< 何西阿書 8 >

1 你要把號角放你的口上,當作上主家的哨兵,因為百姓違背了我的盟約,,干犯了我的法律。
“Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
2 他們呼喊我說:以色列的天主! 我們認識你。
Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
3 但以色列拋棄了善,所以敵人要迫害她。
Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
4 他們自立了君王,卻沒有我的同意;他們自立了首領,卻沒有叫知道;他們用金錢為自己製造了偶像,給自己招來滅亡。
Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
5 撒馬黎雅! 我必要除掉你的牛犢,我的怒火必要對牠燃起;以色列子民不能自新要到幾時呢﹖
Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
6 牛犢是工匠製造的,牠並不是天主;撒馬黎雅的牛犢必定被粉碎!
Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
7 他們既播種了風,收的也必是風;麥子不抽穗,做不成麵粉;既使做出麵粉來,也必被外邦人吃掉。
“Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
8 以色列疲吞滅了,今後在列邦中必成為一個無用的廢物。
A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
9 他們去投奔亞述──一匹孤獨的野驢──同時又給埃及送愛情的禮物。
Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
10 縱然他們在列邦中行賄,我現在就要分散他們,使他們暫時停止給君王和領袖傅油。
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
11 厄弗辣因建築了許多祭壇,但這些祭壇卻只有犯罪的用途。
“Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
12 雖然我為他們寫了許多法律,卻被看作陌生人的廢話。
Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
13 讓他們奉獻燔祭,讓他們取吃祭肉;這一切上主都不喜歡;今後衪必記住他們的邪惡,必懲罰他們的罪孽;他們必要回到埃及去。
Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
14 以色列忘了自己的造主,建立了許多宮殿,猶大也增建了許多堅固的城池;但是,我必要把火投在你們的1城中,吞滅城中的宮室。
Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”

< 何西阿書 8 >