< ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲚ 8 >

1 ⲁ̅ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲠⲒⲦⲰⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲒϪⲰⲒⲦ
Jesu sì lọ sí orí òkè olifi.
2 ⲃ̅ ⲒⲦⲀ ⲀϤⲒ ⲚϨⲀⲚⲀⲦⲞⲞⲨⲒ ⲈⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲚⲒⲘⲎ ϢⲆⲈ ⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲈϮⲤⲂⲰ ⲚⲰⲞⲨ
Ó sì tún padà wá sí tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gbogbo ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì jókòó, ó ń kọ́ wọn.
3 ⲅ̅ ⲚⲒⲀⲢⲬⲎⲈⲢⲈⲨⲤ ⲆⲈ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲀⲨⲒⲚⲒ ⲚⲀϤ ⲚⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲀⲨϪⲈⲘⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲞⲢⲚⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲀϨⲞⲤ ⲈⲢⲀⲦⲤ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi sì mú obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tí a mú nínú ṣíṣe panṣágà; wọ́n sì mú un dúró láàrín.
4 ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲪⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲦⲀⲒⲤϨⲒⲘⲒ ⲐⲀⲒ ⲀⲚϪⲈⲘⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲞⲢⲚⲒⲀ
Wọ́n sì wí fún un pé, “Olùkọ́, a mú obìnrin yìí nínú ìṣe panṣágà.
5 ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲚⲞⲘⲞⲤ ⲘⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲈϨⲒⲰⲚⲒ ⲈϪⲰⲤ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲔϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲚⲐⲞⲔ
Ǹjẹ́ nínú òfin, Mose pàṣẹ fún wa láti sọ irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ ní òkúta, ṣùgbọ́n ìwọ ha ti wí?”
6 ⲋ̅ ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲀⲨϪⲰϤ ⲈⲨⲈⲢⲠⲒⲢⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨϪⲈⲘ ⲖⲰⲒϪⲒ ϨⲒϪⲰϤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲀϤⲢⲒⲔⲒ ⲚⲚⲈϤⲂⲀⲖ ⲀϤⲤϦⲀⲒ ⲘⲠⲈϤⲦⲎⲂ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲒⲔⲀϨⲒ
Èyí ni wọ́n wí, láti dán án wò, kí wọn ba à lè rí ẹ̀sùn kan kà sí i lọ́rùn. Ṣùgbọ́n Jesu bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ń fi ìka rẹ̀ kọ̀wé ní ilẹ̀.
7 ⲍ̅ ⲈⲦⲀⲨⲰⲤⲔ ⲆⲈ ⲘⲠⲈϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲀϤϤⲀⲒ ⲚⲦⲈϤⲀⲪⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲀϬⲚⲈ ⲚⲞⲂⲒ ⲘⲀⲢⲈϤϨⲒⲰⲚⲒ ⲈϪⲰⲤ ⲚϢⲞⲢⲠ ⲚⲞⲨⲰⲚⲒ
Nígbà tí wọ́n ń bi í léèrè lemọ́lemọ́, ó gbe orí rẹ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Jẹ́ kí ẹni tí ó wà láìní ẹ̀ṣẹ̀ nínú yín kọ́kọ́ sọ òkúta lù ú.”
8 ⲏ̅ ⲦⲞⲦⲈ ⲀϤⲢⲈⲔ ϪⲰϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤϦⲀⲒ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ
Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó ń kọ̀wé ní ilẹ̀.
9 ⲑ̅ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲪⲀⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲔⲀϮ ⲈⲠⲈϤⲤⲞϨⲒ ⲀⲨⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲪⲞⲨⲀⲒ ⲪⲞⲨⲀⲒ ϢⲀⲦⲞⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲞⲨⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲰϪⲠ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲚⲈⲘ ϮⲤϨⲒⲘⲒ ⲐⲎ ⲈⲚⲀⲤⲬⲎ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ
Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, wọ́n sì jáde lọ lọ́kọ̀ọ̀kan, bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbà títí dé àwọn tí ó kẹ́yìn; a sì fi Jesu nìkan sílẹ̀, àti obìnrin náà láàrín, níbi tí ó wà.
10 ⲓ̅ ⲀⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϤⲀⲒ ⲚⲦⲈϤⲀⲪⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲰϮⲤϨⲒⲘⲒ ⲀⲨⲐⲰⲚ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞ ⲘⲘⲞⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲈϤϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞ
Jesu sì dìde, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, àwọn olùfisùn rẹ dà? Kò sí ẹnìkan tí ó dá ọ lẹ́bi?”
