< 1 Samuelova 10 >

1 Tada Samuel uze uljanicu s uljem te je izli na glavu Šaulu; zatim ga poljubi i reče: “Ovim te Jahve pomazao za kneza nad svojim narodom Izraelom. Ti ćeš vladati nad narodom Jahvinim i izbavit ćeš ga iz ruke njegovih neprijatelja unaokolo. I evo ti znaka da te Jahve pomazao za kneza nad svojom baštinom.
Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
2 Kad odeš sada od mene, naći ćeš dva čovjeka kod Rahelina groba, na granici zemlje Benjaminove, u Selsahu. Oni će ti reći: 'Našle su se magarice koje si pošao tražiti; i gle, tvoj je otac zaboravio na magarice, a zabrinut je za vas i govori: Što da učinim za svoga sina?'
Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
3 A kad odeš odande dalje i dođeš do Taborskog Hrasta, srest ćeš ondje tri čovjeka koja će ići gore k Bogu u Betel. Jedan će nositi tri jareta, drugi tri okrugla kruha, a treći mijeh vina.
“Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
4 Oni će te pozdraviti i dat će ti dva kruha, a ti ih primi iz njihove ruke.
Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
5 Poslije toga doći ćeš u Gibeu Božju (gdje se nalazi filistejski stup). Kad uđeš u grad, namjerit ćeš se na povorku proroka koji će silaziti s uzvišice, a pred njima harfe, bubnjevi, frule i citre; oni će biti u proročkom zanosu.
“Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
6 Tada će na te sići duh Jahvin te ćeš pasti u proročki zanos s njima i promijenit ćeš se u drugog čovjeka.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
7 A kad ti se ispune ti znakovi, onda čini kako ti se prilika pruži jer je Bog s tobom.
Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
8 Zatim ćeš sići preda mnom u Gilgal i ja ću sići k tebi da prinesem žrtve paljenice i žrtve pričesnice. Sedam dana čekaj dok ne dođem k tebi i ne poučim te što ćeš činiti.”
“Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
9 Čim je Šaul okrenuo leđa da ode od Samuela, Bog mu promijeni srce i svi se oni znakovi ispuniše u onaj dan.
Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
10 Kad su, naime, došli u Gibeu, gle, dođe mu u susret povorka proroka i duh Božji siđe na njega te on pade u proročki zanos usred njih.
Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
11 I kad su ga svi koji ga poznavahu otprije vidjeli gdje prorokuje s prorocima, počeše govoriti jedan drugome: “Što se to dogodilo sa sinom Kiševim? Zar je Šaul među prorocima?”
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
12 A jedan od njih odvrati i reče: “A tko je njihov otac?” Otuda je nastala poslovica: “Zar je i Šaul među prorocima?”
Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
13 Kad je prošao njegov zanos, Šaul se vrati kući.
Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
14 A Šaulov stric upita njega i njegova momka: “Kamo ste išli?” A Šaul odgovori: “Da tražimo magarice; a kad smo vidjeli da ih nema, otišli smo k Samuelu.”
Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
15 A njegov ga stric zamoli: “Pripovijedaj mi što vam je rekao Samuel.”
Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
16 A Šaul odgovori svome stricu: “Rekao nam je da su se našle magarice.” Ali mu ništa ne reče o kraljevskoj časti koju mu je prorekao Samuel.
Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
17 Poslije toga Samuel sazva narod pred Jahvu u Mispu
Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
18 i reče sinovima Izraelovim: “Ovako govori Jahve: 'Ja sam izveo Izraela iz Egipta i izbavio sam vas iz egipatske ruke i iz ruke svih kraljevstava koja su vas tlačila.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
19 A vi ste danas odbacili svoga Boga, onoga koji vas je izbavljao od svih vaših zala i svih vaših nevolja i rekli ste mu: 'Ne, nego postavi kralja nad nama!' Zato sada stanite pred Jahvom po svojim plemenima i rodovima.'”
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
20 Potom Samuel privede sva plemena Izraelova i ždrijeb pade na pleme Benjaminovo.
Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
21 Zatim privede pleme Benjaminovo po rodovima i ždrijeb pade na Matrijev rod; a kad privede Matrijev rod, čovjeka po čovjeka, ždrijeb pade na Šaula, sina Kiševa; ali kad ga potražiše, na nađoše ga.
Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
22 Tada još jednom upitaše Jahvu: “Je li taj čovjek došao ovamo?” A Jahve odgovori: “Eno ga, sakrio se za tovarom.”
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
23 Otrčaše i dovedoše ga odande; a kad je stao usred naroda, bijaše glavom i ramenima viši od sviju.
Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
24 Tada Samuel reče svemu narodu: “Vidite li koga je izabrao Jahve? Nema mu ravna u svemu narodu.” I sav narod uze klicati i vikati: “Živio kralj!”
Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
25 Nato Samuel objavi narodu kraljevsko pravo i zapisa ga u knjigu koju položi pred Jahvu. Najposlije Samuel otpusti sav narod da ide svaki svojoj kući.
Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
26 Šaul se također vrati kući u Gibeu, a s njim pođoše junaci kojima je Bog taknuo srce.
Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
27 Ali neke ništarije rekoše: “Kako će nas taj spasiti?” I prezreše ga i ne donesoše mu nikakva dara.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.

< 1 Samuelova 10 >