< ⲔⲞⲖⲀⲤⲤⲒⲀⲤ 3 >

1 ⲁ̅ ⲉϣϫⲉ ⲁⲧⲉⲧⲛⲧⲱⲟⲩⲛ ϭⲉ ⲙⲛ ⲡⲉⲭⲥ ϣⲓⲛⲉ ⲛⲥⲁ ⲛⲁ ⲧⲡⲉ ⲡⲙⲁ ⲉⲧⲉⲣⲉⲡⲉⲭⲥ ⲛϩⲏⲧϥ ⲉϥϩⲙⲟⲟⲥ ϩⲓⲧⲟⲩⲛⲁⲙ ⲙⲡⲛⲟⲩⲧⲉ
Níwọ́n ìgbà tí a ti jí yín dìde pẹ̀lú Kristi ẹ máa ṣàfẹ́rí àwọn nǹkan tí ń bẹ lókè, níbi tí Kristi gbé wà tí ó jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
2 ⲃ̅ ⲙⲉⲉⲩⲉ ⲉⲛⲁ ⲧⲡⲉ ⲛⲉⲧϩⲓϫⲙ ⲡⲕⲁϩ ⲁⲛ
Ẹ máa ronú àwọn ohun tí ń bẹ lókè kì í ṣe àwọn nǹkan tí ń bẹ ní ayé.
3 ⲅ̅ ⲁⲧⲉⲧⲛⲙⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧⲛⲱⲛϩ ϩⲏⲡ ⲙⲛ ⲡⲉⲭⲥ ϩⲙ ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ
Nítorí ẹ̀yin ti kú, a sì fi ìyè yín pamọ́ pẹ̀lú Kristi nínú Ọlọ́run.
4 ⲇ̅ ⲉⲣϣⲁⲛ ⲡⲉⲭⲥ ⲟⲩⲱⲛϩ ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲧⲉ ⲡⲉⲛⲱⲛϩ ⲡⲉ ⲧⲟⲧⲉ ϩⲱⲧ ⲧⲏⲩⲧⲛ ⲧⲉⲧⲛⲁⲟⲩⲱⲛϩ ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲙⲙⲁϥ ϩⲛ ⲟⲩⲉⲟⲟⲩ
Nígbà tí Kristi, ẹni tí í ṣe ìyè yín yóò farahàn, nígbà náà ni ẹ̀yin pẹ̀lú yóò farahàn pẹ̀lú rẹ̀ nínú ògo.
5 ⲉ̅ ⲙⲟⲩⲟⲩⲧ ϭⲉ ⲛⲛⲉⲧⲛⲙⲉⲗⲟⲥ ⲉⲧϩⲓϫⲙ ⲡⲕⲁϩ ⲧⲡⲟⲣⲛⲉⲓⲁ ⲧⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲥⲓⲁ ⲡⲡⲁⲑⲟⲥ ⲧⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲁ ⲉⲑⲟⲟⲩ ⲧⲙⲛⲧⲙⲁⲓⲧⲟ ⲛϩⲟⲩⲟ ⲉⲧⲉ ⲧⲁⲓ ⲧⲉ ⲧⲙⲛⲧⲣⲉϥϣⲙϣⲉ ⲉⲓⲇⲱⲗⲟⲛ
Ẹ máa pa ẹ̀yà ara yín tí ń bẹ ní ayé run: àgbèrè, panṣágà, ìwà àìmọ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti ìwọra, nítorí pé ìwọ̀nyí jásí ìbọ̀rìṣà.
6 ⲋ̅ ⲛⲁⲓ ⲉⲣⲉⲧⲟⲣⲅⲏ ⲙⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲛⲏⲩ ⲉⲧⲃⲏⲏⲧⲟⲩ
Lórí àwọn wọ̀nyí ni ìbínú Ọlọ́run ń bọ̀ wá.
7 ⲍ̅ ⲉⲁⲧⲉⲧⲛⲙⲟⲟϣⲉ ϩⲛ ⲛⲁⲓ ϩⲱⲧ ⲧⲏⲩⲧⲛ ⲙⲡⲓⲟⲩⲟⲉⲓϣ ⲛⲛⲉϩⲟⲟⲩ ⲉⲧⲉⲧⲛⲟⲛϩ ϩⲛ ⲛⲁⲓ
Ẹ máa ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀ nígbà tí ìgbé ayé yín sì jẹ́ apá kan ayé yìí.
