< 2 Thusimbu 18 >

1 Jehoshaphat hi haona le jabolna'a bulhing setnin ananeitan ahi. Amahin numei kilah tona lamma Ahab to kisam kaina ananei lhonnin ahi.
Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
2 Kum phabep jouhin Samaria Ahab villin aga che suhin ahileh, Ahab in bongchal leh kelngoi athat nin ama leh ahin kilhon piho nehding chun nengtah in anagon peh in; chuleh Ramoth Gilead langa chetou dingin ana tem in ahi.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
3 Ahab lengpa chun Jehoshaphat jah’a chun Ramoth Gilead toh kidouna dinga hi neihung kitho pi ding ham anatin ahi. Jehoshaphat chun adonbut in, “Keile nang thakhat ihin, keimite jong nang mite ahin hiche galla chun nahung kithopi nange,” ati.
Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
4 Chujongleh Jehoshaphat chun Israel lengpa komma chun aseijin, “Tunin Pathenin epi asei jem veohite ati”
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
5 Hichun Israel lengpan themgao jali akou khommin amaho chu adongin, “Keiho hi Ramoth – Gilead satna galkon na kachediu ham ahilouleh kacheda diuham?” ati. Hichun amaho chun, “Chetou jengun amaho chu Pathen in lengpa nangkhut a ahin pehdoh ding ahi,” atiuve.
Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
6 Ahinlah Jehoshaphat in, “Tua hi eihon idoh theiju themgao adang umlou hitam?” ati.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
7 Israel lengpa chun Jehoshaphat kom’a, “Eihon idoh theiju Pakai themgao khatvang aumme, ahinlah keiman amahi kavetnom poi; ajeh chu amahin keidinga thilpha aseingai jipon, thilphalou ngen eisei peh ji ahi. Amachu Imla chapa Micaiah kitipa chu ahi. Hichun Jehoshaphat in, “Lengpa hiti chun thu seihih in,” ati.
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
8 Hiche phat chun Israel lengpan a sepai lamkai khat chu akouvin, Imla chapa Micaiah chu gangtah in gapuijin ati.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
9 Israel lengpaleh Judah lengpa Jehoshaphat chu aleng von lhon cheh a akivon lhonin, Samaria khopi lutna kelkot lutna tollhang achun atou lhonin amasang lhonna themgao hochun gaothu aseijun ahi
Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
10 Zedekiah chun thih alan saki limin asemmin, Pakaiyin hitin aseije, “Nangman hiche saki hi namanna Syria mite chu nasuhmang ding ahi,” ati.
Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
11 Hitichun themgao ho jouse chun gaothu aseisoh keijun, Ramoth Gilead jonin chetouvun nalolhin diu ahi, ajeh chu Pakaiyin amaho chu lengpa khutna ahin pehlut ding ahi atiuve
Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
12 Micaiah kouva kisol pachun akom’a hitin aseijin, “Ven, themgao ho jouse chun lengpan gal ajo dingin aseisoh keijun ahi, nangman jong hitimachun seile chun phading ahi,” atipeh e.
Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
13 Hichu Micaiah in adonbut in, “Hingjing Pakai minna kasei ahi, ka Pathen in asei seibou kaseiding ahi,” ati.
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
14 Micaiah chu lengpa kom ahung lhun phat in, lengpan, “Micaiah Ramoth – Gilead na hi galsatna kache diuham ahilouleh kache dauva pha ham? tin adongin ahileh aman, “Cheovin galolhing tauvin amaho chun nangma khut-a pehdoh in umnante,” atipeh in ahi.
Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
15 Hichun lengpan hitin aseije, “Micaiah nangkom mahi ijatvei Pakai minnin thudih seijin tia kangeh ding nahim?” atin ahi.
