< Jeremiah 10 >

1 Israel imkhui nangmih taengah BOEIPA loh a thui olka te ya uh.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
2 BOEIPA loh he ni a thui. Namtom kah longpuei te awt uh boel lamtah vaan miknoek nen khaw rhihyawp uh boeh. Te lamlong ni namtom rhoek khaw a rhihyawp uh.
Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
3 A honghi pilnam kah khosing dongah he duup lamkah thing ni kutthai kut kah bibi loh tubael neh a saii ngawn.
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
4 ngun neh, sui neh a sawtthen sak tih, thicung neh thilung neh a khing dongah lol voel pawh.
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
5 Te te uitang lo kah vatai bangla om tih cal thai pawh. A kan uh thai pawt dongah a koh la a koh uh. Te te rhih uh boeh. Thaehuet uh thai pawt tih a voelphoeng ham khaw a om uh moenih.
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
6 BOEIPA namah bang moenih. Namah tah na len tih na ming khaw, thayung thamal dongah tanglue pai.
Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
7 Namtom kah manghai namah aka rhih pawt te unim? Namtom hlangcueih boeih khuikah khaw na taengah naep ngawn tih a ram pum ah namah bang a om moenih.
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
8 Pakhat la dom uh thae tih a hong thing kah thuituennah dongah ang uh.
Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
9 Tarshish lamkah cak ben hang khuen tih Uphaz lamkah sui khaw kutthai kah a bibi mai ni. Te boeih te aka picai kah kut long ni hlangcueih kah bibi bangla a pueinak te a thim neh daidi neh a loeih pah.
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 Tedae BOEIPA amah he oltak Pathen, mulhing Pathen neh kumhal manghai ni. A thinhul dongah diklai hinghuen tih a kosi te namtom loh ueh pawh.
Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
11 Amih pathen rhoek taengah khaw he tlam he thui uh. Amih loh vaan neh diklai a saii pawt dongah te rhoek tah diklai lamkah neh vaan hmui lamloh hmata uh ni.
“Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
12 A thadueng neh diklai a saii, a cueihnah neh lunglai a thoh tih a lungcuei neh vaan khaw a dih.
Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Vaan kah tui len khaw a ol a paek tih diklai khobawt lamkah khoboei khaw a pongpa sak. Diklai te rhaek neh khotlan a saii pah tih a thakvoh lamloh khohli a thoeng sak.
Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
14 Hlang boeih he mingnah dongah rhawm coeng tih aka picai boeih khaw mueithuk dongah koh coeng. A muei hong neh a khuiah hil om pawh.
Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Amih ahonghi neh a hohap kah khoboe tah amamih kah cawhnah tue vaengah milh bitni.
Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Jakob kah hamsum tah he bang moenih. Amah kah rho la Israel koca boeih aka hlinsai tah a ming khaw caempuei BOEIPA ni.
Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
17 Vongup ah aka om, aka om loh na hnocun te diklai lamloh coi uh laeh.
Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
18 BOEIPA loh he ni a thui. Tahae ah diklai khosa rhoek te voeikhat la ka dong coeng he. Amih soah ka daengdaeh daengah ni a hmuh uh eh.
Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
19 Anunae kai aih he, ka pocinah dongah ka hmasoe khaw nue coeng. Tedae tloh he ka phuei mai eh ka ti coeng.
Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
20 Ka dap khaw a rhoelrhak tih ka liva khaw boeih pat. Ka ca rhoek khaw kai lamloh coe uh tih om uh pawh. Ka dap aka tuk tih ka himbaiyan aka thoh khaw om voel pawh.
Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
21 Boiva aka dawn khaw a dom coeng tih BOEIPA te toem uh pawh. Te dongah ni cangbam uh pawt tih a rhamtlim khaw boeih a taekyak pah.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
22 Tlangpuei khohmuen lamkah hinghuennah puei loh Judah khopuei te khopong kah pongui khuirhung la khueh ham olthang ol ha pawk coeng ke.
Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
23 BOEIPA aw, a longpuei te hlang kah pawt tih hlang dongah a pongpa kolla a khokan a rhoekbah te khaw ka ming.
Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
24 Aw BOEIPA kai he tiktamnah nen mah n'thuituen lamtah na thintoek nen boel saeh. Kai nan hnop ve.
Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
25 Nang aka ming pawh namtom so neh na ming aka phoei pawt cako soah na kosi te hawk mai. Jakob te a yoop la a yoop uh coeng. Te dongah amah te a khah uh tih a tolkhoeng te a pong sakuh.
Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.

< Jeremiah 10 >