11 ⲓ̅ⲁ̅ ⲠⲈϪⲀⲤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ϮⲚⲀⲨ ⲀⲚ ⲈⲞⲨⲀⲒ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲒϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲈⲒⲤϪⲈⲚ ϮⲚⲞⲨ ⲘⲠⲈⲢⲦⲀⲤⲐⲞ ⲈⲈⲢⲚⲞⲂⲒ ϪⲈ
Ó wí pé, “Kò sí ẹnìkan, Olúwa.” Jesu wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni èmi náà kò dá ọ lẹ́bi, máa lọ, láti ìgbà yìí lọ, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́.”
12 ⲓ̅ⲃ̅ ⲠⲀⲖⲒⲚ ⲞⲚ ⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲪⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲘⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰⲒ ⲚⲚⲈϤⲘⲞϢⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲬⲀⲔⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲈϤⲈϬⲒ ⲘⲪⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲚⲦⲈⲠⲰⲚϦ.
Jesu sì tún sọ fún wọn pé, “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé, ẹni tí ó bá tọ̀ mí lẹ́yìn kì yóò rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n yóò ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.”
13 ⲓ̅ⲅ̅ ⲠⲈϪⲈ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲔ ⲈⲦⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞⲔ ⲦⲈⲔⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲞⲨⲘⲎⲒ ⲀⲚ ⲦⲈ.
Nítorí náà àwọn Farisi wí fún un pé, “Ìwọ ń jẹ́rìí ara rẹ; ẹ̀rí rẹ kì í ṣe òtítọ́.”
14 ⲓ̅ⲇ̅ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲔⲀⲚ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒϢⲀⲚⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞⲒ ⲞⲨⲘⲎⲒ ⲦⲈ ⲦⲀⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ϪⲈ ϮⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲈⲦⲀⲒⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲒⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲐⲰⲚ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲆⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ⲀⲚ ϪⲈ ⲈⲦⲀⲒⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲒⲈ ⲀⲒⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲐⲰⲚ.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo tilẹ̀ ń jẹ́rìí fún ara mi, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi: nítorí tí mo mọ ibi tí mo ti wá, mo sì mọ ibi tí mo ń lọ; ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò lè mọ ibi tí mo ti wá, àti ibi tí mo ń lọ.
15 ⲓ̅ⲉ̅ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϮϨⲀⲠ ⲔⲀⲦⲀ ⲤⲀⲢⲜ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϮϮϨⲀⲠ ⲈϨⲖⲒ ⲀⲚ.
Ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ nípa ti ara; èmi kò ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni.
16 ⲓ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒϢⲀⲚϮϨⲀⲠ ⲠⲀϨⲀⲠ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲘⲎⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ⲚϮⲬⲎ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲚⲞⲔ ⲚⲈⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲪⲒⲰⲦ.
Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì ṣe ìdájọ́, òtítọ́ ni, nítorí èmi nìkan kọ́, ṣùgbọ́n èmi àti Baba tí ó rán mi.
17 ⲓ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲆⲈ ⲞⲚ ϦⲈⲚⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲐⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲂⲞⲨⲐⲘⲎⲒ ⲦⲈ.
A sì kọ ọ́ pẹ̀lú nínú òfin pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí ènìyàn méjì.
18 ⲓ̅ⲏ̅ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞⲒ ⲞⲨⲞϨ ϤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞⲒ ⲚϪⲈⲪⲒⲰⲦ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ.
Èmi ni ẹni tí ń jẹ́rìí ara mi, Baba tí ó rán mi sì ń jẹ́rìí mi.”
19 ⲓ̅ⲑ̅ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ϪⲈ ⲀϤⲐⲰⲚ ⲠⲈⲔⲒⲰⲦ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲒ ⲀⲚ ⲞⲨⲆⲈ ⲠⲀⲔⲈⲒⲰⲦ ⲈⲚⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲒ ⲚⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲤⲞⲨⲈⲚ ⲠⲀⲔⲈⲒⲰⲦ.
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Níbo ni Baba rẹ wà?” Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ mí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ Baba mi, ìbá ṣe pé ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá sì ti mọ Baba mi pẹ̀lú.”