8 ⲏ̅ ⲧⲉⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲕⲱ ⲛⲥⲱⲧⲛ ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ⲧⲟⲣⲅⲏ ⲡϭⲱⲛⲧ ⲧⲕⲁⲕⲓⲁ ⲧⲙⲛⲧⲣⲉϥϫⲓⲟⲩⲁ ⲟⲩϣⲁϫⲉ ⲛϣⲗⲟϥ ⲙⲡⲣⲧⲣⲉϥⲉⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ ⲣⲱⲧⲛ
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ gbọdọ̀ fi àwọn wọ̀nyí sílẹ̀: ìbínú, ìrunú, àrankàn, fífi ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-ba-tẹni-jẹ́ àti ọ̀rọ̀ èérí kúrò ní ètè yín.
9 ⲑ̅ ⲙⲡⲣϫⲓϭⲟⲗ ⲉⲛⲉⲧⲛⲉⲣⲏⲩ ⲉⲁⲧⲉⲧⲛⲕⲁ ⲧⲏⲩⲧⲛ ⲕⲁϩⲏⲩ ⲙⲡⲣⲱⲙⲉ ⲛⲁⲥ ⲙⲛ ⲛⲉϥϩⲃⲏⲩⲉ
Ẹ má ṣe purọ́ fún ara yín, níwọ̀n ìgbà tí ẹ ti bọ́ ògbólógbòó ara yín pẹ̀lú ìṣe rẹ̀ sílẹ̀,
10 ⲓ̅ ⲁⲩⲱ ⲁⲧⲉⲧⲛϯ ϩⲓⲱⲧⲧⲏⲩⲧⲛ ⲙⲡⲃⲣⲣⲉ ⲡⲁⲓ ⲉⲧⲣⲃⲣⲣⲉ ⲉⲡⲥⲟⲟⲩⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⲑⲓⲕⲱⲛ ⲙⲡⲉⲛⲧⲁϥⲥⲟⲛⲧϥ
tí ẹ sì ti gbé ìgbé ayé tuntun wọ̀, èyí tí a sọ di tuntun nínú ìmọ̀ ní ìbámu pẹ̀lú àwòrán ẹni tí ó dá a.
11 ⲓ̅ⲁ̅ ⲡⲙⲁ ⲉⲧⲉ ⲙⲛ ϩⲉⲗⲗⲏⲛ ⲛϩⲏⲧϥ ϩⲓ ⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲥⲃⲃⲉ ϩⲓ ⲙⲛⲧⲁⲧⲥⲃⲃⲉ ⲃⲁⲣⲃⲁⲣⲟⲥ ⲥⲕⲩⲑⲏⲥ ϩⲙϩⲁⲗ ⲣⲙϩⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲧⲏⲣϥ ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧϩⲙ ⲡⲧⲏⲣϥ ⲡⲉ ⲡⲉⲭⲥ
Níbi tí kò gbé sí Giriki tàbí Júù, ìkọlà tàbí aláìkọlà, aláìgbédè, ara Skitia, ẹrú tàbí òmìnira, ṣùgbọ́n Kristi ni ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
12 ⲓ̅ⲃ̅ ϯϭⲉ ϩⲓⲱⲧ ⲧⲏⲩⲧⲛ ϩⲱⲥ ⲥⲱⲧⲡ ⲙⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲛⲉⲧⲟⲩⲁⲁⲃ ⲙⲙⲉⲣⲓⲧ ⲛϩⲉⲛⲥⲡⲗⲁⲭⲛⲟⲛ ⲙⲙⲛⲧϣⲁⲛϩⲧⲏϥ ⲛⲟⲩⲙⲛⲧⲭⲣⲏⲥⲧⲟⲥ ⲛⲟⲩⲑⲃⲃⲓⲟ ⲛⲟⲩⲙⲛⲧⲣⲙⲣⲁϣ ⲛⲟⲩⲙⲛⲧϩⲁⲣϣϩⲏⲧ
Nítorí náà, bí àyànfẹ́ Ọlọ́run, ẹni mímọ́ àti olùfẹ́, ẹ gbé ọkàn ìyọ́nú wọ̀, ìṣoore, ìrẹ̀lẹ̀, inú tútù àti sùúrù.
13 ⲓ̅ⲅ̅ ⲉⲧⲉⲧⲛⲁⲛⲉⲭⲉ ⲛⲛⲉⲧⲛⲉⲣⲏⲩ ⲁⲩⲱ ⲉⲧⲉⲧⲛⲕⲱ ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲛⲉⲧⲛⲉⲣⲏⲩ ⲉϣⲱⲡⲉ ⲟⲩⲁ ⲉⲟⲩⲛⲧϥ ⲟⲩⲁⲣⲓⲕⲉ ⲙⲛ ⲟⲩⲁ ⲕⲁⲧⲁ ⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁ ⲡⲉⲭⲥ ⲕⲱ ⲛⲏⲧⲛ ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲣⲓⲧⲉⲓϩⲉ ϩⲱⲧ ⲧⲏⲩⲧⲛ
Ẹ máa fi ara dà á fún ara yín, ẹ sì máa dáríjì ara yín bí ẹnikẹ́ni bá ní ẹ̀sùn sí ẹnìkan: bí Kristi ti dáríjì yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó máa ṣe pẹ̀lú.
