahvi, Bogu svome. TÓa Jahvi je zazorno i mrsko sve što su oni činili svojim bogovima. Čak su svoje sinove i kćeri spaljivali u čast svojim bogovima.
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
32 Sve što vam naređujem držite; tomu ništa ne domeći i ništa ne oduzimaj.
Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.

< Ponovljeni zakon 12 >