20 ⲕ̅ ⲚⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲀϤϪⲞⲦⲞⲨ ϦⲈⲚⲠⲒⲄⲀⲌⲞⲪⲨⲖⲀⲔⲒⲞⲚ ⲈϤϮⲤⲂⲰ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ϢⲀⲘⲞⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲚⲈⲘⲠⲀⲦⲈⲤⲒ ⲚϪⲈⲦⲈϤⲞⲨⲚⲞⲨ.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Jesu sọ níbi ìṣúra, bí ó ti ń kọ́ni ní tẹmpili, ẹnikẹ́ni kò sì mú un; nítorí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
21 ⲕ̅ⲁ̅ ⲠⲀⲖⲒⲚ ⲞⲚ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲈⲘⲦ ⲀⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲂⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲘⲀ ⲀⲚⲞⲔ ⲈϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲒ ⲈⲢⲞϤ.
Nítorí náà ó tún wí fún wọn pé, “Èmi ń lọ, ẹ̀yin yóò sì wá mi, ẹ ó sì kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá.”
22 ⲕ̅ⲃ̅ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ϪⲈ ⲘⲎ ⲀϤⲚⲀϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ϪⲈ ϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲒⲘⲀ ⲀⲚⲞⲔ ⲈϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ.
Nítorí náà àwọn Júù wí pé, “Òun ó ha pa ara rẹ̀ bí? Nítorí tí ó wí pé, ‘Ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá’?”
23 ⲕ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲠⲈ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚϦⲢⲎⲒ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ⲘⲠϢⲰⲒ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀⲚ.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ìsàlẹ̀ wá; èmi ti òkè wá; ẹ̀yin jẹ́ ti ayé yìí; èmi kì í ṣe ti ayé yìí.
24 ⲕ̅ⲇ̅ ⲀⲒϪⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲂⲒ ⲈϢⲰⲠ ⲄⲀⲢ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲦⲈⲘⲚⲀϨϮ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ⲚϦⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲂⲒ.
Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, nítorí bí kò ṣe pé ẹ bá gbàgbọ́ pé èmi ni, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
25 ⲕ̅ⲉ̅ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲀϤ ⲠⲈ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚϮⲀⲢⲬⲎ ⲀⲒⲈⲢ ⲠⲔⲈⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲦⲈⲚ
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ jẹ́?” Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ni èyí tí mo ti wí fún yín ní àtètèkọ́ṣe.
26 ⲕ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞⲚϮ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲈϪⲞⲦⲞⲨ ⲈⲐⲂⲈ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈϮϨⲀⲠ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲞⲨⲐⲘⲎⲒ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲒⲤⲞⲐⲘⲞⲨ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲚⲀⲒ ϮⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ.
Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ, àti láti ṣe ìdájọ́ nípa yín, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ohun tí èmi sì ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, wọ̀nyí ni èmi ń sọ fún aráyé.”
27 ⲕ̅ⲍ̅ ⲘⲠⲞⲨⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲚⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲒⲰⲦ.
Kò yé wọn pé ti Baba ni ó ń sọ fún wọn.
28 ⲕ̅ⲏ̅ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚϬ ⲈⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲢⲰⲘⲒ ⲦⲞⲦⲈ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϮⲈⲢ ϨⲖⲒ ⲀⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲀⲖⲖⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀϤⲦⲤⲀⲂⲞⲒ ⲚϪⲈⲠⲀⲒⲰⲦ ⲚⲀⲒ ϮⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
Lẹ́yìn náà Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ mọ̀ pé, nígbà tí ẹ bá gbé Ọmọ Ènìyàn sókè, nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ pé èmi ni àti pé èmi kò dá ohunkóhun ṣe fún ara mi, ṣùgbọ́n bí Baba ti kọ́ mi, èmí ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
29 ⲕ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ϤⲬⲎ ⲚⲈⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤⲬⲀⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲒⲢⲒ ⲚⲚⲎ ⲈⲐⲢⲀⲚⲀϤ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
Ẹni tí ó rán mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, kò fi mí sílẹ̀ ní èmi nìkan; nítorí tí èmi ń ṣe ohun tí ó wù ú nígbà gbogbo.”
30 ⲗ̅ ⲚⲀⲒ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲰⲞⲨ ϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ.
Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn gbà á gbọ́.
31 ⲗ̅ⲁ̅ ⲚⲀϤϪⲰ ⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚⲞϨⲒ ϦⲈⲚⲠⲀⲤⲀϪⲒ ⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ
Nítorí náà Jesu wí fún àwọn Júù tí ó gbà á gbọ́, pé, “Bí ẹ bá tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ mi ẹ ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi nítòótọ́.