14 ⲓ̅ⲇ̅ ⲉϫⲛ ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲧⲁⲅⲁⲡⲏ ⲉⲧⲉ ⲧⲁⲓ ⲧⲉ ⲧⲙⲣⲣⲉ ⲙⲡϫⲱⲕ ⲉⲃⲟⲗ
Àti borí gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ẹ gbé ìfẹ́ wọ̀, tí í ṣe àmùrè ìwà pípé.
15 ⲓ̅ⲉ̅ ⲁⲩⲱ ϯⲣⲏⲛⲏ ⲙⲡⲉⲭⲥ ⲙⲁⲣⲉⲥⲧⲁϫⲣⲟ ϩⲛ ⲛⲉⲧⲛϩⲏⲧ ⲧⲁⲓ ⲟⲛ ⲉⲛⲧⲁⲩⲧⲉϩⲙ ⲧⲏⲩⲧⲛ ⲉⲣⲟⲥ ϩⲙ ⲡⲥⲱⲙⲁ ⲁⲩⲱ ⲛⲧⲉⲧⲛϣⲱⲡⲉ ⲛⲣⲉϥϣⲡϩⲙⲟⲧ
Ẹ sì jẹ́ kí àlàáfíà Ọlọ́run kí ó máa ṣe àkóso ọkàn yín, sínú èyí tí a pè yín pẹ̀lú nínú ara kan; kí ẹ sì máa dúpẹ́.
16 ⲓ̅ⲋ̅ ⲡϣⲁϫⲉ ⲙⲡⲉⲭⲥ ⲙⲁⲣⲉϥⲟⲩⲱϩ ⲛϩⲏⲧ ⲧⲏⲩⲧⲛ ϩⲛ ⲟⲩⲙⲛⲧⲣⲙⲙⲁⲟ ⲉⲧⲉⲧⲛϯ ⲥⲃⲱ ϩⲛ ⲥⲟⲫⲓⲁ ⲛⲓⲙ ⲁⲩⲱ ⲉⲧⲉⲧⲛⲧⲥⲁⲃⲟ ⲙⲙⲱⲧⲛ ϩⲛ ϩⲉⲛⲯⲁⲗⲙⲟⲥ ⲙⲛ ϩⲉⲛⲥⲙⲟⲩ ⲙⲛ ϩⲉⲛⲱⲇⲏ ⲙⲡⲛⲁⲧⲓⲕⲟⲛ ϩⲣⲁⲓ ϩⲛ ⲧⲉⲭⲁⲣⲓⲥ ⲉⲧⲉⲧⲛϫⲱ ϩⲛ ⲛⲉⲧⲛϩⲏⲧ ⲉⲡⲛⲟⲩⲧⲉ
Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ Kristi máa gbé inú yín ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú ọgbọ́n gbogbo; kí ẹ máa kọ́ ọ, kí ẹ sì máa gba ara yín níyànjú nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin ẹ̀mí, ẹ máa kọrin sí Ọlọ́run ní ọkàn ọpẹ́.
17 ⲓ̅ⲍ̅ ⲁⲩⲱ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲉⲧⲛⲁⲁⲁⲩ ϩⲙ ⲡϣⲁϫⲉ ⲏ ϩⲙ ⲡϩⲱⲃ ⲛⲧⲉⲧⲛⲁⲁⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϩⲣⲁⲓ ϩⲙ ⲡⲣⲁⲛ ⲙⲡⲉⲛϫⲟⲉⲓⲥ ⲓⲏⲥ ⲉⲧⲉⲧⲛϣⲡϩⲙⲟⲧ ⲛⲧⲙⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲡⲉⲓⲱⲧ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲟⲧϥ
Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sì ń ṣe ní ọ̀rọ̀ tàbí ní ìṣe, ẹ máa ṣe gbogbo wọn ní orúkọ Jesu Olúwa, ẹ máa fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run Baba nípasẹ̀ rẹ̀.
18 ⲓ̅ⲏ̅ ⲛⲉϩⲓⲟⲙⲉ ϩⲩⲡⲟⲧⲁⲥⲥⲉ ⲛⲛⲉⲧⲛϩⲟⲟⲩⲧ ⲛⲑⲉ ⲉⲧϣⲉ ϩⲙ ⲡϫⲟⲉⲓⲥ
Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ nínú Olúwa.
