< Ruth 1 >

1 Lawkcengkung ni a uknae tueng nah Isarel ram takang a tho teh, Judah ram Bethlehem tami buet touh teh a yucanaw hoi Moab kho kampuen hanlah a cei awh.
Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
2 Ahnie min teh Elimelek. A yu min teh Naomi, a ca roi e a min teh Mahlon hoi Khilion. Ahnimouh teh Judah ram, Bethlehem kho, Ephraim tami lah ao. Moab ram lah a cei teh hawvah ao awh.
Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
3 Naomi teh a vâ, Elimelek a due hnukkhu a capa roi hoi cungtalah kho a sak awh.
Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
4 A ca roi ni Moab napui, Orpah hoi Ruth hah a yu lah a la roi.
Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
5 Hote ram dawk kum hra touh hane ao awh hnukkhu, hote a capa roi Mahlon hoi Khilion hai a due roi dawkvah Naomi teh a vâ hoi a ca laipalah ao.
Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
6 Cathut ni a taminaw a khet teh khobu a tho sak tie Moab ram hoi a thai navah, Moab ram hoi ban hanlah a langa roi hoi a kamthaw awh teh,
Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
7 Judah ram lah a cei awh.
Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
8 Hatei, Naomi ni a langa roi hanlah na manu im lah ban roi leih, kadout tangcoung naw hoi kai koe na saknae phu teh Cathut ni yawhawi na poe roi lawiseh.
Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
9 Nangmouh roi ni na vâ alouke na sak roi hnukkhu kanawmcalah na o roi nahan yawhawinae na poe lawiseh ati teh, a kut a man roi. Ahnimouh roi hai a khuika roi.
Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
10 Bangtelah hai thoseh nama hoi cungtalah, na miphunnaw koe kâbang han atipouh roi.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
11 Naomi nihai, ka canu roi, ban roi leih. Bangkongmaw kai koe na kâbang roi han. kai teh nangmouh roi hanlah ka vonthung ca tongpa ka tawn rah maw.
Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
12 Ka canu roi, ban roi leih. kai teh nangmouh roi na ngaihawi nahanelah ka kumcue toung dawkvah vâ hai ka tawn thai mahoeh toe. Hatei, vâ ka tawn nakunghai thoseh, sahnin tangmin vah ca tongpanaw ka khe ei nakunghai thoseh,
Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
13 Ahnimouh a nawsai ditouh na ring thai han na maw. Vâ laipalah ahnimanaw ngaihawi rah vaw, ka canu roi hottelah nahoeh. Cathut e kut teh kai koe ao hoeh toung dawkvah nangmouh roi hanlah lungpatawnae ka tawn atipouh navah
ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
14 Ahnimanaw teh puenghoi bout a ka awh. Hahoi, Orpah ni a mani hah a paco teh a imthungnaw koe a ban takhai. Hatei, Ruth teh a mani hoi cungtalah o hane a kârawi.
Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
15 Naomi ni na hmau teh na miphun cathut koe a ban toe. Na hmau e hnuk vah kâbang van leih atipouh navah,
Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
16 Ruth ni nang hoi na kampek sak hanh. Nang koe ka cei hoeh nahanlah sak hanh. Na ceinae pueng koe ka cei han. Na inae koe ka i han. Na miphun teh ka miphun lah ao han. Na Cathut teh ka Cathut lah ao han.
Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
17 Na duenae koe ka due vaiteh kâpakawp han. Duenae laipalah bang ni hai kapek pawiteh Cathut ni kai koe het hlak hai hno sak naseh, telah atipouh.
Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
18 Ruth ni lungtang lahoi a hnukkâbang han ati e Naomi ni a hmu navah lawkkamuem lah a o
Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
19 Ahnimouh roi teh a kamthaw roi teh Bethlehem a pha roi navah, taminaw ni ruengrueng ati awh teh, hetheh, Naomi namaw telah a pacei awh.
Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
20 Naomi ni kai heh Naomi telah na kaw awh hanh lawih. Marah telah na kaw awh lawih. Bangkongtetpawiteh, a Thakasaipounge ni kakhat e hno na poe.
Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
21 Kai teh bawirengnae hoi ka tâco. Hatei, roedeng teh takcaici hoi Cathut ni bout na bankhai. A Thakasaipounge ni kai na pabo teh na roedeng sak dawkvah bangkongmaw Naomi telah na kaw awh, atipouh.
Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
22 Hottelah, Moab kho hoi ka kâbang e Moab napui, a langa hoi Bethlehem kho vah canga tue nah a pha roi.
Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.

< Ruth 1 >