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
16 Hichun Micaiah in aseijin, “Keiman Israel tehi achingbei kelngoi banga molchung dunga akithe cheh-u kamui,” chuleh Pakaiyin hitin aseijin “Amaho hi lungmongin a incheh uva kileu hen,” ati.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
17 Israel lengpa chun Jehoshaphat komma hitin aseije, “Amahin kakomma thilpha asei khapon, thilse jeng aseije kati hilouham?” atin ahi.
Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
18 Hichun Micaiah in aseijin Pakaiyin hitin aseije, “Ngaijun Pakai chu alal touna – a atouvin van mite chu ajet aveijah adingun ahi.”
Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
19 “Pakai chun hitin aseijin, “Koipenin Ahab komma nacheova Ramoth – Gilead nakhu aga lhuhkam nadinga naga seipeh diu ham? Hichun vantil khatchun hitin aseijin achom khat nin thilchom aseijin ahi.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
20 Hichun lhagao khat nin Pakai angsung ahin nailut nin keima chengtin galhem lhange ati, Pakaiyin i-nagalo ding ham? ati.
Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
21 “Hichun aman keima chengting Ahab themgao jouse chu jou gaseisah ingkate ati, Pakaiyin chenlang hiti chun gabollin lang hung lolhing tan,” ati.
“‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
22 Hijeh chun veovin! “Pakaiyin a themgao jouse chu jou aseisah ahin, Pakaiyin naman thah nadinga asei sah ahibouve,” ati.
“Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
23 Hichun Chenaanah chapa Zedekiah chun anailut nin angeiphe abeh pih in, itih a chu Pakai lhagaovin keima eidalhah a nangkomma thu asei ham?” ati.
Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
24 Micaiah chun adonbut in “Tomlam a nalhailut’a naga kisel teng hetannate!” atipehin ahi.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
25 Hichun Israel lengpan a sepai lamkai komma chun, man inlang khopi vaihompa leh leng chapa Joash kommah ga pelut tan ati.
Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
26 Amani komma chun songkulla akoilhon ding keima damsella kahung kilekit kahsen anehding changlhah themkhat toh twi themkhat anapeo vin ati.
Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
27 Micaiah in asamjah jengin, nangma nahung kile poupouleh Pathen in keikomma thu aseilou hiding ahi! ati. “Chuleh aman Avella umho kommachun hiche kasei hi jasoh keijun,” ati.
Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
28 Hiche jouchun Israel lengpan Ahab leh Judah lengpa Jehoshaphat chu, Ramoth – Gilead khopi chu abulu dingin akondoh lhontai.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
29 Ahab chun Jehoshaphat kommah hitin aseijin, “Galmunna ilut tengleh nangin lengvon kivon nin lang, ken vonchom kivon inge,” ati. Hichun Israel lengpa chun vonchom aki vonnin gal munnah aluttan ahi.
Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
30 Syria lengpa chun sakol kangchunga tou gallam kai hochu Israel lengpa bou atup diuvin thu apen ahi.
Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
31 Hijeh chun Jehoshaphat lengpa chu amu phatnun Israel lengpa ahisah sohkeijun, anokhum tauvin ahi. Ahinlah Jehoshaphat chu apeng jah in ahileh, Pakaiyin ahuhdoh in ama nokhumho chu adalhah sah tan ahi.
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
32 Sakol kangchunga tou lamkai hochun ama chu Israel lengpa ahilou ahedoh tauvin adalha tauve.
Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
33 Ahinlah Syria sepai khatnin thalchang khatchu agah donkapmin ahileh, Israel lengpa galvon kikah – a chun akaplut khatan ahi, hichun asakol kangtalai tolpa komma chun kakitong khatai galmunna kon in neitol doh tan atin ahi.
Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
34 Hiche ni chun galkisat chu akhoh cheh jengin, Israel lengpa vangchu sakol kangtalai chunga aoplhatan, nilhah lang geijin Syria te lang chu angan nilhum kon in athitai.
Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.

< 2 Thusimbu 18 >