19 ⲓ̅ⲑ̅ ⲛϩⲟⲟⲩⲧ ⲙⲉⲣⲉ ⲛⲉⲧⲛϩⲓⲟⲙⲉ ⲁⲩⲱ ⲙⲡⲣⲛⲟⲩϭⲥ ⲉⲣⲟⲟⲩ
Ẹ̀yin ọkọ, ẹ máa fẹ́ràn àwọn aya yín, ẹ má sì ṣe korò sí wọn.
20 ⲕ̅ ⲛϣⲏⲣⲉ ⲥⲱⲧⲙ ⲛⲥⲁ ⲛⲉⲧⲛⲉⲓⲟⲧⲉ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲙⲟⲧ ⲛⲓⲙ ⲡⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲡⲟⲩⲱϣ ⲙⲡϫⲟⲉⲓⲥ
Ẹ̀yin ọmọ ẹ máa gbọ́ ti àwọn òbí yín ní ohun gbogbo, nítorí èyí dára gidigidi nínú Olúwa.
21 ⲕ̅ⲁ̅ ⲛⲉⲓⲟⲧⲉ ⲙⲡⲣϯⲛⲟⲩϭⲥ ⲛⲛⲉⲧⲛϣⲏⲣⲉ ϫⲉ ⲛⲛⲉⲩⲟⲩⲱⲗⲥ ⲛϩⲏⲧ
Ẹ̀yin baba, ẹ má ṣe mú àwọn ọmọ yín bínú, kí wọn má bà á rẹ̀wẹ̀sì.
22 ⲕ̅ⲃ̅ ⲛϩⲙϩⲁⲗ ⲥⲱⲧⲙ ⲛⲥⲁ ⲛⲉⲧⲛϫⲓⲥⲟⲟⲩⲉ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ϩⲛ ⲟⲩⲙⲛⲧⲉⲓⲁ ⲛϭⲁⲩⲟⲛ ⲁⲛ ϩⲱⲥ ⲣⲉϥⲁⲣⲉⲥⲕⲉ ⲛⲣⲱⲙⲉ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲛ ⲟⲩⲙⲛⲧϩⲁⲡⲗⲟⲩⲥ ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲛϩⲏⲧ ⲉⲧⲉⲧⲛⲣ ϩⲟⲧⲉ ϩⲏⲧϥ ⲙⲡϫⲟⲉⲓⲥ
Ẹ̀yin ẹrú, ẹ gbọ́ ti àwọn olówó yín nípa ti ara ní ohun gbogbo; kì í ṣe ní àrọ́júṣe, bí àwọn aláṣehàn ènìyàn; ṣùgbọ́n ní òtítọ́ inú, ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
23 ⲕ̅ⲅ̅ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲉⲧⲛⲁⲁⲁⲩ ⲁⲣⲓⲥⲟⲩ ϩⲙ ⲡⲉⲧⲛϩⲏⲧ ⲧⲏⲣϥ ϩⲱⲥ ⲉⲧⲉⲧⲛⲉⲓⲣⲉ ⲙⲙⲟⲟⲩ ⲙⲡϫⲟⲉⲓⲥ ⲛⲣⲱⲙⲉ ⲁⲛ
Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá ń ṣe, ẹ máa fi tọkàntọkàn ṣe é fún Olúwa, kí í ṣe fún ènìyàn;
24 ⲕ̅ⲇ̅ ⲉⲧⲉⲧⲛⲥⲟⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲛⲁϫⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲙ ⲡϫⲟⲉⲓⲥ ⲙⲡⲧⲟⲩⲉⲓⲟ ⲛⲧⲉⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲁ ⲛⲧⲉⲧⲛⲣϩⲙϩⲁⲗ ⲙⲡϫⲟⲉⲓⲥ ⲡⲉⲭⲥ
kí ẹ mọ̀ pé lọ́wọ́ Olúwa ni ẹ̀yin ó gba èrè, nítorí ẹ̀yin ń sìn Olúwa Kristi.
25 ⲕ̅ⲉ̅ ⲡⲉⲧϫⲓ ⲅⲁⲣ ⲛϭⲟⲛⲥ ϥⲛⲁϫⲓ ⲙⲡⲧⲟⲩⲉⲓⲟ ⲙⲡϫⲓ ⲛϭⲟⲛⲥ ⲉⲛⲧⲁϥⲁⲁϥ ⲁⲩⲱ ⲙⲛ ⲙⲛⲧⲣⲉϥϫⲓ ϩⲟ
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe àìṣòdodo, yóò gbà á padà nítorí àìṣòdodo náà tí ó ti ṣe: kò sì ṣí ojúsàájú.

< ⲔⲞⲖⲀⲤⲤⲒⲀⲤ 3 >