< Masengo 7 >
1 Nipele, Jwambopesi Jwankulu ŵambusisye che Stefano, “Ana yelei ni iyoyo?”
Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
2 Che Stefano nombe ŵaajanjile, “Achalongo achinjangu ni achatati, mumbilikanile! Akunnungu Ŵakulu ŵaakopochele atati ŵetu che Iblahimu paŵaliji ku Mesopotamia akanaŵe kwaula kukutama ku Halani.
Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
3 Akunnungu ŵansalile che Iblahimu, ‘Ntyoche mchilambo chenu, mwaleche ŵandu ŵa lukosyo lwenu, njaule kuchilambo chatinganlanjile cho.’
Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
4 Nipele, che Iblahimu ŵasamile chilambo cha Ŵakalidayo, ŵajawile kukutama ku Halani. Paŵawile atatigwe, Akunnungu ŵansamisye sooni ku Halani ni kwika kukutama ku chilambo chino munkutamanga ŵanyamwe sambano jino.
“Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
5 Akunnungu nganiŵapa che Iblahimu namose chipande cha chilambo chi kuti chiŵe chao, nambo ŵannanjile kwapa chilambo chi chiŵe chakwe nsyene ni cha uŵelesi wakwe, namuno katema ko ŵaliji akanaŵe kola mwanache.
Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
6 Akunnungu ŵansalile yeleyi, ‘Uŵelesi wenu chiutame mu chilambo cha chilendo, ni kweleko chachatenda achikapolo ni kwasausya yaka mia nne.
Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
7 Nambo Akunnungu akuti, uneji chinjalamula ŵandu ŵa chilambo uchachatenda achikapolo. Nipele chinjakoposya mchilambo cho ni kwaikanawo apano kuti ambopele.’
Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
8 Ni Akunnungu ŵatesile malangano ni che Iblahimu ga kuumbala gaŵe chimanyisyo cha kugakunda malangano gao. Nipele che Iblahimu ŵambumbesye che Isaka mwanagwe pa lyuŵa lya ncheche ni ncheche pakumala kupagwa. Ni che Isaka nombe ŵambumbesye che Yakobo mwanagwe, ni che Yakobo nombe ŵaatesile iyoyo peyo achambuje ŵetu likumi ni ŵaŵili ŵala.
Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
9 “Aŵala achambuje ŵetu ŵankolele wiu che Yusufu, ni ŵansyumisye aŵe kapolo ku chilambo cha Misili. Nambo Akunnungu ŵaliji pamo nawo,
“Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
10 ni kunkulupusya mmasausyo gakwe gose. Akunnungu ŵampele che Yusufu upile ni lunda paujo pa Falao, mwenye jwa ku Misili, ni mwenye Falao ŵammisile che Yusufu kuŵa jwankulu jwa chilambo ni jwa wose ŵaali mu nyuumba jao ja chimwenye.
ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
11 Nipele kwatyochele sala jajikulungwa pa chilambo cha ku Misili ni ku Kanaani, ni ŵandu ŵalasile kwannope ligongo lya sala. Achambuje ŵetu nganakombola kuchipata chakulya chachilichose.
“Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
12 Nipele, che Yakobo paŵapilikene kuti kwana yakulya ku Misili ko, ŵaalajisye achiŵanagwe, yaani achatati ŵetu, ajaulangane kaandanda ku Misili ko.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
13 Ni pa ulendo wao waŵili, che Yusufu ŵalikolasile kwa achapwakwe, ni mwenye jwa ku Misili ŵalumanyilile lukosyo lu che Yusufu.
Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
14 Ni che Yusufu ŵaalajisye ŵandu kukwaŵilanga che Yakobo atatigwe ni achalongo achinjakwe wose, ŵandu sabini na mbili aichanje ku Misili.
Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
15 Che Yakobo ŵajawile ku Misili, kweleko ni kuŵawilile pamo ni achambuje ŵetu.
Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
16 Ni malilo gao gajigalikwe mpaka ku Shekemu, ni kusikwa mwilembe liŵasumile che Iblahimu kutyochela ku lukosyo lwa Hamoli kwa mbiya simpepe.”
A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
17 “Nambo pikaiche katema ka chilanga chiŵalumbile Akunnungu ku che Iblahimu, ŵandu ŵala ŵatupile ni konjecheka kwa nnope ku Misili kula.
“Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
18 Nipele ŵajimwiche mwenye jwine ku Misili jwanganammanyilila che Yusufu.
Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
19 Mwenye jo ŵaatesile yangalumbana ni kwaonela achambuje ŵetu kwa kwakanganichisya akaajase achiŵana ŵao achanandi kuti nganasaka akole umi.
Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
20 Katema ko che Musa ŵapagwile, nombejo ŵaliji jwambone paujo pa Akunnungu. Ŵalelitwe pa musi pa atatigwe kwa miesi jitatu,
“Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
21 ni paŵalepele kungosa mwakupunda mu nyuumba ŵankopwesye paasa, mwali jwa mwenye jwa ku Misili ŵanjigele ni kunlela mpela mwanagwe nsyene.
Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
22 Che Musa ŵajigenywe indu ya lunda lwa Ŵamisili nombejo ŵaliji jwakulimbangana kwa maloŵe ni masengo.
A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
23 “Paŵaliji ni yaka alobaini, ntima wakwe wasachile kwajimajimila achinjakwe Ŵaisilaeli kukulola indu iŵapanganyichiswaga.
“Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
24 Kweleko ŵambweni Mmisili jumo achimpanganyichisyaga yangalumbana jumo jwa achalongo achinjakwe, ŵapokasisye, ni che Musa kwakwauchisya ŵambuleje Mmisili jula.
Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
25 Ŵaganisisye kuti achalongo achinjakwe Ŵaisilaeli akaimanyilile kuti Akunnungu akuntuma jwelejo kwakulupusya, nambo nganaimanyilila.
Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
26 Malaŵi jakwe, ŵaweni Ŵaisilaeli ŵaŵili ali nkuputana achinsyene pe, ni ŵalinjile kwajilanya achitiji; ‘Ŵanyamwe ndi ŵa lukosyo lumo, ligongo chi nkusaka kuulasyana achinsyene pe?’
Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
27 Nambo jwejula juŵamputaga njakwe jula ŵantutile pambali che Musa ni kunsalila, ‘Ana ŵaani ŵambisile mmwejo kuŵa chilongola ni jwakulamula pa uweji?
“Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
28 Ana nkusaka kumulaga mpela imwatite pakummulaga Mmisili jula liiso?’
Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
29 Che Musa paŵagapilikene maloŵe go ŵatisile, ŵatemi ku chilambo cha ku Midiani nti jwannendo, ni kweleko ŵaŵelechele ŵanache ŵaŵili ŵachilume.
Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
30 “Payaichile yaka alobaini, katumetume jwa kwinani jwa Ambuje jwankopochele che Musa pa chisukutu chichakolelaga mooto kwipululu kula pachiŵandi ni Litumbi lya Sinai.
“Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
31 Che Musa ŵachisimonjile nnope chichaoneche cho, ŵasejelele pachiŵandi kukulolechesya uchenene, nambo ŵapilikene liloŵe lya Ambuje lilinkuti,
Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
32 ‘Uneji ndili Akunnungu ŵa achambuje ŵenu, Akunnungu ŵa che Iblahimu ni ŵa che Isaka ni ŵa che Yakobo!’ Che Musa ŵatetemele kwa lipamba ni nganapunda kulolechesya sooni.
wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
33 Ambuje ŵansalile, ‘Mmuule italawanda yenu pakuŵa pelepo panjimi pali papaswela.
“Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
34 Naiweni yangalumbana yakwapanganyichisya ŵandu ŵangu ŵakutama ku Misili. Mbilikene kulilasika kwao none ndulwiche kukwakulupusya, ni sambano chinantume ku Misili.’
Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
35 “Che Musa aju ni jwejula juŵankanile Ŵaisilaeli paŵansalile, ‘Ana ŵaani ŵambisile mmwejo kuŵa chilongola ni jwakulamula pa uweji?’ Kwa litala lya julajula katumetume jwa kwinani juŵankopochele che Musa mu chisukutu chichakolelaga mooto, Akunnungu ŵantumile che Musa wo aŵe chilongola ni nkulupusyo.
“Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
36 Jwelejo ni juŵaalongwesye ŵandu akopoche ku Misili kwa kupanganya imanyisyo ni yakusimonjeka mu chilambo cha ku Misili ni mu bahali ja Shamu ni mwipululu, kwa yaka alobaini.
Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
37 Che Musa ni juŵaasalile Ŵaisilaeli, ‘Akunnungu chanjimuchisye jwakulondola mpela uneji kutyochela mwa achalongo achinjenu mwachinsyene.’
“Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
38 Ŵaisilaeli paŵasongangene mwipululu mula, che Musa ŵaliji kweleko pamo ni achambuje ŵetu ni katumetume jwa kwinani juŵaŵechete najo mu Litumbi lya Sinai. Jweleju ni juŵagapochele maloŵe gagakwikanawo umi kutupa uweji.
Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
39 “Nambo achambuje ŵetu nganasakanga kumpilikanila che Musa, ŵantutile pambali ni ŵasachile mmitima jao kuujila ku Misili.
“Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
40 Ŵansalile che Haluni, ‘Ntupanganyichisye achiminungu jati tujipopelele ni jitulongosye mwitala, pakuŵa che Musa juŵatulongwesye kopoka ku Misili ngatukuchimanyilila chichasimene!’
Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
41 Katema ko ŵapanganyisye chinyago cha ng'ombe ja mwana, ni ŵatasile mbopesi kwa chinyago ni kuchijangalila chindu chichaliji masengo ga makono gao achinsyene.
Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
42 Nambo Akunnungu ŵatyosile pa ŵanyawo, ŵaalesile asipopele ndondwa sya kwiunde, mpela yaitite pakulembekwa mchitabu cha ŵakulondola ŵa Akunnungu, ‘Ŵanyamwe ŵandu ŵa chilambo cha ku Isilaeli! Ana ŵanyamwe mwambelechele inyama yesinje ni sadaka kwa yaka alobaini mwipululu mula?
Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
43 Ŵanyamwe mwalijigele lisakasa lya nnungu jwenu Moleki, ni chinyago cha ndondwa ja nnungu jwenu Lefani. Inyago imwaipanganyisye ni iyoyo imwaipopele. Kwa ligongo lyo chinansamichisye ku ukapolo kwakutalika kupita ku Babeli!’
Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
44 Achambuje ŵenu ŵakwete lisakasa lya umboni lyalikulosya kuti Akunnungu ali mwele mwipululu. Lisakasa lila lyakolochekwe mpela Akunnungu iŵatite pakwasalila che Musa akolosye, chisau ni achila chiŵachiweni.
“Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
45 Nipele achambuje ŵetu ŵapochelangene achinsyene pe mpaka katema ka che Yoshua, paŵachipatile chilambo chi kutyochela kwa ŵandu ŵaŵaŵinjikwe ni Akunnungu paujo pao. Lyatemi pelepo mpaka katema ka che Daudi.
Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
46 Che Daudi ŵanonyelwe ni Akunnungu nombe che Daudi ŵaŵendile Akunnungu ŵaataŵile nyuumba ŵele ŵaali Akunnungu ŵa che Yakobo.
Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
47 Nambo che Selemani ni juŵantaŵile Akunnungu nyuumba.”
Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
48 “Natamuno yeleyo, Akumanani ngakutama mmajumba gagataŵikwe ni ŵandu, mpela yakuti jwakulondola jwa Akunnungu,
“Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
49 Ambuje akuti, ‘Kwinani kuli chitengu changu cha umwenye ni chilambo chili pakuŵichila makongolo gangu. Nyuumba jati uli jichimundaŵile une, ni liuto chi pachimbumulile?
“‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
50 Ana ngaŵa uneji jumbanganyisye yelei yose?’”
Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
51 Che Stefano ŵapundile kuŵecheta, “Ŵakukanila achakulungwa ŵanyamwe! Mitima ni mawiwi genu gali mpela ga ŵandu ŵangakwamanyilila Akunnungu. Ŵanyamwe nli mpela achambuje ŵenu, moŵa gose nkukanilana ni Mbumu jwa Akunnungu.
“Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
52 Ana jwapi mwa ŵakulondola jwangananlagasya achambuje ŵenu? Ŵaauleje ŵelewo ŵaŵalajiswe kalakala ni Akunnungu asale kwika kwa ajula jwakupanganya yaili yambone. Ni sambano ŵanyamwe mungalawiche ni kumbulaga.
Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
53 Ŵanyamwe mwagapochele Malajisyo ga Akunnungu gagaiche kukwenu ni achikatumetume ŵa kwinani, nambo nganingakamulichisya.”
Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
54 Achakulu ŵa Nkungulu paŵagapilikene maloŵe go, yachimile nnope ni kuchilimya meeno.
Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
55 Nambo che Stefano ali aguumbele Mbumu jwa Akunnungu, ŵalolite kwinani, ŵauweni ukulu wa Akunnungu ni Che Yesu ali ajimi kundyo kwa Akunnungu.
Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
56 Ni ŵatite, “Nnole! Ngukuwona kwinani kwakuugule ni Mwana jwa Mundu ajimi kundyo kwa Akunnungu.”
Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
57 Pelepo ŵandu wose ŵaŵaliji pa Nkungulu ula ŵagumisile kwa liloŵe lyekulungwa ni kusiŵila mawiwi ni makono gao. Nipele ŵanguluchile ŵanawose kwana kamo,
Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
58 Ni ŵankopwesye mmusi ni kumponya maganga. Ŵaumboni ŵala ŵaŵisile yakuwala yao kwa jwanchanda jumo liina lyakwe che Sauli kuti aigose.
wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
59 Paŵapundile kwaponya maganga, che Stefano ŵapopele achitiji, “Alakwe Ambuje Che Yesu, mpochele mbumu jangu!”
Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
60 Ŵatindiŵele ni ŵanyanyisye achitiji, “Ambuje nkaaŵalanjila sambi si.” Paŵaŵechete yeleyo ŵajasiche. Ni che Sauli ŵakundile kuti che Stefano akuŵajilwa kuulajikwa.
Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.