< Semtilbu 21 >
1 Pakaiyin ana seisa bang chun Sarah ahung vil in Sarah chunga asuh bulhit peh tai.
Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
2 Hichun Sarah in nao ahin vop'in, Abraham chu atehset nung in Pathen in atep peh phat don tah in chapa khat ahin pe tan ahi.
Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
3 Abraham'in achapa chu amin Isaac asah tan ahi.
Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
4 Chule Isaac pen jou niget alhin nin Abraham'in Pathen thupeh bang in achapa chu chep atan pehtai.
Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
5 Isaac ahung pen chun, Apa Abraham chu kum jakhat ana lhing tai.
Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
6 Chuin Sarah in aphong doh in, “Pathen in nuina eipei,” ati.
Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
7 Chule aman, “Sarah hin chale nao noi hin chep sah inte tin koipen in Abraham kom a ana sei ngam dem? ahin lah keiman atehset nung in chapa khat kahin peh tai,” ati.
Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
8 Isaac chu ahung khanglen diu in an neh masa pen Abraham'in kipanan kikhop na asem e.
Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
9 Hichun Sarah in jong achapa chu Egypt mi Hagar'in Abraham ahinpeh Ishmael to aki chep lhon chu amudoh tai.
Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
10 Hichun amanun Abraham kom ah hitin aseiye, “Hiche sohnu le achapa chu solmang in ajeh chu hiche chapang hin keima chapa toh chanvou anei khom lhon ding aum poi; Isaac toh ki komto thei lou ding ahi.”
ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
11 Hichun Abraham'in nopmo asa lheh jeng in ajeh chu Ishmael jong chu achapa ahiye.
Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
12 Hinlah Pathen in Abraham chu ahoulimpi in, “Nangman chapang chung chang chule na sohnu jeh in ima lungphat mo na nei hih in, Sarah in bol in atiho chu bol in ajeh chu Isaac akonna bou na chilhah te hung kisim ding bou ahi.”
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
13 Hinlah keiman Hagar chapa jong chu nam lentah khat kaso thou thou ding ahi. Ajeh chu amapa jong chu nangma chapa jong ahi thouve.”
Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
14 Hichun Abraham ajing in matah in akithou vin, neh ding bu asutup'in chule twipoh na ding twibom Hagar chu apen aleng kouva aledoh peh tan ahi, hichun amanu le achapa chu asolmang in, chuin Hagar chu suhna ding helouvin Beersheba gamthip noiya avah lelei.
Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
15 Hichun twi ahung bei chun amanu (Hagar) chun naosen chu hampa nang boh lim noi ah akoi tai.
Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
16 Hichun amanu (Hagar) apot doh in atou lha tan achang seh in lamsom tobang kikah in “Keiman hiche chapang thi hi kamu nompoi,” atin amanu chu alhi along in akap tai.
Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
17 Hinlah Pathen in chapang ka awgin chu ajan chuin Pakai Vantil in vanna kon in Hagar chu ahin kouvin, “Hagar ipi boina nanei ham? Imacha kichatna nei hih in, Pathen in chapang ka awgin chu ajatai aumna muna kon in ati.
Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
18 Kipat doh inlang nao khu gaki dop loiyin na khut in kipom chah jon, ijeh inem itile keiman ama khu nam lentah ka hisah ding ahi.”
Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
19 Hichun Pathen in Hagar mit chu kho amusah in chua twi tamtah amusah tan, hichun amanun gangtah in twipai chu asu dim in chapang chu adon sah tai.
Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
20 Chule chapang chu Pathen in ahin umpi jing in neocha ahi apat gamthip gamnoi jenga ahung cheng in, thalpi kap ahung them lheh jeng in ahi.
Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
21 Chule Ishmael chu Paran gamthip noi a ana cheng in, chule anun Egypt gam'a ama ji ding in numei khat aga pui peh in ahi.
Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
22 Hiche phat laitah chun Abimelech le asepai jalamkai Phicol chu Abraham vil din ahung'e. “Pathen in nangma hi na umpi jing in, na thilbol na jouse ah na kithopi jinge,” tin ahung seiye.
Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
23 Pathen min'in kitem in, chule nei joulhep louhel ding, ka chate jong ahilou leh ka chilhah ho jong, kei vang nangma adia thilpha bolnom jing, chule tuhin naki hahsel ding, thilpha na bol jing ding hiche gam-sunga maljin gampam nahi laisen,” ati.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
24 Abraham'in adonbut in “Heng'e kaki tem e,” ati.
Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
25 Hichun Abraham'in Abimelech komma lunglhai louna aphong doh in Abimelech sohten twikul namphu a Abraham sohte ana lah peh'u thu chu ahi.
Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
26 “Tuchung hi hiche thu kajah masah pen ahi,” tin Abimelech in a donbut'e. “Keiman hiche chungchang hi koi oimo a, koi ngoh ding ham kahepoi. Ajeh chu phat masan ima thu nana sei kha poi,” ati.
Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
27 Abraham'in hichun akelngoi ho, kelcha ho, chule bonghon ho Abimelech apen kinop tona anei lhon'e.
Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
28 Hichun Abraham'in kelngoi nou sagi ho chu achom a alheng doh'in ahi.
Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
29 Abimelech in Abraham chu adonbut in “Hiche Kelngoi nou sagi ho hi ipi tina ham? amaho hina tum lhen doh in,” ati.
Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30 Abraham'in adonbut in, “Hiche twikhuh keiman ka laisa ahi, tia ahetoh aneipan peh na dinga hiche kelngoi pi sagi hi keima khut tah a na kisan ding ahi,” ati.
Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
31 Hijeh chun ama in hiche mun chun Beersheba asah tai. Ajeh chu mihem teni akihet tona mun lhon ahiye.
Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32 Beersheba mun a kihet tona muna aki muto jouvin, Abimelech le Phicol sepai lamkai pachu Philistine mun lama akinung le lhon tan ahi.
Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
33 Abraham'in Beersheba mun achun chahthing phung aphutdoh in, hiche achun aman Pathen chu tonsot Pathen ahi tin aphong doh e.
Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
34 Hichun Abraham chu Phillistine muna chun phat sottah achengin ahi.
Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.