< 2 Samuelova 17 >

1 Nato Ahitofel reče Abšalomu: “Dopusti da izaberem dvanaest tisuća ljudi pa da se dignem i pođem u potjeru za Davidom još noćas.
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Èmi ó yan ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin èmi ó sì dìde, èmi ó sì lépa Dafidi lóru yìí.
2 Navalit ću na njega kad bude umoran i bez snage; plašit ću ga i razbježat će se sav narod koji je s njim. Onda ću ubiti samoga kralja.
Èmi ó sì yọ sí i nígbà tí àárẹ̀ bá mú un tí ọwọ́ rẹ̀ sì ṣe aláìle, èmi ó sì dá a ní ìjì, gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ yóò sì sá, èmi ó sì kọlu ọba nìkan ṣoṣo.
3 A sav ću narod dovesti natrag k tebi, kao što se mlada vraća svome mužu: ti radiš o glavi samo jednome čovjeku, a sav će narod onda biti miran.”
Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
4 Svidje se to Abšalomu i svim starješinama Izraelovim.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Absalomu, àti lójú gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli.
5 Ali Abšalom reče: “Pozovimo još Hušaja Arčanina da čujemo što će nam on kazati!”
Absalomu sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Huṣai ará Arki, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
6 Kad je Hušaj došao k Abšalomu, reče mu Abšalom: “Ahitofel je svjetovao ovako. Hoćemo li učiniti kako je on predložio? Ako ne, govori ti!”
Huṣai sì dé ọ̀dọ̀ Absalomu, Absalomu sì wí fún un pé, “Báyìí ni Ahitofeli wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”
7 A Hušaj odgovori Abšalomu: “Ovaj put savjet Ahitofelov nije dobar.”
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Ìmọ̀ tí Ahitofeli gbà yìí, kò dára nísinsin yìí.”
8 I nastavi Hušaj: “Ti znaš da su tvoj otac i njegovi ljudi junaci i da su ljuti kao medvjedica kojoj su oteli njezine medvjediće. Tvoj je otac ratnik, neće on dopustiti da narod počiva preko noći.
Huṣai sì wí pé, “Ìwọ mọ baba rẹ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé alágbára ni wọ́n, wọ́n sì wà ní kíkorò ọkàn bí àmọ̀tẹ́kùn tí a gbà ní ọmọ ni pápá, baba rẹ sì jẹ́ jagunjagun ọkùnrin kì yóò bá àwọn ènìyàn náà gbé pọ̀ lóru.
9 On se sada krije u kakvoj jami ili na kakvu drugom mjestu. Pa ako odmah u početku koji od naših padne, proširit će se glas o porazu u vojsci koja je pristala uz Abšaloma.
Kíyèsi i, ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ nísinsin yìí ni ihò kan, tàbí ní ibòmíràn: yóò sì ṣe, nígbà tí díẹ̀ nínú wọn bá kọ́ ṣubú, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóò sì wí pé, ‘Ìparun sì ń bẹ́ nínú àwọn ènìyàn tí ń tọ Absalomu lẹ́yìn.’
10 Tada će i najhrabriji, u koga je srce kao u lava, izgubiti srčanost. Jer sav Izrael zna da je tvoj otac junak i da su hrabri oni koji ga prate.
Ẹni tí ó sì ṣe alágbára, tí ọkàn rẹ̀ sì dàbí ọkàn kìnnìún, yóò sì rẹ̀ ẹ́: nítorí gbogbo Israẹli ti mọ̀ pé alágbára ni baba rẹ, àti pé, àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ jẹ́ alágbára.
11 Zato ja svjetujem ovo: neka se sav Izrael, od Dana do Beer Šebe, okupi oko tebe, da ga bude kao pijeska na obali morskoj, a ti sam da stupaš u njihovoj sredini.
“Nítorí náà èmi dámọ̀ràn pé, kí gbogbo Israẹli wọ́jọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dani títí dé Beerṣeba, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn létí òkun fún ọ̀pọ̀lọpọ̀; àti pé, kí ìwọ tìkára rẹ̀ ó lọ sí ogun náà.
