< Joshua 24 >

1 Hahoi Joshua ni Isarel miphunnaw abuemlah Shekhem kho dawk a kamkhueng sak teh, Isarel miphun dawk e kacuenaw, kaukkungnaw, lawkcengkungnaw bawinaw hah a kaw teh, ahnimouh ni Cathut e hmalah a hnai awh.
Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
2 Hahoi Joshua ni taminaw abuemlah koe a pathang e teh, Isarelnaw e BAWIPA ni kâ a poe e teh, Abraham hoi Nahor e a na pa Terah koehoi kamtawng teh, nangmae mintoenaw ni, a yan e tueng dawk tuipui namran lah ao awh teh, alouke cathutnaw hah a bawk awh.
Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
3 Nangmae na pa Abraham teh tuipui namran lah, ka kaw teh, Kanaan ram e hmuen koe ka hrawi teh, ahnie miphunnaw ka pung sak teh Isak hah ka poe.
Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
4 Isak koehoi Jakop hoi Esaw hah kai ni ka poe teh, Esaw hai Seir mon hah ka poe. Jakop hoi ahnie canaw ni Izip ram lah a cei awh.
àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
5 Mosi hoi Aron teh kai ni ka patoun teh, Izip taminaw koe a sak e patetlah Izip ram hah ka toun hnukkhu nangmanaw hah na tâco sak.
“‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
6 Telah nangmae mintoenaw hah Izip ram hoi kai ni ka tâco sak teh, ahnimouh ni Edom tuipui koe a pha awh. Izip taminaw ni rangleng hoi marangransanaw hoi tuipui totouh a pâlei awh.
Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
7 BAWIPA koe a hram awh torei teh, nangmouh hoi Izip taminaw a rahak hmonae hah kai ni ka ta teh, ahnimanaw hah, tuipui hoi muen ka ramuk sak. Izip ram dawk kai ni ka sak e hno hah, namamouh roeroe ni na hmu awh. Kahrawng dawk hai atueng moikasawlah na o awh.
Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
8 Hathnukkhu, Jordan palang kanîtholah kaawm e Amornaw e ram dawk nangmanaw hah kai ni na hrawi teh, ahnimouh ni na tuk awh navah ahnimouh teh nangmae kut dawk kai ni na poe teh, ahnimae talai hah, nangmouh ni na la pouh awh. Ahnimouh teh nangmae hmalah, kai ni koung ka raphoe.
“‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
9 Moab siangpahrang Zippor e capa Balak ni a thaw teh, Isarelnaw hah a tuk teh nangmanaw hah, thoebo sak hanelah, Beor e capa BaLaam hah a kaw torei teh,
Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
10 BaLaam e lawk kai ni ka ngâi pouh hoeh dawkvah, yawhawinae hah letlang a poe teh, ahnie kut dawk hoi nangmanaw hah kai ni na hlout sak awh.
Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
11 Hahoi nangmanaw ni Jordan palang na raka teh, Jeriko kho dawk na pha toteh, Jeriko tami, Amor tami, Periz tami, Kanaan tami, Hit tami, Gigashite tami, Hiv tami, Jubusitnaw hah na tuk awh teh, ahnimanaw hah nangmae kut dawk kai ni na poe.
“‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
12 Nangmouh dawk tahloi hoi licung awm laipalah, nangmae hmalah khoingan hah ka tha teh, Amor siangpahrang kahni touh nangmae hmalah kai ni ka pâlei.
Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
13 Nangmouh ni kho na thawng awh hoeh e khonaw hah kai ni na poe awh teh, nangmouh ni na o nah awh. Namamouh ni na ung hoeh e misur takha, olive takha naw hah, na ca awh telah, BAWIPA ni atipouh.
Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
14 Atuteh, Cathut hah, taket nateh, lungthin kathoung hoi, yuemkamcunae hoi bawk awh. Tuipui namran dawk, Izip ram dawk, mintoenaw ni a bawk e cathutnaw hah pahnawt nateh, BAWIPA duengma bawk awh.
“Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
15 Nahoeh pawiteh, BAWIPA hah bawk hanelah awmhoeh telah na pouk pawiteh, tuipui namran lae, mintoenaw ni a bawk e cathut, nangmouh na onae Amor ram dawk e cathutnaw thung dawk bangpatet e cathutnaw maw na bawk awh han tie hah sahnin kârawi awh leih. Kai hoi ka imthung niteh, Jehovah duengdoeh ka bawk awh han ati navah,
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
16 Taminaw ni alouke cathutnaw hah bawk hanelah Cathut hah pahnawtnae teh kaimouh hoi kâhlat naseh.
Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
17 Kaimae BAWIPA ni san lah onae Izip ram hoi mintoenaw hoi kaimanaw hah na tâco sak teh, kalenpounge mitnoutnaw hah kaimae mithmu vah a kamnue sak. Kaimouh ka ceinae hmuen pueng koe, ka cei sin e miphunnaw koe na okhai.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
18 BAWIPA ni hai hete ram dawk kaawm e Amornaw abuemlah kaimae hmalah hoi a pâlei toe. BAWIPA hah ka bawk han. Hote BAWIPA teh kaimae Cathut doeh telah bout ati awh.
Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
19 Joshua ni vah nangmouh ni BAWIPA hah na bawk thai mahoeh. Hote BAWIPA teh, kathounge Cathut, dipma ka sin e BAWIPA lah ao. Nangmouh ni na payon e yonnaw hah, na ngaithoum thai mahoeh.
Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
20 Nangmouh ni BAWIPA hah na pahnawt teh, ram alouke cathutnaw hah, na bawk pawiteh, nangmouh dawk hawinae ka sak hnukkhu bout ka kamlang vaiteh, na rektap awh vaiteh na raphoe awh han telah atipouh navah,
Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
21 Taminaw ni, telah nahoeh, BAWIPA duengdoeh ka bawk han bout ati awh.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
22 Joshua ni hai nangmouh ni Cathut hah bawk hanelah, na kârawi awh toe telah, namamouh hoi namamouh doeh kapanuekkhaikung lah na kaawm awh telah atipouh navah, ahnimouh ni kapanuekkhaikung lah ka o awh ati awh teh,
Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
23 Joshua ni telah pawiteh, nangmouh koe kaawm e ram alouke cathutnaw hah pahnawt awh nateh Isarelnaw e BAWIPA Cathut koelah na lungthin kamlang awh ati pou.
Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
24 Taminaw ni kaimae BAWIPA hah ka bawk han. A lawk ka ngâi pouh han telah ati awh.
Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
25 Joshua ni hat hnin vah taminaw hoi lawkkam a sak teh, Shekhem kho vah, kâlawk, phunglamnaw a hruek pouh.
Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
26 Hote lawknaw hah BAWIPA e kâlawk cauk dawk a thut teh, BAWIPA e kathoungpounge hmuen teng kaawm e kathen kung rahim vah talung kalen poung a ung teh,
Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
27 hete talung teh maimanaw kapanuekkhaikung lah ao han. Cathut ni kâ na poe e lawk ka kuepcalah thai awh toe. Hatdawkvah nangmouh ni Cathut hah, na pahnawtnae hoi na hlout thai nahanelah, nangmanaw hah, kapanuekkhaikung lah na o han telah tami abuemlah koe a dei pouh hnukkhu,
“E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
28 amamouh lengkaleng râw a coe awh e hmuen koe bout a ban sak.
Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
29 Hathnukkhu BAWIPA e san, Nun capa Joshua teh kum 110 touh a pha teh a due.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
30 Ephraim mon dawk Gaash monrui atunglah kaawm e ahnie râw a coe e, Timnath-serah kho e talai dawk a pakawp awh.
Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
31 Joshua e kut dawk ao nathung pueng Isarelnaw ni BAWIPA teh a bawk awh. BAWIPA ni Isarel miphunnaw hanelah a sak e naw pueng hah a panue awh teh, Joshua a due hnukkhu kahring rae kacuenaw e kut rahim hai BAWIPA hah a bawk awh.
Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
32 Isarel miphunnaw ni Izip ram hoi a sin e Joseph e hrunaw hah, Shekhem a napa, Hamor e canaw koe ngun tangka cum touh hoi Jakop ni a ran e Shekhem kho e talai dawk a pakawp awh. Hote talai teh, Joseph capanaw e râw talai lah ao.
Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
33 Aron e ca vaihma bawi Eleazar hai a due. Ahnie capa Phinehas hai a yunaw ni a poe e Ephraim mon, Phinehas monrui dawk a pakawp awh.
Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.

< Joshua 24 >