32 ⲗ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲤⲞⲨⲈⲚ ⲐⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈ ⲐⲘⲎⲒ ⲈⲢ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲢⲈⲘϨⲈ.
Ẹ ó sì mọ òtítọ́, òtítọ́ yóò sì sọ yín di òmìnira.”
33 ⲗ̅ⲅ̅ ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲚ ⲚⲀ ⲠⲤⲠⲈⲢⲘⲀ ⲚⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲚⲈⲢⲂⲰⲔ ⲚϨⲖⲒ ⲈⲚⲈϨ ⲠⲰⲤ ⲚⲐⲞⲔ ⲔϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲢⲈⲘϨⲈ.
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Irú-ọmọ Abrahamu ni àwa jẹ́, àwa kò sì ṣe ẹrú fún ẹnikẹ́ni rí láé; ìwọ ha ṣe wí pé, ‘Ẹ ó di òmìnira’?”
34 ⲗ̅ⲇ̅ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲒⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲂⲒ ⲞⲨⲂⲰⲔ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲂⲒ ⲠⲈ.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni.
35 ⲗ̅ⲉ̅ ⲠⲒⲂⲰⲔ ⲆⲈ ⲘⲠⲀϤⲞϨⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲎⲒ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ ⲠⲒϢⲎⲢⲒ ⲆⲈ ⲚⲐⲞϤ ϢⲀϤⲞϨⲒ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ. (aiōn g165)
Ẹrú kì í sì í gbé ilé títí láé, ọmọ ní ń gbé ilé títí láé. (aiōn g165)
36 ⲗ̅ⲋ̅ ⲈϢⲰⲠ ⲞⲨⲚ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲠⲒϢⲎⲢⲒ ⲈⲢ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲢⲈⲘϨⲈ ⲞⲚⲦⲰⲤ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲈⲢⲢⲈⲘϨⲈ.
Nítorí náà, bí Ọmọ bá sọ yín di òmìnira ẹ ó di òmìnira nítòótọ́.
37 ⲗ̅ⲍ̅ ϮⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀ ⲠϪⲢⲞϪ ⲚⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲀⲖⲖⲀ ⲦⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲈϦⲞⲐⲂⲎⲦ ϪⲈ ⲠⲀⲤⲀϪⲒ ϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲀⲚ.
Mo mọ̀ pé irú-ọmọ Abrahamu ni ẹ̀yin jẹ́; ṣùgbọ́n ẹ ń wá ọ̀nà láti pa mí nítorí ọ̀rọ̀ mi kò rí ààyè nínú yín. Jesu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ nípa ara rẹ̀.
38 ⲗ̅ⲏ̅ ⲚⲎ ⲞⲨⲚ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲦⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲀⲒⲰⲦ ⲚⲀⲒ ϮⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲞⲐⲘⲞⲨ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲦⲈⲦⲈⲚⲒⲢⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
Ohun tí èmi ti rí lọ́dọ̀ Baba ni mo sọ, ẹ̀yin pẹ̀lú sì ń ṣe èyí tí ẹ̀yin ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ baba yín.”
39 ⲗ̅ⲑ̅ ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲠⲈⲚⲒⲰⲦ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲚⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲈⲚϢⲎⲢⲒ ⲚⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲠⲈ ⲚⲒϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲚⲦⲈⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲚⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲀⲒⲦⲞⲨ.
Wọ́n dáhùn, wọ́n sì wí fún un pé, “Abrahamu ni baba wa!” Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ìbá ṣe iṣẹ́ Abrahamu.
40 ⲙ̅ ϮⲚⲞⲨ ⲆⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲈϦⲞⲐⲂⲎ ⲦⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈϤϪⲰ ⲚⲐⲘⲎⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲐⲎ ⲈⲦⲀⲒⲤⲞⲐⲘⲈⲤ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲪⲀⲒ ⲘⲠⲈ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲀⲒϤ.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń wá ọ̀nà láti pa mí, ẹni tí ó sọ òtítọ́ fún yín, èyí tí mo ti gbọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Abrahamu kò ṣe èyí.
41 ⲙ̅ⲁ̅ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲒⲢⲒ ⲚⲚⲒϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲚⲦⲈⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲀⲚϪⲪⲞ ⲀⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲠⲞⲢⲚⲒⲀ ⲞⲨⲒⲰⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲈⲦⲈⲚⲦⲀⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ.