12 Tada ćemo navaliti na njega gdje se god bude nalazio, oborit ćemo se na nj kao što rosa pada na zemlju i nećemo ostaviti živa ni njega niti ikojega od njegovih ljudi.
Àwa ó sì yọ sí i níbikíbi tí àwa o gbé rí i, àwa ó sì yí i ká bí ìrì ti ń ṣẹ̀ sí ilẹ̀ àní, ọkàn kan kì yóò kù pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 Ako li se povuče u koji grad, sav će izraelski narod donijeti užeta pod onaj grad pa ćemo ga povlačiti do potoka, sve dok više ni kamenčića ne bude od njega.”
Bí o bá sì bọ́ sí ìlú kan, gbogbo Israẹli yóò mú okùn wá sí ìlú náà, àwa ó sì fà á lọ sí odò, títí a kì yóò fi rí òkúta kéékèèké kan níbẹ̀.”
14 Tada Abšalom i svi Izraelci rekoše: “Bolji je savjet Hušaja Arčanina nego savjet Ahitofelov.” Jer Jahve bijaše odlučio da se osujeti izvrsna Ahitofelova osnova, kako bi navukao nesreću na Abšaloma.
Absalomu àti gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wí pé, “Ìmọ̀ Huṣai ará Arki sàn ju ìmọ̀ Ahitofeli lọ! Nítorí Olúwa fẹ́ láti yí ìmọ̀ rere ti Ahitofeli po.” Nítorí kí Olúwa lè mú ibi wá sórí Absalomu.
15 Potom Hušaj javi svećenicima Sadoku i Ebjataru: “Ahitofel je tako i tako savjetovao Abšaloma i starješine izraelske, a ja sam savjetovao tako i tako.
Huṣai sì wí fún Sadoku àti fún Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Báyìí ni Ahitofeli ti bá Absalomu àti àwọn àgbàgbà Israẹli dámọ̀ràn, báyìí lèmi sì bá a dámọ̀ràn.
16 Zato sad brzo javite to Davidu i poručite mu: 'Nemoj noćas noćiti na ravnicama pustinje, nego brzo prijeđi na drugu stranu da ne bude uništen kralj i sva vojska koja je s njim.'”
Nítorí náà yára ránṣẹ́ nísinsin yìí kí o sì sọ fún Dafidi pé, ‘Má ṣe dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà lálẹ́ yìí, ṣùgbọ́n yára rékọjá kí a má bá a gbé ọba mì, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ.’”
17 Jonatan i Ahimaas zadržavali se kod Rogelskog izvora; jedna je sluškinja dolazila i donosila im vijesti, a oni su odlazili da to jave kralju Davidu, jer se nisu smjeli odati ulazeći u grad.
Jonatani àti Ahimasi sì dúró ní En-Rogeli ọ̀dọ́mọdébìnrin kan sì lọ, ó sì sọ fún wọn, wọ́n sì lọ wọ́n sọ fún Dafidi ọba nítorí pé kí a má bá à rí wọn pé wọ́n wọ ìlú.
18 Ali ih opazi neki momak te javi Abšalomu. Nato obojica žurno odoše i dođoše u kuću nekoga čovjeka u Bahurimu. U njegovu dvorištu bijaše studenac i oni se spustiše u nj.
Ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọdékùnrin kan rí wọn, ó sì wí fún Absalomu, ṣùgbọ́n àwọn méjèèjì sì yára lọ kúrò, wọ́n sì wá sí ilé ọkùnrin kan ní Bahurimu, ẹni tí ó ní kànga kan ní ọgbà rẹ̀, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ sí ibẹ̀.
19 A žena uze i razastrije pokrivač preko otvora studencu i posu po njem stučenoga zrnja, tako da se ništa nije moglo opaziti.
Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkan ó fi bo kànga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.