Ẹ̀yin ń ṣe iṣẹ́ baba yín.” Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “a kò bí wa nípa panṣágà, a ní Baba kan, èyí sì ni Ọlọ́run.”
42 ⲙ̅ⲃ̅ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲈⲚⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲠⲈ ⲚⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲘⲈⲚⲢⲒⲦ ⲠⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲄⲀⲢ ⲈⲦⲀⲒⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲒⲒ ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲚⲈⲦⲀⲒⲒ ⲀⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲐⲞϤ ⲠⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ.
Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ̀yin ìbá fẹ́ràn mi, nítorí tí èmi ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run jáde, mo sì wá; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n òun ni ó rán mi.
43 ⲙ̅ⲅ̅ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲀϪⲒⲚⲤⲀϪⲒ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲀⲚ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲀⲤⲀϪⲒ.
Èéṣe tí èdè mi kò fi yé yín? Nítorí ẹ kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
44 ⲙ̅ⲇ̅ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲈⲠⲒⲐⲨⲘⲒⲀ ⲚⲦⲈⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰϢ ⲈⲀⲒⲦⲞⲨ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲚⲈⲞⲨⲢⲈϤϦⲀⲦⲈⲂ ⲢⲰⲘⲒ ⲠⲈ ⲒⲤϪⲈⲚ ϨⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ϦⲈⲚⲐⲘⲎⲒ ⲈⲚⲈϨ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ϢⲞⲠ ⲚϦⲎⲦϤ ⲈϢⲰⲠ ⲀϤϢⲀⲚⲤⲀϪⲒ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲈⲐⲚⲞⲨϪ ϢⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲞⲨϤ ϪⲈ ⲞⲨⲤⲀⲘⲈⲐⲚⲞⲨϪ ⲠⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲔⲈⲒⲰⲦ.
Ti èṣù baba yin ni ẹ̀yin jẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ baba yín ni ẹ sì ń fẹ́ ṣe. Apànìyàn ni òun jẹ́ láti àtètèkọ́ṣe, kò sì dúró nínú òtítọ́; nítorí tí kò sí òtítọ́ nínú rẹ̀. Nígbà tí ó bá ń ṣèké, nínú ohun tirẹ̀ ni ó ń sọ nítorí èké ni, àti baba èké.
45 ⲙ̅ⲉ̅ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϮϪⲰ ⲚⲐⲘⲎⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞⲒ ⲀⲚ.
Ṣùgbọ́n nítorí tí èmi ń sọ òtítọ́ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbà mí gbọ́.
46 ⲙ̅ⲋ̅ ⲚⲒⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲐⲚⲀⲤⲞϨⲒ ⲘⲘⲞⲒ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨⲚⲞⲂⲒ ⲒⲤϪⲈ ⲐⲘⲎⲒ ⲦⲈϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲒⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞⲒ ⲀⲚ.
Ta ni nínú yín tí ó ti dá mi lẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀? Bí mo bá ń ṣọ òtítọ́, èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà mí gbọ́?
47 ⲙ̅ⲍ̅ ⲠⲒⲈⲂⲞⲖ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϢⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲦⲈⲘ ⲀⲚ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲀⲚ.
Ẹni tí ń ṣe ti Ọlọ́run, a máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, nítorí èyí ni ẹ̀yin kò ṣe gbọ́, nítorí ẹ̀yin kì í ṣe ti Ọlọ́run.”
48 ⲙ̅ⲏ̅ ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲔⲀⲖⲰⲤ ⲀⲚⲞⲚ ⲀⲚϪⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲤⲀⲘⲀⲢⲒⲦⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲀⲔ.
Àwọn Júù dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò wí nítòótọ́ pé, ará Samaria ni ìwọ jẹ́, àti pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù?”
49 ⲙ̅ⲑ̅ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲘⲘⲞⲚ ⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲎⲒ ⲀⲖⲖⲀ ϮⲈⲢⲦⲒⲘⲀⲚ ⲘⲠⲀⲒⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚϢⲰϢ ⲘⲘⲞⲒ.
Jesu sì dáhùn pé, “Èmi kò ní ẹ̀mí èṣù, ṣùgbọ́n èmi ń bu ọlá fún Baba mi, ẹ̀yin kò sì bu ọlá fún mi.