20 Abšalomove sluge dođoše k toj ženi u kuću i upitaše: “Gdje su Ahimaas i Jonatan?” A žena im odgovori: “Otišli su dalje prema vodi.” Potom su ih još tražili, ali ih ne nađoše pa se vratiše u Jeruzalem.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Ahimasi àti Jonatani gbé wà?” Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jerusalẹmu.
21 A kad su oni otišli, ona dvojica iziđoše iz studenca i odoše da donesu vijesti kralju Davidu. I rekoše mu: “Ustajte i prijeđite brže preko vode, jer je tako i tako savjetovao protiv vas Ahitofel.”
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dafidi ọba. Wọ́n sọ fún Dafidi pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán, nítorí pé báyìí ni Ahitofeli gbìmọ̀ sí ọ.”
22 Tada se David i sav narod što bijaše s njim diže i prijeđe preko Jordana; u zoru nije više bilo nijednoga koji nije prešao preko Jordana.
Dafidi sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jordani: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jordani.
23 Kad je Ahitofel vidio da se nije izvršio njegov savjet, osamari svoga magarca, krenu na put i ode svojoj kući u svoj grad. Ondje se pobrinu za svoju kuću, zatim se objesi i umrije. Pokopaše ga u grobu njegova oca.
Nígbà tí Ahitofeli sì rí i pé wọn kò fi ìmọ̀ tirẹ̀ ṣe, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ni gàárì, ó sì dìde, ó lọ ilé rẹ̀, ó sì palẹ̀ ilé rẹ̀ mọ̀, ó sì so, ó sì kú, a sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀. Absalomu gbógun ti Dafidi.
24 David je već bio došao u Mahanajim kad je Abšalom prešao preko Jordana sa svim Izraelcima koji bijahu s njim.
Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Absalomu sì gòkè odò Jordani, òun àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli pẹ̀lú rẹ̀.
25 Abšalom bijaše postavio Amasu za zapovjednika nad vojskom namjesto Joaba. A Amasa je bio sin nekoga čovjeka po imenu Jitre, Jišmaelovca, koji je ušao k Abigajili, kćeri Jišajevoj i sestri Sarvije, Joabove majke.
Absalomu sì fi Amasa ṣe olórí ogun ní ipò Joabu: Amasa ẹni tí í ṣe ọmọ ẹnìkan, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Itira, ará Israẹli, tí ó wọlé tọ Abigaili ọmọbìnrin Nahaṣi, arábìnrin Seruiah, ìyá Joabu.
26 Izrael i Abšalom udariše tabor u zemlji gileadskoj.
Israẹli àti Absalomu sì dó ní ilẹ̀ Gileadi.
27 Kad je David došao u Mahanajim, tada Šobi, sin Nahašev iz Rabe Amonske, pa Makir, sin Amielov iz Lo Debara, i Barzilaj, Gileađanin iz Rogelima,
Nígbà tí Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Ṣobi ọmọ Nahaṣi ti Rabba tí àwọn ọmọ Ammoni, àti Makiri ọmọ Ammieli ti Lo-Debari, àti Barsillai ará Gileadi ti Rogelimu.
28 donesoše postelja, pokrivača, čaša i zemljanog suđa, uz to pšenice, ječma, brašna, pržena žita, boba, leće,
Mú àwọn àkéte, àti àwọn àwo, àti ìkòkò amọ̀, àti alikama, àti ọkà barle, àti ìyẹ̀fun, àti àgbàdo díndín, àti ẹ̀wà, àti erèé, àti lẹntili.
29 meda, kiseloga mlijeka i sira kravljeg i ovčjeg i ponudiše Davida i narod što bijaše s njim da jedu. Jer mišljahu: “Ljudi su u pustinji trpjeli glad, umor i žeđu.”
Àti oyin, àti òrí-àmọ́, àti àgùntàn, àti wàràǹkàṣì màlúù, wá fún Dafidi àti fún àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, láti jẹ: nítorí tí wọ́n wí pé, “Ebi ń pa àwọn ènìyàn, ó sì rẹ̀ wọ́n, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”

< 2 Samuelova 17 >