50 ⲛ̅ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲚⲀⲒⲔⲰϮ ⲚⲤⲀⲠⲀⲰⲞⲨ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲀⲚ ϤϢⲞⲠ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲦⲔⲰϮ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦϮϨⲀⲠ.
Èmi kò wá ògo ara mi, ẹnìkan ń bẹ tí ó ń wá a tí yóò sì ṣe ìdájọ́.
51 ⲛ̅ⲁ̅ ⲀⲘⲎⲚ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲀⲢⲈϨ ⲈⲠⲀⲤⲀϪⲒ ⲚⲚⲈϤⲚⲀⲨ ⲈⲪⲘⲞⲨ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ. (aiōn g165)
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò rí ikú láéláé.” (aiōn g165)
52 ⲛ̅ⲃ̅ ⲠⲈϪⲈ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ϪⲈ ϮⲚⲞⲨ ⲀⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲀⲔ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲀϤⲘⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲔⲈⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞⲔ ⲔϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲀⲢⲈϨ ⲈⲠⲀⲤⲀϪⲒ ⲚⲚⲈϤϪⲈⲘϮⲠⲒ ⲘⲪⲘⲞⲨ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ. (aiōn g165)
Àwọn Júù wí fún un pé, “Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù. Abrahamu kú, àti àwọn wòlíì; ìwọ sì wí pé, ‘Bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò tọ́ ikú wò láéláé.’ (aiōn g165)
53 ⲛ̅ⲅ̅ ⲘⲎ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲐⲞⲔ ⲈⲠⲈⲚⲒⲰⲦ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲔⲈⲠⲢⲞⲪⲎ ⲦⲎⲤ ⲀⲨⲘⲞⲨ ⲀⲔⲒⲢⲒ ⲘⲘⲞⲔ ⲚⲚⲒⲘ.
Ìwọ ha pọ̀ ju Abrahamu Baba wa lọ, ẹni tí ó kú? Àwọn wòlíì sì kú, ta ni ìwọ ń fi ara rẹ pè?”
54 ⲛ̅ⲇ̅ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒϢⲀⲚϮⲰⲞⲨ ⲚⲎⲒ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲠⲀⲰⲞⲨ ϨⲖⲒ ⲠⲈ ϤϢⲞⲠ ⲚϪⲈⲠⲀⲒⲰⲦ ⲈⲐⲚⲀϮⲰⲞⲨ ⲚⲎⲒ ⲪⲎ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲦⲈⲚϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲈⲚⲚⲞⲨϮ ⲠⲈ
Jesu dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ nǹkan, Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe.
55 ⲛ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲞⲨⲰⲚϤ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲒϢⲀⲚϪⲞⲤ ϪⲈ ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ ⲈⲒⲈϢⲰⲠⲒ ⲈⲒⲞⲚⲒ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲚⲤⲀⲘⲈⲐⲚⲞⲨϪ ⲀⲖⲖⲀ ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϤⲤⲀϪⲒ ϮⲀⲢⲈϨ ⲈⲢⲞϤ.
Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.
56 ⲛ̅ⲋ̅ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲠⲈⲦⲈⲚⲒⲰⲦ ⲚⲀϤⲐⲈⲖⲎⲖ ⲠⲈ ⲈϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲚⲀⲨ ⲈⲞⲨⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲦⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲀϤⲢⲀϢⲒ.
Abrahamu baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi, ó sì rí i, ó sì yọ̀.”
57 ⲛ̅ⲍ̅ ⲠⲈϪⲈ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲘⲠⲀⲦⲈⲔⲈⲢ ⲚⲚⲢⲞⲘⲠⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲔⲚⲀⲨ ⲈⲀⲂⲢⲀⲀⲘ.
Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Abrahamu?”
58 ⲛ̅ⲏ̅ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲘⲠⲀⲦⲈ ⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ϢⲰⲠⲒ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Abrahamu tó wà, èmi ti wa.”
59 ⲛ̅ⲑ̅ ⲀⲨⲈⲖ ⲰⲚⲒ ⲞⲨⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈϨⲒⲞⲨⲒ ⲈϪⲰϤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲀϤⲬⲞⲠϤ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲒⲚⲒ ⲚⲀϤⲘⲞϢⲒ ϦⲈⲚⲦⲞⲨⲘⲎϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲤⲒⲚⲒⲰⲞⲨ.
Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú, ṣùgbọ́n Jesu fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹmpili.

< ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲚ 8 >